< Hosea 2 >
1 “Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
Khulumani kubafowenu lithi: Ami; lakubodadewenu lithi: Ruhama.
2 “Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
Phikisanani lonyoko, liphikise, ngoba kasuye umkami, lami kangisiyo indoda yakhe, ukuthi asuse ukuwula kwakhe phambi kwami, lokufeba kwakhe ngaphakathi kwamabele akhe,
3 Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
hlezi ngimhlubule abe nqunu, ngimbeke abe njengosukwini lokuzalwa kwakhe, ngimenze afanane lenkangala, ngimbeke njengelizwe elomileyo, ngimbulale ngokoma.
4 Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
Labantwana bakhe kangiyikubahawukela, ngoba bangabantwana bobufebe.
5 Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
Ngoba unina uwulile, owabazalayo wenzile ihlazo; ngoba wathi: Ngizazilandela izithandwa zami, ezingipha ukudla kwami, lamanzi ami, uboya bezimvu bami, lefilakisi yami, amafutha ami, lokunathwayo kwami.
6 Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
Ngakho, khangela, ngizabiya indlela yakho ngameva, ngimakhele umduli ukuze angatholi imikhondo yakhe.
7 Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
Alandele izithandwa zakhe, kodwa angazifici; uzazidinga, kodwa angazitholi. Abesesithi: Ngizahamba ngibuyele endodeni yami yokuqala, ngoba kwakungcono kimi ngalesosikhathi kulakhathesi.
8 Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
Ngoba wayengazi ukuthi mina ngamnika amabele, lewayini elitsha, lamafutha, ngamandisela isiliva legolide, abalisebenzisela uBhali.
9 “Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
Ngakho ngizabuyela, ngithathe amabele ami ngesikhathi sawo, lewayini lami elitsha ngesikhathi salo esimisiweyo, ngihluthune uboya bezimvu bami lefilakisi yami okwembesa ubunqunu bakhe.
10 Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
Khathesi sengizakwambula ihlazo lakhe emehlweni ezithandwa zakhe, njalo kungabi khona omophulayo esandleni sami.
11 Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
Sengizaqeda intokozo yakhe yonke, amadili akhe, ukuthwasa kwenyanga zakhe, lamasabatha akhe, lemikhosi yakhe yonke emisiweyo.
12 Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
Sengizachitha ivini lakhe lomkhiwa wakhe, atsho ngakho ukuthi: Lokhu kungumvuzo wobuwule bami izithandwa zami ezinginike khona; kodwa ngizakwenza kube ligusu, ukuze inyamazana zeganga zikudle.
13 Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
Njalo ngizaphindisela phezu kwakhe insuku zaboBhali, ayebatshisela ngazo impepha, ezicecisa ngamasongo akhe langamangqongqo akhe, walandela izithandwa zakhe, kodwa wangikhohlwa, itsho iNkosi.
14 “Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
Ngakho, khangela, ngizamhuga, ngimuse enkangala, ngikhulume enhliziyweni yakhe.
15 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
Ngibe sengimnika izivini zakhe kusukela lapho, lesihotsha seAkori, sibe ngumnyango wethemba. Njalo uzahlabela lapho njengensukwini zobutsha bakhe, lanjengosuku lokwenyuka kwakhe elizweni leGibhithe.
16 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
Kuzakuthi ngalolosuku, itsho iNkosi, ungibize uthi: Ndoda yami; ungabe usangibiza ngokuthi: Bhali wami.
17 Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
Ngoba ngizasusa amabizo aboBhali emlonyeni wakhe, bangabe besakhunjulwa futhi ngebizo labo.
18 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
Langalolosuku ngizabenzela isivumelwano lenyamazana zeganga lenyoni zamazulu lezinto ezihuquzelayo zomhlaba; ngephule idandili, lenkemba, lempi kusuke emhlabeni, ngibalalise phansi bevikelekile.
19 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
Njalo ngizakugana ube ngowami kuze kube phakade, yebo, ngikugane ube ngowami ngokulunga langesahlulelo langothandolomusa langezihawu.
20 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
Yebo, ngizakugana ube ngowami ngothembeko; njalo uzayazi iNkosi.
21 “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
Kuzakuthi ngalolosuku, ngizaphendula, itsho iNkosi, ngizaphendula amazulu, wona aphendule umhlaba,
22 ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
lomhlaba uphendule amabele lewayini elitsha lamafutha, khona kuphendule uJizereyeli.
23 Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”
Besengizihlanyelela yena emhlabeni, ngibe lomusa phezu kongazuzanga umusa, ngithi kwababengasibantu bami: Lina lingabantu bami; bona bathi: Nkulunkulu wami.