< Hosea 14 >

1 Yípadà ìwọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ló fa ìparun rẹ!
Izraelu, nawróć się całkowicie do PANA, swego Boga. Upadłeś bowiem z powodu swojej nieprawości.
2 Ẹ gba ọ̀rọ̀ Olúwa gbọ́, kí ẹ sì yípadà sí Olúwa. Ẹ sọ fún un pé, “Darí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá kí o sì fi oore-ọ̀fẹ́ gbà wá, kí àwa kí ó lè fi ètè wa sán an fún ọ
Weźcie ze sobą słowa i zawróćcie do PANA. Mówcie do niego: Przebacz całą naszą nieprawość i daj to, co dobre, wtedy oddamy ci cielce naszych warg.
3 Asiria kò le gbà wá là; a kò ní í gorí ẹṣin ogun. A kò sì ní tún sọ ọ́ mọ́ láé, ‘Àwọn ni òrìṣà wa’ sí àwọn ohun tí ó fi ọwọ́ wa ṣe; nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni àwọn aláìní baba tí ń rí àánú.”
Asyria nas nie wybawi, nie będziemy jeździć na koniach i nie będziemy już mówili do dzieł naszych rąk: [Wy jesteście] naszymi bogami. W tobie bowiem sierota znajduje miłosierdzie.
4 “Èmi wo àgàbàgebè wọn sàn, Èmi ó sì fẹ́ràn wọn, lọ́fẹ̀ẹ́, nítorí ìbínú mi ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Uzdrowię ich odstępstwo i umiłuję ich dobrowolnie, bo mój gniew odwrócił się od nich.
5 Èmi o dàbí ìrì sí Israẹli, wọn o sì yọ ìtànná bi ewéko lílì. Bi kedari ti Lebanoni yóò si ta gbòǹgbò.
Będę dla Izraela jak rosa, [tak] że rozkwitnie jak lilia i zapuści korzenie jak Liban.
6 Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ẹ̀ka rẹ̀ yóò dàgbà, dídán ẹwà yóò rẹ̀ dànù bí igi olifi. Òórùn rẹ yóò sì dàbí igi kedari ti Lebanoni.
Jego gałęzie rozrosną się i jego piękno będzie jak drzewo oliwne, a jego woń jak Liban.
7 Àwọn ènìyàn yóò tún padà gbé lábẹ́ òjijì rẹ̀. Yóò rúwé bi ọkà. Yóò sì yọ ìtànná bi àjàrà, òórùn rẹ yóò dàbí ti wáìnì Lebanoni.
Wrócą, aby siedzieć pod jego cieniem, ożyją [jak] zboże i rozkwitną jak winorośl, ich sława będzie jak wino Libanu.
8 Ìwọ Efraimu, kín ló tún kù tí mo ní ṣe pẹ̀lú ère òrìṣà? Èmi ó dá a lóhùn, èmi ó sì ṣe ìtọ́jú rẹ. Mo dàbí igi junifa tó ń fi gbogbo ìgbà tutù, èso tí ìwọ ń so si ń wá láti ọ̀dọ̀ mi.”
Efraim [powie]: Cóż mi już do bożków? Ja [cię] wysłucham i wejrzę na ciebie. Ja jestem jak zielona jodła, ode mnie pochodzi twój owoc.
9 Ta ni ọlọ́gbọ́n? Òun yóò mòye àwọn nǹkan wọ̀nyí. Ta a ní ó mọ̀? Òun yóò ní ìmọ̀ wọn. Títọ́ ni ọ̀nà Olúwa àwọn olódodo si ń rìn nínú wọn, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ni yóò kọsẹ̀ nínú wọn.
Kto mądry, niech to zrozumie, a [kto] roztropny, niech to pozna. Drogi PANA bowiem [są] proste; sprawiedliwi po nich będą chodzić, ale przestępcy na nich upadną.

< Hosea 14 >