< Hosea 2 >

1 “Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
— Ananglargha dewayimni yetküzüp, uning bilen dewalishinglar; chünki u Méning ayalim emes we Men uning éri emes; u pahishilik turqini chirayidin, zinaxorluq haletlirini köksining arisidin yaqatsun!
2 “Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
3 Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
Bolmisa, Men uni qip-yalingach qilip qoyimen, tughulghan künidikidek anidin tughma qilip qoyimen; Men uni xuddi chöl-bayawan’gha oxshash qilimen, Uni bir qaghjiraq yerge aylandurimen, Uni ussuzluq bilen öltürimen;
4 Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
Uning balilirigha rehim qilmaymen, Chünki ular pahishiliklerdin törelgen balilardur.
5 Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
Chünki ularning anisi pahishilik qilghan, Ularni qarnida kötürgüchi nomussizliq qilghan; Chünki u: «Men manga nan we süyümni, yung we kanapimni, zeytun méyim we ichimlik-sharablirimni teminligüchi ashnilirimgha intilip ularni qoghlishimen» — dédi.
6 Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
— Shunga mana, Men yolungni tiken-jighanliqlar bilen chitlap qorshiwalimen, [Israilning] etrapini tam bilen tosimen, u chighir yollirini tapalmaydighan bolidu.
7 Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
Shuning bilen u ashnilirini qoghlaydu, biraq ulargha yétishelmeydu; Ularni izdeydu, tapalmaydu; Shunglashqa u: «Men bérip birinchi érimni tépip, uning yénigha qaytimen; chünki ehwalim bügünkidin yaxshi idi» — deydu.
8 Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
— U ziraetlerni, yéngi sharab we zeytun méyini teminligüchining Men ikenlikimni, Özliri «Baal» butlarni yasashqa ishletken kümüsh-altunni köp qilghuchining Men ikenlikimni zadi bilmidi.
9 “Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
Shunga Men qaytip kélimen, uningdiki ziraetlirimni öz waqtida, Yéngi sharablirimni öz peslide élip kétimen, Özümdiki ularning yalingachliqini yépishqa kéreklik yung-kanaplirimni bermey qayturup kétimen;
10 Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
Hazir Men uning nomussizliqini ashnilirining köz aldida ashkarilaymen, Héchkim uni qolumdin qutquzalmaydu.
11 Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
Shundaq qilip uning tamashalirigha xatime bérimen; Uning héytlirigha! Uning «yéngi ay»lirigha! Uning «shabat»lirigha! Qisqisi, uning barliq «jamaet ibadet sorun»lirigha xatime bérimen!
12 Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
We Men uning üzüm tallirini we enjür derexlirini weyran qilimen; U bularni: «Bular bolsa ashnilirim manga bergen ish heqqilirimdur!» dégenidi; Men bularni janggalgha aylandurimen, yawayi haywanlar ularni yep kétidu.
13 Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
Men uning béshigha «Baal»larning künlirini chüshürimen; Chünki u [shu künliride] ulargha isriq salatti, U özini üzükliri we zibu-zinnetliri bilen perdazlap, Ashnilirini qoghliship, Méni untudi — deydu Perwerdigar.
14 “Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
Shunga mana, Men uning könglini alimen, Uni dalagha élip kélimen, könglige sözleymen.
15 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
Shundaq qilip Men uninggha shu yerde üzümzarlirini qayturimen, «Aqor jilghisi»ni «ümid ishiki» qilip bérimen; Andin u shu yerde yashliq künliridikidek, Misir zéminidin chiqqan künidek küy-naxsha éytidu.
16 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
We shu küni emelge ashuruliduki, — deydu Perwerdigar —«Sen Méni «érim» dep chaqirisen, Ikkinchi Méni «Baal»im démeysen.
17 Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
Chünki Men «Baal»larning namlirini séning aghzingdin élip tashlaymen, Ular bu nami bilen ikkinchi héchqandaq eslenmeydu.
18 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
Shuning bilen Men ular üchün daladiki haywanlar, asmandiki uchar-qanatlar we yer yüzidiki ömüligüchiler bilen ehde tüzimen; Men oqya, qilich we jengni sundurup zémindin élip tashlaymen; [xelqimni] aman-ésen yatquzimen.
19 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
Shundaq qilip Men séni ebedil’ebed Özümge baghlaymen; heqqaniyliqta, méhir-muhebbette, rehim-shepqetlerde séni Özümge baghlaymen;
20 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
Sadaqetlikte séni Özümge baghlaymen, shuning bilen sen Perwerdigarni bilip yétisen.
21 “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
We shu künide emelge ashuruliduki, «Men anglaymen» — deydu Perwerdigar, — «Men asmanlarning telipini anglaymen, bular yer-zéminning telipini anglaydu;
22 ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
Yer-zémin ziraetlerning, yéngi sharab we zeytun méyining telipini anglaydu; we bular «Yizreel»ning telipini anglaydu!
23 Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”
We Men Özüm üchün uni zéminda tériymen; Men «Lo-ruhamah»gha rehim qilimen; Men «Lo-ammi»gha: «Méning xelqim!» deymen; we ular Méni: «Méning Xudayim!» — deydu.

< Hosea 2 >