< Hosea 4 >

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Israẹli, nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùn kan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà. “Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́, Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà,
BOEIPA ol he Israel ca rhoek loh ya saeh. BOEIPA kah tuituknah te diklai khosa taengah om coeng. Oltak tal tih sitlohnah tal coeng. Diklai ah Pathen mingnah khaw tal coeng.
2 àfi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyàn olè jíjà àti panṣágà. Wọ́n rú gbogbo òfin, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
Tap ham neh basa ham, ngawn ham neh huen hamla, samphaih ham a phae uh tih thii te thii la a kap sakuh.
3 Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo olùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù. Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹja inú omi ló ń kú.
Te dongah khohmuen loh nguekcoi tih a khuikah khosa boeih khaw tahah coeng. Diklai mulhing neh vaan kah vaa khaw, tuitunli kah nga khaw khum coeng.
4 “Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá, kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹnìkejì nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbí àwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà.
Tedae hlang loh ho boel saeh lamtah hlang loh tluung boel saeh. Na pilnam khaw khosoih kah a ho bangla om coeng.
5 Ẹ ń ṣubú lọ́sàn án àti lóru àwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lú yín. Èmi ó pa ìyá rẹ run,
Khothaih ah na paloe vetih na taengkah tonghma khaw khoyin ah paloe ni. Te vaengah na manu te ka hmata sak ni.
6 àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀. “Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀. Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi; nítorí pé ẹ ti kọ òfin Ọlọ́run yín sílẹ̀, Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.
Mingnah a tal lamloh ka pilnam hmata uh coeng. Nang loh mingnah na hnawt dongah nang te ka khosoih lamloh kan hnawt. Na Pathen kah olkhueng na hnilh dongah kai long khaw na ca rhoek te ka hnilh ni.
7 Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí i bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú
A pungtai uh bangla kai taengah a tholh dongah amih thangpomnah te yahpohnah neh ka tho pah.
8 wọ́n ń jẹun nípa ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi, wọ́n sì ń gbádùn nínú ìwà búburú wọn.
Ka pilnam kah boirhaem maeh a caak tih amih kathaesainah dongah a hinglu a phueih uh.
9 Yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe rí náà ni àwọn àlùfáà rí. Èmi ó jẹ gbogbo wọn ní yà nítorí ọ̀nà wọn. Èmi ó sì san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.
Te dongah pilnam bangla khosoih khaw om boeiloeih coeng. Anih te a longpuei ka cawh vetih a khoboe bangla amah te ka thuung ni.
10 “Wọn ó máa jẹun ṣùgbọ́n wọn kò ní yó; wọn ó ṣe àgbèrè ṣùgbọ́n, wọn kò ni pọ̀ sí i, nítorí pé wọ́n ti kọ Olúwa sílẹ̀, wọ́n sì ti fi ara wọn
BOEIPA te hnawt hamla a dawn uh dongah ca uh cakhaw uh hah uh mahpawh. Cukhalh uh cakhaw pungtai uh mahpawh.
11 fún àgbèrè; wọ́n fi ara wọn fún wáìnì àtijọ́, àti tuntun èyí tó gba òye àwọn ènìyàn mi sọnù.
Pumyoihnah, misurrhuem neh misur thai loh lungbuei ni a loh.
12 Wọ́n ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ère igi ọ̀pá igi sì ń dá wọn lóhùn. Ẹ̀mí àgbèrè ti mú wọn ṣìnà wọ́n sì jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wọn.
Ka pilnam loh a thingngo te a dawt tih a conghol loh anih ham a thui pah. Pumyoihnah mueihla dongah kho a hmang tih a Pathen hnuk lamloh cukhalh uh.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ lórí àwọn òkè ńlá, wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeré, lábẹ́ igi óákù, àti igi Poplari àti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dára. Nítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrè àti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.
Tlang soi ah a nawn uh tih som kah thingnu, khabok neh rhokael hmui he a hlip a then dongah a phum uh. He dongah ni na tanu rhoek loh cukhalh uh tih na langa rhoek khaw a samphaih uh.
14 “Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yín ní yà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè tàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín, nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè nítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́. Wọ́n sì ń rú ẹbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ojúbọ òrìṣà. Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!
Na tanu te cukhalh uh tih na langa rhoek te a samphaih vaengah ka cawh mahpawt nim? Amih te pumyoi rhoek neh pam uh tih hlanghalh rhoek taengah a nawn uh. Tedae pilnam khaw a yakming pawt dongah caehdoelh ni.
15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Israẹli, ìdájọ́ yìí wà fún un yín. Ẹ má ṣe jẹ́ kí Juda di ẹlẹ́bi. “Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali. Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Beti-Afeni ẹ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láààyè nítòótọ́!’
Israel nang na cukhalh akhaw Judah te boe pawt lah mako. Gilgal te paan boel lamtah Bethaven la cet boeh. BOEIPA kah hingnah te toemngam uh boeh.
16 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe agídí bí alágídí ọmọ màlúù. Báwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọn bí àgùntàn ní pápá oko tútù?
Israel kah thinthah, thinthah rhoe mah vaito banghui pawni. Amih te BOEIPA loh tuca bangla a hoengpoeknah ah a luem sak coeng dae ta.
17 Efraimu ti darapọ̀ mọ́ òrìṣà, ẹ fi sílẹ̀!
Muei aka sun Ephraim aw anih te toeng laeh.
18 Bí ohun mímu wọn bá tilẹ̀ tán, wọ́n tún tẹ̀síwájú nínú àgbèrè. Àwọn olórí wọn fẹ́ràn ohun ìtìjú ju ohun ìyìn lọ.
A yuhuem te a khok vaengah a cukhalh hmuen la cukhalh uh tih a photling kah yahpohnah te a lung la a lungnah uh.
19 Ìjì ni yóò gbá wọn lọ. Gbogbo ìrúbọ wọn yóò sì kó ìtìjú bá wọn.
Amah neh a phae te khohli loh a yawn vetih a hmueih dongah yak ni.

< Hosea 4 >