< Hosea 2 >

1 “Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
Sanokaat teidän veljillenne: He ovat minun kansani, ja teidän sisarillenne: He ovat armossa.
2 “Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
Riidelkäät teidän äitinne kanssa, riidelkäät, sillä ei hän ole minun emäntäni, enkä minä ole hänen miehensä, että hän heittäis pois haureutensa kasvoistansa ja huoruutensa rinnoistansa:
3 Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
Etten minä häntä alasti riisuisi, ja panisi häntä niinkuin hän syntyissänsä oli, ja panisi myös häntä niinkuin hävitettyä ja niinkuin karkiaa maata, enkä janoon häntä kuolettaisi;
4 Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
Ja en armahtaisi hänen lapsiansa; sillä he ovat huoran lapset.
5 Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
Sillä heidän äitinsä on huorin tehnyt, ja se, joka heidät siitti, käytti itsensä häpiällisesti, ja sanoi: Minä tahdon juosta rakastajaini perässä, jotka minulle antavat leipää, vettä, villoja, pellavia, öljyä ja juomaa.
6 Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
Sentähden katso, minä aitaan sinun ties orjantappuroilla ja panen aidan eteen, ettei hän löytäisi polkujansa.
7 Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
Ja kuin hän juoksee rakastajainsa perässä, niin ei hänen pidä heitä käsittämän, eikä löytämän, kuin hän heitä etsii; ja hänen pitää sanoman: Minä menen ja palajan entisen mieheni tykö, sillä silloin oli minun parempi kuin nyt.
8 Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
Ja ei hän tahdo tietää minua siksi, joka hänelle annoin jyviä, viinaa ja öljyä, ja että minä annoin hänelle paljon hopiaa ja kultaa, josta he Baalimit tekivät.
9 “Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
Sentähden minä palajan ja otan aikanansa jälleen minun jyväni, ja minun viinani ajallansa, ja otan pois villani ja pellavani, joilla hän häpiänsä peittää.
10 Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
Ja minä tahdon paljastaa hänen häpiänsä, hänen rakastajainsa silmäin eteen; ja ei pidä kenenkään häntä minun käsistäni päästämän.
11 Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
Ja minä lakkautan kaiken hänen ilonsa, juhlansa, uuden kuunsa, lepopäivänsä ja kaikki hänen pyhäpäivänsä.
12 Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
Minä hävitän myös hänen viinapuunsa ja fikunapuunsa, että hän sanoi: Se on minun palkkani, jonka minun rakastajani minulle antaneet ovat; minä teen niistä metsän, että metsän pedot ne syövät.
13 Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
Juuri niin etsin minä häntä Baalimin päivinä, joina hän heille savu-uhria sytytti, ja kaunisti itsensä kultalehdillä ja kaulakaunistuksella, ja juoksi rakastajainsa perässä; ja niin unhotti minun, sanoo Herra.
14 “Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
Sentähden katso, minä tahdon häntä houkutella, viedä hänen korpeen ja puhua suloisesti hänen kanssansa.
15 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
Silloin annan minä hänelle hänen viinamäkensä ja Akorin laakson, ja tahdon toivon avata; siellä hän on lauleskeleva, niinkuin nuorella ijällänsä ja niinkuin sinä päivänä, jona hän Egyptin maalta läksi.
16 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
Ja sinä päivänä pitää tapahtuman, sanoo Herra, ettäs minun kutsut miehekses, ja et enään minua kutsu Baalimiksi.
17 Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
Sillä minä tahdon Baalimin nimet ottaa pois hänen suustansa, niin ettei kenenkään pidä sitä nimeä enään muistaman.
18 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
Vaan minä tahdon tehdä heille sillä ajalla liiton, petoin kanssa kedolla, lintuin kanssa taivaan alla ja matoin kanssa maan päällä; ja tahdon ottaa pois joutsen, miekan ja sodan maalta, ja annan heidän asua turvallisesti.
19 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
Minä kihlaan sinun itselleni ijankaikkisesti; ja minä kihlaan sinun itselleni vanhurskaudessa, tuomiossa, armossa ja laupiudessa.
20 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
Minä kihlaan tosin sinun itselleni uskossa, ja sinun pitää Herran tunteman.
21 “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
Sillä ajalla, sanoo Herra; tahdon minä kuulla, minä tahdon taivaasta kuulla, ja taivaan pitää maata kuuleman.
22 ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
Mutta maan pitää kuuleman jyviä, viinaa ja öljyä, ja niiden pitää Jisreeliä kuuleman.
23 Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”
Ja minä tahdon sen itselleni pitää siemeneksi maan päälle, ja tahdon sitä armahtaa, jota ei ole armahdettu. Ja sanon hänelle, joka ei ollut minun kansani: Sinä olet minun kansani, ja hänen pitää sanoman: Sinä olet minun Jumalani.

< Hosea 2 >