< Hosea 2 >

1 “Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
Spuneţi fraţilor voştri: Ami; şi surorilor voastre: Ruhama.
2 “Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
Certaţi-vă cu mama voastră, certaţi-vă [cu ea], căci ea nu este soţia mea, nici eu nu sunt soţul ei; de aceea să pună deoparte curviile ei dinaintea ochilor ei, şi faptele ei de adulter dintre sânii ei;
3 Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
Ca nu cumva să o dezbrac de tot şi să o pun ca în ziua în care s-a născut şi să o pustiesc şi să o pun ca pe un pământ uscat şi să o ucid de sete.
4 Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
Şi nu voi avea milă de copiii ei; fiindcă ei sunt copii ai curviilor.
5 Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
Fiindcă mama lor a făcut pe curva; cea care i-a conceput a făcut fapte ruşinoase, fiindcă a spus: Voi merge după iubiţii mei, care îmi dau pâinea mea şi apa mea, lâna mea şi inul meu, untdelemnul meu şi băutura mea.
6 Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
De aceea, iată, îţi voi îngrădi calea cu spini şi voi face un zid, ca ea să nu îşi poată găsi cărările.
7 Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
Şi îi va urmări pe iubiţii ei, dar nu îi va ajunge; şi îi va căuta, dar nu îi va găsi; atunci va spune: Voi merge şi mă voi întoarce la întâiul meu soţ, pentru că atunci îmi era mai bine decât acum.
8 Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
Fiindcă nu a cunoscut că eu îi dădeam grâne şi vin şi untdelemn şi îi înmulţeam argintul şi aurul, pe care ei le-au pregătit lui Baal.
9 “Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
De aceea mă voi întoarce şi voi lua grânele mele la timpul lor şi vinul meu la timpul lui, şi voi lua înapoi lâna mea şi inul meu, dat pentru a-i acoperi goliciunea.
10 Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
Şi acum îi voi descoperi desfrânarea ei înaintea ochilor iubiţilor ei, şi nimeni nu o va scăpa din mâna mea.
11 Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
Voi face de asemenea să înceteze toată bucuria ei, zilele ei de sărbătoare, lunile ei noi şi sabatele ei şi toate sărbătorile ei solemne.
12 Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
Şi voi distruge viile ei şi smochinii ei, despre care a spus: Acestea sunt răsplăţile mele pe care iubiţii mei mi le-au dat; şi le voi preface într-o pădure şi fiarele câmpului le vor mânca.
13 Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
Şi voi cerceta asupra ei zilele Baalilor, în care ea le ardea tămâie şi se împodobea cu cerceii ei şi cu bijuteriile ei şi mergea după iubiţii ei, iar pe mine m-a uitat, spune DOMNUL.
14 “Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
De aceea, iată, o voi ademeni şi o voi aduce în pustie şi voi vorbi cu mângâiere inimii ei.
15 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
Şi de acolo îi voi da viile ei şi valea Acor ca o uşă a speranţei; şi ea va cânta acolo, ca în zilele tinereţii ei şi ca în ziua când a urcat din ţara Egiptului.
16 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
Şi se va întâmpla în acea zi, spune DOMNUL, că, tu mă vei numi Işi, şi nu mă vei mai numi Baali.
17 Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
Fiindcă voi lua numele Baalilor din gura ei şi nu vor mai fi amintiţi după numele lor.
18 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
Şi în acea zi voi face un legământ pentru ei cu fiarele câmpului şi cu păsările cerului şi cu târâtoarele pământului; şi voi frânge arcul şi sabia şi bătălia de pe pământ şi le voi face să se culce în siguranţă.
19 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
Şi te voi logodi cu mine pentru totdeauna; da, te voi logodi cu mine în dreptate şi în judecată şi în bunătate iubitoare şi în îndurări.
20 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
Chiar în credincioşie te voi logodi cu mine; şi tu vei cunoaşte pe DOMNUL.
21 “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
Şi se va întâmpla în acea zi că, voi asculta, spune DOMNUL, voi asculta cerurile, şi ele vor asculta pământul;
22 ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
Şi pământul va asculta grânele şi vinul şi untdelemnul; şi acestea vor asculta pe Izreel.
23 Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”
Şi o voi semăna pentru mine pe pământ; şi voi avea milă de cea care nu a obţinut milă; şi voi spune celor care nu erau poporul meu: Tu eşti poporul meu; iar ei vor spune: Tu eşti Dumnezeul meu.

< Hosea 2 >