< Hosea 2 >

1 “Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
Svojim bratom recite: ›Moje ljudstvo‹ in svojim sestram: ›Pomiloščena.‹
2 “Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
Pravdajte se s svojo materjo, pravdajte, kajti ona ni moja žena niti jaz nisem njen soprog. Naj torej odloži svoja vlačugarstva iz svojega pogleda in svoja zakonolomstva izmed svojih prsi,
3 Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
da je ne bom slekel do golega in jo postavil kakor na dan, ko je bila rojena in jo naredil kakor divjino in jo postavil kakor suho deželo in jo pogubil z žejo.
4 Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
Ne bom se usmilil njenih otrok, kajti oni so otroci vlačugarstev.
5 Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
Kajti njihova mati je igrala pocestnico. Ta, ki jih je spočela, je storila sramotno, kajti rekla je: ›Hodila bom za svojimi ljubimci, ki mi dajejo moj kruh in mojo vodo, mojo volno in moj lan, moje olje in mojo pijačo.‹
6 Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
Zatorej glej, tvojo pot bom ogradil s trnjem in naredil zid, da ne bo našla svojih steza.
7 Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
Sledila bo za svojimi ljubimci, toda ne bo jih dohitela in iskala jih bo, toda ne bo jih našla. Tedaj bo rekla: ›Šla bom in se vrnila k svojemu prvemu soprogu, kajti takrat je bilo z menoj bolje kakor sedaj.‹
8 Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
Kajti ni vedela, da sem ji jaz dajal njeno žito, vino, olje in množil njeno srebro in zlato, ki so ga pripravili za Báala.
9 “Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
Zatorej se bom vrnil in odvzel svoje žito ob njegovem času in svoje vino v njegovem obdobju in nazaj bom dobil svojo volno in svoj lan, izročen, da pokrije njeno nagoto.
10 Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
Sedaj bom odkril njeno nespodobnost pred očmi njenih ljubimcev in nihče je ne bo rešil iz moje roke.
11 Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
Prav tako bom vsemu njenemu veselju povzročil, da bo prenehalo, njenim prazničnim dnevom, njenim mlajem, njenim šabatom in vsem njenim slovesnim praznikom.
12 Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
Uničil bom njene trte in njena figova drevesa, o katerih je rekla: ›To so moje nagrade, ki so mi jih dajali moji ljubimci.‹ Jaz pa jih bom naredil za gozd in živali polja jih bodo jedle.
13 Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
Na njej bom obiskal dneve Báalov, na katere jim je zažigala kadilo in se krasila s svojimi uhani in svojimi dragocenostmi in hodila za svojimi ljubimci, mene pa pozabila, « govori Gospod.
14 “Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
»Zatorej glej, jaz jo bom privabil in jo pripeljal v divjino in ji tolažilno prigovarjal.
15 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
Jaz ji bom od tam dal njene vinograde in dolino Ahór za vrata upanja in ona bo tam prepevala kakor v dneh svoje mladosti in kakor na dan, ko je prišla gor iz egiptovske dežele.
16 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
In zgodilo se bo tisti dan, « govori Gospod, » da me boš klicala: ›Ishi‹ in ne boš me več klicala: ›Báali.‹
17 Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
Kajti odstranil bom imena Báalov iz njenih ust in po njihovem imenu se jih ne bodo več spominjali.
18 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
Na ta dan bom zanje sklenil zavezo s poljskimi živalmi, s perjadjo neba in s plazečimi stvarmi zemlje. Prelomil bom lok, meč in bitko z zemlje in storil jim bom, da se varno zleknejo.
19 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
In zaročil te bom k sebi za vedno. Da, zaročil te bom k sebi v pravičnosti, v sodbi, v ljubeči skrbnosti in v milostih.
20 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
Zaročil te bom k sebi, celo v zvestobi in spoznala boš Gospoda.
21 “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
Zgodilo se bo na tisti dan; uslišal bom, « govori Gospod, »uslišal bom nebo in to bo uslišalo zemljo
22 ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
in zemlja bo uslišala žito in vino in olje in ti bodo uslišali Jezreéla.
23 Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”
Posejal si jo bom na zemlji in usmilil se bom nje, ki ni dosegla usmiljenja in rekel bom tistim, ki niso bili moje ljudstvo: ›Vi ste moje ljudstvo.‹ In oni bodo rekli: › Ti si moj Bog.‹«

< Hosea 2 >