< Hosea 4 >

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Israẹli, nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùn kan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà. “Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́, Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà,
Écoutez la parole du Seigneur, ô fils d'Israël; car le Seigneur va entrer en jugement avec les habitants de la terre, parce qu'il n'existe plus sur la terre ni vérité, ni miséricorde, ni connaissance de Dieu.
2 àfi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyàn olè jíjà àti panṣágà. Wọ́n rú gbogbo òfin, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
Les malédictions, le mensonge, le meurtre, le vol, l'adultère, sont répandus sur la terre, et le sang se mêle au sang.
3 Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo olùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù. Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹja inú omi ló ń kú.
C'est pourquoi la terre sera en deuil, et elle sera affaiblie avec tout ce qui l'habite, avec les bêtes des champs, les reptiles et les oiseaux du ciel; et même les poissons de la mer dépériront.
4 “Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá, kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹnìkejì nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbí àwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà.
Que nul n'ait de contestation, que nul ne reprenne autrui; Mon peuple est comme un peuple révolté contre ses prêtres.
5 Ẹ ń ṣubú lọ́sàn án àti lóru àwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lú yín. Èmi ó pa ìyá rẹ run,
Et il perdra sa force de jour en jour, et, avec toi, le prophète aussi perdra sa force; J'ai comparé ta mère à la nuit.
6 àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀. “Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀. Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi; nítorí pé ẹ ti kọ òfin Ọlọ́run yín sílẹ̀, Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.
Mon peuple est comme s'il ne savait rien; car tu as repoussé la science, et Moi Je te repousserai à Mon tour, pour que tu n'aies plus Mon sacerdoce; tu as oublié la loi de Dieu, et Moi j'oublierai tes enfants.
7 Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí i bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú
Plus ils se sont multipliés, plus ils ont péché contre Moi; Je changerai leur gloire en opprobre.
8 wọ́n ń jẹun nípa ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi, wọ́n sì ń gbádùn nínú ìwà búburú wọn.
Ils se nourriront des péchés de Mon peuple, et ils mettront leurs âmes en leurs iniquités.
9 Yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe rí náà ni àwọn àlùfáà rí. Èmi ó jẹ gbogbo wọn ní yà nítorí ọ̀nà wọn. Èmi ó sì san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.
Et tel sera le peuple, tel sera la prêtre; et sur eux Je tirerai vengeance de leurs voies, et Je les rétribuerai selon leurs conseils.
10 “Wọn ó máa jẹun ṣùgbọ́n wọn kò ní yó; wọn ó ṣe àgbèrè ṣùgbọ́n, wọn kò ni pọ̀ sí i, nítorí pé wọ́n ti kọ Olúwa sílẹ̀, wọ́n sì ti fi ara wọn
Ils mangeront, et ne seront pas rassasiés; ils se sont prostitués, et ne prospèrent point, parce qu'ils ont cessé de prendre garde au Seigneur.
11 fún àgbèrè; wọ́n fi ara wọn fún wáìnì àtijọ́, àti tuntun èyí tó gba òye àwọn ènìyàn mi sọnù.
Le cœur de Mon peuple s'est complu dans la prostitution, le vin et l'ivresse.
12 Wọ́n ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ère igi ọ̀pá igi sì ń dá wọn lóhùn. Ẹ̀mí àgbèrè ti mú wọn ṣìnà wọ́n sì jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wọn.
Ils ont consulté des présages, et avec des baguettes on leur a fait des prédictions; ils ont été égarés en un esprit de débauche, et ils se sont prostitués en s'éloignant de leur Dieu.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ lórí àwọn òkè ńlá, wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeré, lábẹ́ igi óákù, àti igi Poplari àti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dára. Nítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrè àti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.
Ils ont sacrifié sur les hauts lieux; ils ont brûlé de l'encens sur des collines, sous un chêne ou sous un peuplier, ou sous tout arbre touffu, parce qu'ils se plaisent à l'ombre. À cause de cela, vos filles se prostitueront, et vos femmes seront adultères.
14 “Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yín ní yà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè tàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín, nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè nítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́. Wọ́n sì ń rú ẹbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ojúbọ òrìṣà. Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!
Et Je ne visiterai plus vos filles quand elles se prostitueront, ni vos femmes quand elles seront adultères, parce que vous-mêmes vous vous êtes souillés avec des prostituées, et que vous avez sacrifié avec des initiés, et que le peuple (un peuple intelligent!) s'est laissé prendre aux filets d'une prostituée.
15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Israẹli, ìdájọ́ yìí wà fún un yín. Ẹ má ṣe jẹ́ kí Juda di ẹlẹ́bi. “Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali. Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Beti-Afeni ẹ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láààyè nítòótọ́!’
Or sache-le bien, toi, Israël, et toi, Juda: n'allez point en Galgala, ne montez point à la maison de On, et ne jurez point par le Dieu vivant.
16 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe agídí bí alágídí ọmọ màlúù. Báwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọn bí àgùntàn ní pápá oko tútù?
Car Israël, comme une génisse aiguillonnée par un taon, a eu des transports frénétiques, et maintenant le Seigneur le fera paître comme un agneau dans un lieu spacieux.
17 Efraimu ti darapọ̀ mọ́ òrìṣà, ẹ fi sílẹ̀!
Éphraïm, qui participe aux idoles, a mis devant lui des pierres d'achoppement.
18 Bí ohun mímu wọn bá tilẹ̀ tán, wọ́n tún tẹ̀síwájú nínú àgbèrè. Àwọn olórí wọn fẹ́ràn ohun ìtìjú ju ohun ìyìn lọ.
Il a provoqué les Chananéens; ils se sont prostitués et prostitués, et ils ont aimé l'ignominie et ses rugissements.
19 Ìjì ni yóò gbá wọn lọ. Gbogbo ìrúbọ wọn yóò sì kó ìtìjú bá wọn.
Seigneur, Tu es un tourbillon de vent emporté sur ses ailes; pour eux, ils seront confondus à cause de leurs autels.

< Hosea 4 >