< Hosea 12 >

1 Efraimu ń jẹ afẹ́fẹ́; o ń lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀-oòrùn ní gbogbo ọjọ́. O sì ń gbèrú nínú irọ́ o dá májẹ̀mú pẹ̀lú Asiria o sì fi òróró olifi ránṣẹ́ sí Ejibiti.
Efraim jagar efter vind och far efter östanväder; beständigt går han framåt i lögn och våld. Med Assur sluter man förbund, och olja för man till Egypten.
2 Olúwa ní ẹjọ́ kan tí yóò bá Juda rò, yóò fì ìyà jẹ Jakọbu gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ yóò sì sán fún un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
Men HERREN skall gå till rätta med Juda och hemsöka Jakob, såsom hans vägar förtjäna; efter hans gärningar skall han vedergälla honom.
3 Láti inú oyún ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀, àti nípa ipá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
I moderlivet grep han sin broder i hälen, och i sin mandomskraft kämpade han med Gud.
4 Ó bá angẹli ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀, o sọkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere rẹ̀. Ó bá Olúwa ní Beteli, Ó sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
Ja, han kämpade med ängeln och vann seger, han grät och bad honom om nåd. I Betel mötte han honom, och där talade han med oss.
5 àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀.
Och HERREN, härskarornas Gud, "HERREN" är hans namn.
6 Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀; di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo mú kí ẹ sì dúró de Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
Så vänd nu om till din Gud; håll fast vid kärlek och rätt, och förbida din Gud beständigt.
7 Oníṣòwò ń lo òsùwọ̀n èké o fẹ́ràn láti rẹ́ ni jẹ.
Kanaans folk går med falsk våg i sin hand, det älskar orättrådig vinning;
8 Efraimu gbéraga, “Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀, pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéé tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́.”
så säger ock Efraim: "Jag har ju blivit rik, jag har förvärvat mig gods; vad jag än gör, skall det ej draga över mig skuld som kan räknas för synd."
9 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ; ẹni tí ó mu ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti; èmi yóò tún mú yín gbé nínú àgọ́ bí i ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn wọ̀n-ọn-nì.
Men jag som är HERREN, din Gud, alltsedan du var i Egyptens land, jag skall återigen låta dig bo i tält, likasom vid eder högtid.
10 Mo sọ fún àwọn wòlíì, mo fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìran hàn wọ́n mo sì pa òwe láti ẹnu wòlíì wọn.”
Jag har talat till profeterna, jag har låtit dem skåda mångahanda syner, och genom profeterna har jag talat i liknelser.
11 Gileadi ha burú bí? Àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ́ asán. Ǹjẹ́ wọ́n ń fi akọ màlúù rú ẹbọ ní Gilgali? Gbogbo pẹpẹ wọ́n sì dàbí ebè nínú aporo oko.
Är nu Gilead ett ogärningsnäste, där allenast falskhet råder, och offrar man tjurar i Gilgal, så skola ock deras altaren bliva lika stenrösen vid markens fåror.
12 Jakọbu sálọ si orílẹ̀-èdè Aramu; Israẹli sìn kí o tó fẹ́ ìyàwó ó ṣe ìtọ́jú ẹran láti fi san owó ìyàwó.
Och Jakob flydde till Arams mark Israel tjänade för en kvinna, för en kvinnas skull vaktade han hjorden.
13 Olúwa lo wòlíì kan láti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, nípasẹ̀ wòlíì kan ó ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
Men genom en profet förde HERREN Israel upp ur Egypten, och genom en profet blev folket bevarat.
14 Ṣùgbọ́n Efraimu ti mú un bínú gidigidi; Olúwa rẹ̀ yóò sì fi ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sí orí rẹ̀ òun yóò sì san án padà fún un nítorí ìwà ẹ̀gàn an rẹ̀.
Efraim har uppväckt bitter förtörnelse; hans Herre skall låta hans blodskulder drabba honom och låta hans smädelser falla tillbaka på honom själv.

< Hosea 12 >