< Hosea 4 >

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Israẹli, nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùn kan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà. “Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́, Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà,
Kuulkaat Herran sanaa, te Israelin lapset! Sillä Herralla on syy niitä nuhdella, jotka maassa asuvat; sentähden ettei totuutta, eikä laupiutta, eikä Jumalan tuntoa ole maassa.
2 àfi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyàn olè jíjà àti panṣágà. Wọ́n rú gbogbo òfin, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
Mutta valapattoisuus, valhe, murha, varkaus ja huoruus, ne ovat vallan saaneet, ja yksi veren vika tapahtuu toisen jälkeen.
3 Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo olùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù. Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹja inú omi ló ń kú.
Sentähden pitää maakunnan surkiana oleman, ja kaikki, jotka siinä asuvat, pitää nääntymän, ynnä eläinten kanssa kedolla ja taivaan lintuin kanssa; ja kalat meressä pitää myös hukkaantuman.
4 “Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá, kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹnìkejì nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbí àwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà.
Tosin ei saa kenkään nuhdella eikä rangaista ketään; sillä sinun kansas on niinkuin pappein nuhtelia.
5 Ẹ ń ṣubú lọ́sàn án àti lóru àwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lú yín. Èmi ó pa ìyá rẹ run,
Sentähden pitää sinun päivällä lankeeman, ja propheta sinun kanssas yöllä; ja minä tahdon äitis hukuttaa.
6 àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀. “Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀. Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi; nítorí pé ẹ ti kọ òfin Ọlọ́run yín sílẹ̀, Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.
Minun kansani on turmeltu, ettei heillä ole ymmärrystä; että sinä hylkäsit ymmärryksen, tahdon minä myös sinun hyljätä, ettei sinun pidä enään minun pappini oleman: ja sinä unohdit sinun Jumalas lain, sentähden tahdon minä myös unohtaa sinunkin lapses.
7 Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí i bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú
Jota enempi heitä on, sitä enemmin he tekevät syntiä minua vastaan; sentähden teen minä heidän kunniansa häpiäksi.
8 wọ́n ń jẹun nípa ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi, wọ́n sì ń gbádùn nínú ìwà búburú wọn.
He syövät minun kansani syntiuhria ja himoitsevat heidän syntejänsä.
9 Yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe rí náà ni àwọn àlùfáà rí. Èmi ó jẹ gbogbo wọn ní yà nítorí ọ̀nà wọn. Èmi ó sì san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.
Kansalle pitää niinkuin papeillekin tapahtuman; sillä minä tahdon heidän pahat tekonsa etsiä, ja kostan heille niinkuin he ansainneet ovat;
10 “Wọn ó máa jẹun ṣùgbọ́n wọn kò ní yó; wọn ó ṣe àgbèrè ṣùgbọ́n, wọn kò ni pọ̀ sí i, nítorí pé wọ́n ti kọ Olúwa sílẹ̀, wọ́n sì ti fi ara wọn
Niin että he syövät, ja ei tule ravituksi; he tekevät huoruutta, ja ei heidän pidä menestymän; sillä he ovat hyljänneet Herran, ja ei totelleet häntä.
11 fún àgbèrè; wọ́n fi ara wọn fún wáìnì àtijọ́, àti tuntun èyí tó gba òye àwọn ènìyàn mi sọnù.
Huoruus, viina ja väkevä juoma hulluksi saattavat.
12 Wọ́n ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ère igi ọ̀pá igi sì ń dá wọn lóhùn. Ẹ̀mí àgbèrè ti mú wọn ṣìnà wọ́n sì jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wọn.
Minun kansani kysyy neuvoa puulta ja hänen sauvansa saarnaa hänelle; sillä huoruuden henki vietteli heitä, niin että he tekivät huorin Jumalaansa vastaan.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ lórí àwọn òkè ńlá, wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeré, lábẹ́ igi óákù, àti igi Poplari àti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dára. Nítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrè àti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.
Vuorten kukkuloilla he uhraavat, ja korkeuksilla he suitsuttavat, tammien alla, haapain ja saarnien alla, että ne antavat suloisen varjon; sentähden tulevat teidän tyttärenne portoiksi ja teidän morsiamenne huoraksi.
14 “Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yín ní yà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè tàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín, nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè nítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́. Wọ́n sì ń rú ẹbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ojúbọ òrìṣà. Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!
En minä tahdo etsiä teidän tyttäriänne, koska he salavuoteudessa elävät, enkä teidän morsiamianne, koska he huorin tekevät; sillä he eroittavat itsensä huorain sekaan, ja porttoin kanssa uhraavat; ja se ymmärtämätöin kansa saa haavoja.
15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Israẹli, ìdájọ́ yìí wà fún un yín. Ẹ má ṣe jẹ́ kí Juda di ẹlẹ́bi. “Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali. Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Beti-Afeni ẹ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láààyè nítòótọ́!’
Israel, jos sinä kuitenkin tahdot huorin tehdä, niin älköön Juuda sentähden vialliseksi tulko! Älkäät menkö Gilgaliin, ja älkäät tulko ylös Betaveniin, ja älkäät vannoko: Niin totta kuin Herra elää!
16 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe agídí bí alágídí ọmọ màlúù. Báwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọn bí àgùntàn ní pápá oko tútù?
Sillä Israel on hillimätöin niinkuin kiiliväinen lehmä; niin Herra on myös kaitseva heitä, kuin lammasta avarassa paikassa.
17 Efraimu ti darapọ̀ mọ́ òrìṣà, ẹ fi sílẹ̀!
Sillä Ephraim on suostunut epäjumaliin; anna hänen mennä.
18 Bí ohun mímu wọn bá tilẹ̀ tán, wọ́n tún tẹ̀síwájú nínú àgbèrè. Àwọn olórí wọn fẹ́ràn ohun ìtìjú ju ohun ìyìn lọ.
He ovat itsensä juopumiseen ja huoruuteen laskeneet, ja heidän valtamiehensä rakastavat antimia häpiäksi.
19 Ìjì ni yóò gbá wọn lọ. Gbogbo ìrúbọ wọn yóò sì kó ìtìjú bá wọn.
Tuulispään pitää siivillänsä heidät sidottuina ajaman pois, ja heidän pitää häpiään tuleman uhreistansa.

< Hosea 4 >