< Hosea 4 >

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Israẹli, nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùn kan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà. “Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́, Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà,
Hear [the] word of Yahweh O people of Israel for a case at law [belongs] to Yahweh with [the] inhabitants of the land for there not [is] faithfulness and there not [is] covenant loyalty and there not [is] knowledge of God in the land.
2 àfi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyàn olè jíjà àti panṣágà. Wọ́n rú gbogbo òfin, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
Cursing and deceiving and murdering and stealing and committing adultery people have broken out and blood blood they have touched.
3 Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo olùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù. Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹja inú omi ló ń kú.
There-fore - it will dry up the land and he will wither every [one who] dwells in it among [the] animal[s] of the field and among [the] bird[s] of the heavens and also [the] fish of the sea they will be removed.
4 “Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá, kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹnìkejì nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbí àwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà.
Nevertheless anyone may not he bring a case and may not he reprove anyone and people your [is] like [those who] contend a priest.
5 Ẹ ń ṣubú lọ́sàn án àti lóru àwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lú yín. Èmi ó pa ìyá rẹ run,
And you will stumble the day and he will stumble also a prophet with you night and I will destroy mother your.
6 àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀. “Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀. Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi; nítorí pé ẹ ti kọ òfin Ọlọ́run yín sílẹ̀, Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.
They have been destroyed people my because not knowledge for you knowledge you have rejected and I will reject you from serving as a priest me and you have forgotten [the] law of God your I will forget children your also I.
7 Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí i bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú
As increased they so they sinned to me glory their for shame I will exchange.
8 wọ́n ń jẹun nípa ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi, wọ́n sì ń gbádùn nínú ìwà búburú wọn.
[the] sin of People my they eat and to iniquity their they lift up desire its.
9 Yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe rí náà ni àwọn àlùfáà rí. Èmi ó jẹ gbogbo wọn ní yà nítorí ọ̀nà wọn. Èmi ó sì san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.
And it will be as the people as the priest and I will visit on him ways his and deeds his I will repay to him.
10 “Wọn ó máa jẹun ṣùgbọ́n wọn kò ní yó; wọn ó ṣe àgbèrè ṣùgbọ́n, wọn kò ni pọ̀ sí i, nítorí pé wọ́n ti kọ Olúwa sílẹ̀, wọ́n sì ti fi ara wọn
And they will eat and not they will be satisfied they will prostitute themselves and not they will increase for Yahweh they have forsaken to keep.
11 fún àgbèrè; wọ́n fi ara wọn fún wáìnì àtijọ́, àti tuntun èyí tó gba òye àwọn ènìyàn mi sọnù.
Prostitution and wine and new wine it takes away [the] heart.
12 Wọ́n ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ère igi ọ̀pá igi sì ń dá wọn lóhùn. Ẹ̀mí àgbèrè ti mú wọn ṣìnà wọ́n sì jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wọn.
People my by wood his he enquires and stick his it tells to him for a spirit of prostitution it has misled and they have prostituted themselves from under God their.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ lórí àwọn òkè ńlá, wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeré, lábẹ́ igi óákù, àti igi Poplari àti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dára. Nítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrè àti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.
On [the] tops of the mountains they sacrifice and on the hills they make smoke under oak and poplar and terebinth for [is] good shade its there-fore they prostitute themselves daughters your and brides your they commit adultery.
14 “Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yín ní yà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè tàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín, nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè nítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́. Wọ́n sì ń rú ẹbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ojúbọ òrìṣà. Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!
Not I will visit [judgment] on daughters your if they prostitute themselves and on brides your if they commit adultery for they [masc] with the prostitutes they go apart and with the cult prostitutes they sacrifice and a people [which] not it understands it will be ruined.
15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Israẹli, ìdájọ́ yìí wà fún un yín. Ẹ má ṣe jẹ́ kí Juda di ẹlẹ́bi. “Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali. Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Beti-Afeni ẹ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láààyè nítòótọ́!’
Though [are] prostituting yourself you O Israel may not it become guilty Judah and may not you go Gilgal and may not you go up Beth Aven and may not you swear [by] [the] life of Yahweh.
16 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe agídí bí alágídí ọmọ màlúù. Báwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọn bí àgùntàn ní pápá oko tútù?
For like a heifer stubborn it is stubborn Israel now he will pasture them Yahweh like a lamb in roomy place.
17 Efraimu ti darapọ̀ mọ́ òrìṣà, ẹ fi sílẹ̀!
[is] joined of Idols Ephraim leave alone him.
18 Bí ohun mímu wọn bá tilẹ̀ tán, wọ́n tún tẹ̀síwájú nínú àgbèrè. Àwọn olórí wọn fẹ́ràn ohun ìtìjú ju ohun ìyìn lọ.
It has come to an end drink their certainly they have prostituted themselves they have loved love shame shields its.
19 Ìjì ni yóò gbá wọn lọ. Gbogbo ìrúbọ wọn yóò sì kó ìtìjú bá wọn.
It has wrapped a wind it in wings its so they may be ashamed from sacrifices their.

< Hosea 4 >