< Hosea 13 >

1 Nígbà ti Efraimu bá ń sọ̀rọ̀, àwọn ènìyàn máa ń wárìrì, a gbé e ga ní Israẹli ṣùgbọ́n ó jẹ̀bi ẹ̀sùn pé ó ń sin òrìṣà Baali, ó sì kú.
Când Efraim a vorbit tremurând, el s-a înălţat în Israel; dar când s-a făcut vinovat prin Baal, a murit.
2 Báyìí, wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀; wọn fi fàdákà ṣe ère òrìṣà fúnra wọn; ère tí a fi ọgbọ́n dá àrà sí, gbogbo wọn jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ oníṣọ̀nà. Wọn ń sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Pé, “Jẹ́ kí àwọn ènìyàn tí ń rú ẹbọ fi ẹnu, ko àwọn ẹgbọrọ màlúù ni ẹnu.”
Şi acum ei păcătuiesc tot mai mult, şi şi-au făcut imagini turnate din argintul lor şi idoli conform cu propria lor înţelegere, toate acestea fiind lucrarea meşteşugarilor; ei spun despre ele: Oamenii care sacrifică să sărute vițeii.
3 Nítorí náà wọn yóò dàbí ìkùùkuu òwúrọ̀, bí ìrì òwúrọ̀ kùtùkùtù tó máa ń parẹ́, bí i èèpo ìyẹ̀fun tí afẹ́fẹ́ gbé láti ibi ìpakà bí èéfín tó rú jáde gba ojú fèrèsé.
De aceea vor fi ca norul de dimineaţă şi ca roua dimineţii care trece repede, ca pleava care este împinsă din arie de vârtejul de vânt şi ca fumul din horn.
4 “Ṣùgbọ́n Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ẹni tó mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá. Ìwọ̀ kì yóò sì mọ ọlọ́run mìíràn àfi èmi kò sí olùgbàlà mìíràn lẹ́yìn mi.
Totuşi eu sunt DOMNUL Dumnezeul tău din ţara Egiptului şi tu nu vei cunoaşte alt dumnezeu decât pe mine; fiindcă nu este salvator în afară de mine.
5 Mo ṣe ìtọ́jú rẹ ní aginjù, ní ilẹ̀ tí ó gbẹ tí kò ní omi.
Eu te-am cunoscut în pustie, în ţara cu secetă mare.
6 Wọn ni ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí mo fún wọn ní oúnjẹ, Nígbà tí wọ́n ní ìtẹ́lọ́rùn tan wọ́n di agbéraga. Nígbà náà ni wọ́n sì gbàgbé mi.
După păşunea lor, s-au săturat; au fost săturaţi şi inima li s-a înălţat; de aceea m-au uitat.
7 Nítorí náà, Èmi yóò dìde sí wọn bí i kìnnìún, Èmi yóò fi ara pamọ́ dè wọ́n lọ́nà bí i ẹkùn.
De aceea voi fi pentru ei ca un leu, îi voi privi ca un leopard lângă cale,
8 Beari igbó tí a já ọmọ rẹ̀ gbà, Èmi yóò bá wọn jà bí? Èmi yóò sì fà wọ́n ya bí ìgbà tí ẹkùn bá fa ara wọn ya bi ẹranko búburú ni èmi yóò fa wọn ya.
Îi voi întâmpina ca o ursoaică lipsită de puii ei şi voi sfâşia învelitoarea inimii lor, şi acolo, ca un leu, îi voi mânca; fiara sălbatică îi va sfâşia.
9 “A ti pa ọ́ run, ìwọ Israẹli, nítorí pé ìwọ lòdì sí mi, ìwọ lòdì sí olùrànlọ́wọ́ rẹ.
Israele, tu te-ai nimicit pe tine însuţi; dar în mine este ajutorul tău.
10 Níbo ni ọba rẹ gbé wà nísinsin yìí kí ó bá à le gbà ọ là? Níbo ni àwọn olórí ìlú yín wà, àwọn tí ẹ sọ pé, ‘Fún wa ní ọba àti ọmọ-aládé’?
Eu voi fi împăratul tău, unde este vreun altul care să te salveze în toate cetăţile tale? Şi judecătorii tăi despre care ai spus: Dă-mi un împărat şi prinţi?
11 Nítorí èyí nínú ìbínú mi ni mo fún un yín ní ọba, nínú ìbínú gbígbóná mi, mo sì mú un kúrò.
Ţi-am dat un împărat în mânia mea şi l-am luat în furia mea.
12 Ẹ̀bi Efraimu ni a tí ko jọ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ wà nínú àkọsílẹ̀.
Nelegiuirea lui Efraim este legată; păcatul lui este ascuns.
13 Ìrora bí obìnrin tó fẹ́ bímọ ti dé bá a, ṣùgbọ́n ó jẹ́ ọmọ tí kò lọ́gbọ́n, nígbà tí àsìkò tó, ó kọ̀ láti jáde síta láti inú.
Întristările unei femei în travaliu vor veni peste el; el este un fiu neînţelept; fiindcă nu ar trebui să stea mult în locul naşterii copiilor.
14 “Èmi yóò rà wọ́n padà kúrò lọ́wọ́ agbára isà òkú. Èmi yóò rà wọ́n padà lọ́wọ́ ikú, ikú, àjàkálẹ̀-ààrùn rẹ dà? Isà òkú, ìparun rẹ dà? “Èmi kò ní ṣàánú mọ́. (Sheol h7585)
Îi voi răscumpăra din puterea mormântului, îi voi răscumpăra din moarte. Moarte, eu voi fi plăgile tale; mormântule, voi fi nimicirea ta; pocăinţa va fi ascunsă de ochii mei. (Sheol h7585)
15 Bí ó tilẹ̀ gbilẹ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀ afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀dọ̀ Olúwa yóò wá, yóò fẹ́ wá láti inú aginjù orísun omi rẹ̀ yóò gbẹ kànga rẹ̀ yóò gbẹ pẹ̀lú olè yóò fọ́ ilé ẹrù àti gbogbo ilé ìṣúra rẹ̀.
Deşi este roditor între fraţii lui, un vânt de est va veni, vântul DOMNULUI se va ridica din pustie şi izvorul lui se va usca şi fântâna lui va seca; el va prăda tezaurul tuturor vaselor plăcute.
16 Ará Samaria gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn, nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí Ọlọ́run wọn. Wọn ó ti ipa idà ṣubú; a ó fọ́ àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀, a ó sì la àwọn aboyún wọn nínú.”
Samaria va fi pustiită, pentru că s-a răzvrătit împotriva Dumnezeului ei; vor cădea prin sabie; pruncii lor vor fi zdrobiţi în bucăţi şi femeile lor însărcinate vor fi spintecate.

< Hosea 13 >