< Hosea 2 >

1 “Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
Зичець фрацилор воштри Ами ши сурорилор воастре Рухама!
2 “Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
Плынӂеци-вэ, плынӂеци-вэ ымпотрива мамей воастре! Кэч ну есте неваста Мя ши Еу ну сунт бэрбатул ей! Сэ-шь депэртезе курвииле динаинтя ей ши прякурвииле де ла цыцеле ей!
3 Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
Алтфел, о дезбрак ын пеля гоалэ, кум ера ын зиуа наштерий е, о фак ка ун пустиу, ка ун пэмынт ускат, ши о лас сэ моарэ де сете!
4 Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
Ну вой авя милэ де копиий ей, кэч сунт копий дин курвие.
5 Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
Мама лор а курвит; чя каре й-а нэскут с-а нечинстит, кэч а зис: ‘Вой алерга дупэ ибовничий мей, каре ымь дау пыня ши апа мя, лына ши инул меу, унтделемнул ши бэутуриле меле!’
6 Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
Де ачея, ятэ, ый вой аступа друмул ку спинь, и-л вой аступа ку ун зид, ка сэ ну-шь май афле кэрэриле.
7 Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
Ва алерга дупэ ибовничий ей, дар ну-й ва ажунӂе; ый ва кэута, дар ну-й ва гэси. Апой ва зиче: ‘Хай сэ мэ ынторк ярэшь ла бэрбатул меу чел динтый, кэч ерам май феричитэ атунч декыт акум!’
8 Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
Н-а куноскут кэ Еу ый дэдям грыул, мустул ши унтделемнул ши ау ынкинат службей луй Баал арӂинтул ши аурул чел мулт пе каре и-л дэдям.
9 “Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
Де ачея, Ымь вой луа ярэшь ынапой грыул ла время луй ши мустул ла время луй ши ымь вой ридика ярэшь де ла еа лына ши инул пе каре и ле дэдусем ка сэ-й акопере голичуня.
10 Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
Ши акум ый вой дескопери рушиня ынаинтя ибовничилор ей ши ничунул н-о ва скоате дин мына Мя.
11 Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
Вой фаче сэ ынчетезе тоатэ букурия ей, сэрбэториле ей, луниле ей челе ной, сабателе ей ши тоате празничеле ей.
12 Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
Ый вой пустии ши вииле ши смокиний, деспре каре зичя: ‘Ачаста есте плата пе каре мь-ау дат-о ибовничий мей!’ Ле вой префаче ынтр-о пэдуре ши ле вор мынка фяреле кымпулуй.
13 Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
О вой педепси пентру зилеле кынд тэмыя баалилор, кынд се гэтя ку верига де нас, ку салба ей, ши алерга дупэ ибовничий ей, уйтынд де Мине”, зиче Домнул.
14 “Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
„Де ачея, ятэ, о вой адемени ши о вой дуче ын пустиу ши-й вой ворби пе плакул инимий ей.
15 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
Аколо, ый вой да ярэшь вииле ши валя Акор й-о вой префаче ынтр-о ушэ де нэдежде ши аколо ва кынта ка ын время тинереций е ши ка ын зиуа кынд с-а суит дин цара Еӂиптулуй.
16 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
Ын зиуа ачея”, зиче Домнул, „Ымь вей зиче: ‘Бэрбатул меу’ ши ну-Мь вей май зиче: ‘Стэпынул меу’.
17 Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
Вой скоате дин гура ей нумеле баалилор, ка сэ ну май фие помениць пе нуме.
18 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
Ын зиуа ачея, вой ынкея пентру ей ун легэмынт ку фяреле кымпулуй, ку пэсэриле черулуй ши ку тырытоареле пэмынтулуй, вой сфэрыма дин царэ аркул, сабия ши орьче унялтэ де рэзбой ши-й вой фаче сэ локуяскэ ын линиште.
19 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
Те вой логоди ку Мине пентру тотдяуна; те вой логоди ку Мине прин неприхэнире, жудекатэ, маре бунэтате ши ындураре;
20 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
те вой логоди ку Мине прин крединчошие ши вей куноаште пе Домнул!
21 “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
Ын зиуа ачея, вой аскулта, зиче Домнул, вой аскулта черуриле, ши еле вор аскулта пэмынтул;
22 ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
пэмынтул ва аскулта грыул, мустул ши унтделемнул, ши ачестя вор аскулта пе Изреел.
23 Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”
Ымь вой сэди пе Ло-Рухама ын царэ ши-й вой да ындураре; вой зиче луй Ло-Ами: ‘Ту ешть попорул Меу!’ Ши ел ва рэспунде: ‘Думнезеул меу!’”

< Hosea 2 >