< Hosea 2 >
1 “Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
Dites à votre frère, Mon-Peuple, et à votre sœur Pitié:
2 “Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
Plaidez contre votre mère; car elle n'est point Ma femme, et Je ne suis point son Mari. Et J'ôterai de devant Ma face sa prostitution, et son adultère du milieu de ses mamelles,
3 Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
afin de la mettre nue, et de la remettre comme elle était le jour de sa naissance; et Je ferai d'elle un désert, et Je la traiterai comme une terre aride; et Je la tuerai par la soif;
4 Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
et Je n'aurai point pitié de ses enfants; car ce sont des enfants de prostitution.
5 Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
Leur mère s'est prostituée; celle qui les a portés les a couverts de honte; elle a dit: Je m'en irai après mes amants qui me donnent mon pain, et mon eau, et mes vêtements, et mon linge, et mon huile, et tout ce qui m'est nécessaire.
6 Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
C'est pourquoi Je ferme sa voie avec des épines, et Je bâtirai sur ses routes; elle ne retrouvera plus son sentier.
7 Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
Elle poursuivra ses amants, et ne les atteindra pas; elle les cherchera, et ne les trouvera pas; Et elle dira: Je vais partir, je vais retourner auprès de mon premier mari; car, pour moi, il faisait meilleur alors que maintenant.
8 Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
Et elle n'a point connu que Je lui avais donné du pain, du vin et de l'huile, et que Je l'avais comblée d'argent, et elle a fait à Baal des idoles d'argent et d'or.
9 “Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
À cause de cela, Je M'en retournerai, Je prendrai Mon blé lors de la moisson, et Mon vin lors de la vendange; et Je reprendrai Mes vêtements et Mon linge, pour ne plus couvrir sa nudité.
10 Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
Et désormais Je révélerai à ses amants son impureté, et nul ne la délivrera de Mes mains.
11 Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
Et Je supprimerai toutes ses joies, toutes ses fêtes, toutes ses nouvelles lunes, ses sabbats et toutes ses solennités.
12 Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
Et Je détruirai sa vigne et ses figuiers, parce qu'elle a dit: Ce sont les salaires que m'ont donné mes amants. Et Moi, J'en ferai un témoignage; les bêtes des champs viendront y paître, et les oiseaux du ciel, et les reptiles de la terre.
13 Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
Je lui ferai expier les jours où elle a sacrifié à Baal, et où elle a mis ses pendants d'oreilles et ses colliers pour s'en aller après son amant. Et elle M'a oublié, dit le Seigneur.
14 “Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
C'est pourquoi Je l'égarerai et Je l'enverrai dans le désert, et je parlerai à son cœur.
15 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
Et de là Je lui rendrai ses possessions et la vallée d'Achor, pour lui ouvrir l'intelligence. Et là elle s'humiliera autant de jours qu'a duré sa jeunesse, et autant de jours qu'elle a mis à revenir de la terre d'Égypte.
16 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
Et ceci arrivera en ce jour-là, dit le Seigneur; elle M'appellera Mon époux, et elle ne M'appellera plus Baal.
17 Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
Et J'ôterai de sa bouche les noms de Baal, et l'on ne s'en souviendra plus.
18 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
Et en ce jour-là J'établirai une alliance entre eux et les bêtes sauvages, et les oiseaux du ciel, et les reptiles de la terre; et Je briserai sur la terre l'arc, le glaive et les armes de guerre, et Je t'y installerai avec l'espérance.
19 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
Et Je te prendrai pour épouse dans tous les siècles, et Je te prendrai pour épouse en Mon équité, en Mes jugements, en Ma pitié, en Ma miséricorde.
20 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
Et Je te prendrai pour épouse avec confiance, et tu reconnaîtras le Seigneur.
21 “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
Et il arrivera en ce jour-là, dit le Seigneur, que J'exaucerai le ciel, et le ciel exaucera la terre.
22 ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
Et la terre exaucera le blé, et le vin, et l'huile, et toutes ces choses exauceront Jezraël.
23 Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”
Et Je la sèmerai pour moi sur la terre, et J'aimerai celle que Je n'aimais pas. Et Je dirai à Non-Mon-Peuple: Tu es Mon peuple; et il dira: Tu es le Seigneur mon Dieu.