< Hosea 2 >

1 “Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
Nangmacae ih namyanawk khaeah, Ammi (kai ih kami), tiah thui oh loe, na tanuhnawk khaeah, Ruhamah (palungnathaih amtuengsak), tiah thui oh.
2 “Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
Nam no to thuitaek ah, zoeh ah; anih loe kai ih zu na ai ni, kai doeh anih ih sava na ai ni. A mikhmai hoi tangzat zawh han khethaih to va ving nasoe loe, anih ih tahnu salak hoiah zae sakhaih to va ving lai nasoe;
3 Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
to tih ai nahaeloe bangkrai ah oh hanah anih to khukbuen ka khring pae moe, tapenhaih ni nathuem ih baktih toengah, bangkrai ah ka ohsak han, anih to praezaek baktiah ka sak moe, long karoem baktiah ka suem ueloe, tui anghaehhaih hoiah ka duehsak moeng tih.
4 Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
Nihcae loe tangzat zaw kami ih caa ah oh o pongah, a caanawk nuiah tahmenhaih ka tawn mak ai.
5 Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
Anih mah, Kai han buh hoi tui paek kami, tuumui hoi puu ngan khukbuen paekkung, situi hoi naek koi paek kami ah kaom, kaimah ih tlangainawk hnuk ah ka caeh han, tiah a thuih. Nihcae ih amno loe tangzat to zawh moe, azat koi kaom ah khosakhaih hoiah ni nihcae a pomh.
6 Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
To pongah khenah, Na caehhaih loklam to soekhring hoiah ka pakaa khoep moe, sipae kang thungh pae khoep han, to naah loe anih mah caehhaih loklam to hnu mak ai boeh.
7 Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
Anih mah angmah ih tlangainawk to patom tih, toe kae mak ai; anih mah nihcae to pakrong tih, toe hnu mak ai. To naah anih mah, Ka caeh moe, hmaloe ih ka sava khaeah kam laem let han, to tiah ni vaihi pongah khosak ka hoih kue tih, tiah thui tih.
8 Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
Kai mah ni anih hanah cang, misurtui hoi situinawk to ka paek, nihcae mah Baal han patoh o ih sui hoi sum kanglung doeh kai mah ni ka paek, tiah anih mah panoek ai.
9 “Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
To pongah kam laem moe, atue mah phak naah kaimah ih cang hoi misurtui to ka lak pae ving han; anih bangkrai ah ohhaih to khuk hanah, ka paek ih kaimah ih tuumui hoi puu ngan khukbuen doeh ka lak pae let han.
10 Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
To pongah vaihi anih ih tlangainawk mikhnuk ah, anih azathaih to kam tuengsak han, mi mah doeh kai ih ban thung hoiah anih to loih o sak thai mak ai.
11 Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
Anih ih poihsakhaih, poihsakhaih ninawk, khrah kangthanawk, Sabbath ninawk hoi kalah amkhuenghaih poihnawk boih doeh ka boengsak han.
12 Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
Anih mah, Hae loe ka tlangainawk mah tha pathokhaih atho ah paek ih hmuen ah oh, tiah thuih ih angmah ih misurkung hoi thaiduetkungnawk to kam rosak han: to ahmuen to taw ah kang coengsak moe, moisannawk to ka caaksak han.
13 Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
Baalnawk khaeah hmuihoih a thlaekhaih aninawk pongah, anih to ka thuitaek han. Anih loe bantuek, naa tangkraeng, atho kana hmuen hoiah amthoep moe, angmah ih tlangainawk hnuk ah a caeh, kai ang pahnawt sut boeh, tiah Angraeng mah thuih.
14 “Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
To pongah khenah, anih to ka zoek moe, praezaek ah ka caeh haih pacoengah, lok kanaem ka thuih pae han.
15 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
To ah anih han misur takhanawk to ka paek let moe, Akhor Azawn to oephaih khongkha ah ka sak pae han; nawkta nathuem ih baktih, Izip prae hoi angzohhaih ni thuem ih baktih toengah, anih mah to ahmuen ah laa to sah tih boeh.
16 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
To na niah loe, Nang mah, Baali (ka angraeng), tiah nang kawk mak ai, Ishi (ka sava), tiah ni nang kawk tih boeh.
17 Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
Baal ih ahminnawk to anih ih pahni hoiah ka lak pae ving han, nihcae ih ahminnawk panoek lethaih om mak ai boeh.
18 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
To na niah loe moisannawk, van ih tavaanawk, long ah kavak hmuennawk hoiah misa angcoeng han ai ah, nihcae han lokmaihaih ka sak pae han. Nihcae kamding rue ah ohsak hanah, misatukhaih kalii hoi sumsen to long nui hoiah kam rosak han.
19 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
Nang loe kaimah khaeah kang suek poe han, ue, toenghaih hoi kamsoem ah lokcaekhaih, tahmenhaih hoi amlunghaih baktiah, nang to kaimah khaeah kang suek poe han boeh.
20 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
Oepthohhaih hoiah kaimah khaeah kang suek poe han: to naah loe Angraeng to na panoek tih boeh.
21 “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
To na niah loe na lok kang tahngaih pae han, vannawk ih lok to ka tahngaih pae han, nihcae mah doeh long ih lok to tahngai o toeng tih.
22 ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
Long mah, cang, misurtui hoi situi ih lok to tahngai pae ueloe, nihcae mah doeh Jezreel ih lok to tahngai pae o tih.
23 Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”
To pacoengah anih to kaimah hanah long ah ka patit moe, palungnathaih tawn ai kami nuiah palungnathaih to kam tuengsak han; Kai ih kami ah kaom ai kami khaeah, Nangcae loe Kai ih kami ah na oh o, tiah ka naa han; to naah nihcae mah, Nang loe ka Sithaw ni, tiah thui o tih boeh, tiah Angraeng mah thuih.

< Hosea 2 >