< Hosea 2 >
1 “Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
“Luonguru oweteu ni ‘Joga,’ kendo luonguru nyimineu ni ‘Joma ahero.’”
2 “Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
“Kwer minu, kwere, nikech ok en jaoda, kendo ok an chwore. Onego owe wangʼ maneno mar chode kendo gi yorene mag dwanyruok.
3 Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
Ka ok kamano to abiro lonye duk modongʼ kaka ne onywole; anakete ochal kaka lop ongoro, analoke kaka lowo motwo mobaro okak, kendo ananege kod riyo mar pi.
4 Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
Ok anaher nyithinde, nikech gin nyithindo mane oyud e yor chode.
5 Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
Min-gi ok osebedo ja-ratiro kendo osemako ich gi anjawo. Owacho ni, ‘Abiro luwo bangʼ joherana, mamiya chiemba kod piga, yie rombe gi pamba michweyogo lewni, mo kod math.’
6 Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
Omiyo anagengʼ yore kod bungu maduongʼ mar kudho; abiro dinone chuth ma ok noyud yo mowuok godo oko.
7 Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
Enolaw bangʼ jochodenego to ok nomakgi; enomanygi to ok noyudgi. Bangʼe to enowachi niya, Abiro dokne chwora mokwongo, nimar ndalono ne awinjo maber moloyo sani.
8 Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
Ok osengʼeyo adier ni an ema ne amiye cham, divai manyien kod mo, an bende ema ne adhiale gi fedha gi dhahabu mangʼenygo mane gitiyo nego Baal.
9 “Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
“Kuom mano abiro kawo chamba ka osechiek, gi divaina manyien ka oseikore. Bende anakaw yie rombona gi pambana mitwangʼo godo lewni mane onego oum-go duge.
10 Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
Koro abiro nyiso ayanga gombo mare mar chode e lela e nyim joherane; kendo onge ngʼama nogole e lweta.
11 Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
Nyasi duto ma en-go anakethi: nyasi mar higa ka higa, mar dwe ka dwe, mar Sabato kod nyasi motimo juma ka juma.
12 Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
Anaketh yiendene mag mzabibu gi yiend ngʼopene mane owacho ni ne chudone moa kuom joherane. Abiro ketogi bunge, kendo le mag bungu nokethgi.”
13 Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
Jehova Nyasaye wacho niya, “Anakume kuom ndalo duto mane owangʼo ubani ne Baal; korwakore gi gik mabeyo ahinya kolombogo joherane, to an ne wiye owil koda.
14 “Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
“Kuom mano abiro hoye, mi adhi kode e piny motimo ongoro, kendo abiro wuoyo kode gi muolo.
15 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
Kanyo abiro dwokone puothe mar mzabibu, Kendo analos holo mar Akor obed dhood geno. Kanyo nowerie mana kaka nower kapod otin, mana ka chiengʼ mane owuok koa Misri.”
16 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
Jehova Nyasaye owacho niya, “Odiechiengʼno iniluonga ni ‘chwora,’ to ok inichak iluonga ni ‘jatenda.’
17 Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
Abiro golo nyinge mag Baal oa e dhoge. Nying Baal ok nochak owuo kuomgi kendo.
18 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
Chiengʼno anaketnegi singruok e kindgi gi le mag thim gi winy manie kor polo, gi chwech mamol e lowo, atungʼ gi ligangla to abiro turo, kendo lweny bende anatiek e piny, mondo gik moko duto obed gi kwe.
19 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
Abiro timo kodi singruok mar kend mondo ibed mara chuth; abiro timo kodi singruok mar kend e yo maler kendo maratiro, gihera kod kech.
20 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
Abiro timo kodi singruok mar kend e yo mar adiera, kendo ibiro yie kuom Jehova Nyasaye.”
21 “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
Jehova Nyasaye wacho niya, “E odiechiengno abiro dwoko kwayou ma boche polo, nochiw koth ne piny,
22 ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
kendo cham biro nyak e piny, kaachiel gi divai manyien kod mo zeituni, mi giduto ginyag Jezreel.
23 Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”
Abiro pidhe e piny ne an awuon; abiro nyiso herana ni ngʼat mane aluongo ni ‘Ok jaherana.’ Anawach ni joma iluongo ni, ‘Joma ok joga,’ ni, ‘Un joga’; kendo ginidwoka ni, ‘In Nyasachwa.’”