< Hosea 2 >

1 “Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
Mondjátok atyátokfiainak: Ammi! és a ti húgaitoknak: Rukhámáh!
2 “Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
Pereljetek anyátokkal, pereljetek (mert nem feleségem ő, és én sem vagyok néki férje), hogy tüntesse el az ő bujaságát arczáról, és az ő paráznaságát emlői közül;
3 Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
Különben meztelenre vetkőztetem őt és olyanná teszem, a milyen volt születése napján, és a pusztához teszem hasonlatossá, és olyanná változtatom őt, a milyen a kiaszott föld, és megölöm őt szomjúsággal.
4 Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
Sőt fiain sem könyörülök, mert paráznaságnak fiai ők is.
5 Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
Mert paráználkodott az ő anyjok; gyalázatba merült, a ki őket szülte; mert ezt mondotta: Elmegyek szeretőim után, a kik megadják kenyeremet, vizemet, gyapjúmat és lenemet, olajomat és italomat.
6 Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
Azért ímé tövissel rekesztem el útadat, és sövényt fonok eleibe, hogy ne találja meg ösvényeit.
7 Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
És szaladgál majd szeretői után, de nem éri el őket; és mikor keresi őket és nem találja meg azokat, azt mondja majd: Elmegyek hát és visszatérek előbbi férjemhez: mert jobb dolgom volt akkor, hogynem mint mostan:
8 Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
Mert nem vette eszébe, hogy én adtam néki a búzát, a mustot és az olajat, és én sokasítottam meg ezüstjét és az aranyat, a mit ők a Baálra költöttek.
9 “Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
Azért visszaveszem búzámat a maga idejében és mustomat is az ő divatjában, és elragadom gyapjúmat és lenemet, a melyek meztelensége befedésére lettek volna.
10 Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
És most feltárom az ő gyalázatát szeretői előtt, és senki sem szabadítja őt ki az én kezemből.
11 Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
És megszüntetem minden örömét, ünnepét, újholdját, szombatját és minden ünnepe napját.
12 Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
És elpusztítom szőlejét és fügefáját, a melyekről ezt mondta: Ez az én bérem, a mit az én szeretőim adtak nékem, és erdővé teszem azokat, és a mezei vad emészti meg őket.
13 Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
És megbüntetem őt a Baálok napjaiért, a melyeken füstölve áldozott azoknak, és felrakta gyűrűjét és nyaklánczát, és elment szeretői után, rólam pedig elfeledkezett, ezt mondja az Úr.
14 “Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
Azért ímé csalogatom őt, és elviszem őt a pusztába, és szívére beszélek.
15 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
És onnan adom meg néki az ő szőlőjét és az Akor völgyét a reménység ajtaja gyanánt, és úgy énekel ott, mint ifjúságának idején és mint Égyiptomból lett feljövetelének napján.
16 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
És azon a napon, ezt mondja az Úr, így fogsz engem hívni: Én férjem, és nem hívsz engem többé így: Baálom.
17 Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
És kiveszítem az ő szájából a Baálok neveit, hogy azoknak neve se említtessék többé.
18 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
És azon a napon frigyet szerzek nékik a mezei vadakkal, az égi madarakkal és a föld férgével, és az ívet, kardot és háborút eltörlöm e földről, és bátorságos lakozást adok nékik.
19 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
És eljegyezlek téged magamnak örökre, és pedig igazsággal és ítélettel, kegyelemmel és irgalommal jegyezlek el.
20 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
Bizony, hittel jegyezlek el téged magamnak, és megismered az Urat.
21 “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
És azon a napon meghallgatom, azt mondja az Úr, meghallgatom az egeket, azok pedig meghallgatják a földet;
22 ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
A föld pedig meghallgatja a búzát és a mustot és az olajat; azok pedig meghallgatják Jezréelt.
23 Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”
És bevetem őt magamnak a földbe, és megkegyelmezek Ló-Rukhámának, és azt mondom Ló-Amminak: Én népem vagy te; ő pedig ezt mondja: Én Istenem!

< Hosea 2 >