< Hosea 12 >
1 Efraimu ń jẹ afẹ́fẹ́; o ń lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀-oòrùn ní gbogbo ọjọ́. O sì ń gbèrú nínú irọ́ o dá májẹ̀mú pẹ̀lú Asiria o sì fi òróró olifi ránṣẹ́ sí Ejibiti.
Efraim karmi się wiatrem, goni za wiatrem wschodnim. Przez cały dzień mnoży kłamstwo i spustoszenie, bo zawiera przymierze z Asyryjczykami i wynosi oliwę do Egiptu.
2 Olúwa ní ẹjọ́ kan tí yóò bá Juda rò, yóò fì ìyà jẹ Jakọbu gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ yóò sì sán fún un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
PAN wiedzie też spór z Judą i ukarze Jakuba według jego dróg, odda mu według jego czynów.
3 Láti inú oyún ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀, àti nípa ipá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
[Jeszcze] w łonie ujął [on] za piętę swego brata, a swoją siłą mężnie zmagał się z Bogiem.
4 Ó bá angẹli ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀, o sọkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere rẹ̀. Ó bá Olúwa ní Beteli, Ó sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
Mężnie zmagał się z Aniołem i [go] przemógł. Płakał i go prosił. Znalazł go w Betel i tam z nami rozmawiał;
5 àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀.
To [jest] PAN, Bóg zastępów, PAN to jego pamiętne [imię].
6 Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀; di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo mú kí ẹ sì dúró de Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
Ty więc nawróć się do swego Boga, przestrzegaj miłosierdzia i sądu i oczekuj swego Boga nieustannie.
7 Oníṣòwò ń lo òsùwọ̀n èké o fẹ́ràn láti rẹ́ ni jẹ.
[Jest] kupcem, w jego ręce jest fałszywa waga, lubi uciskać.
8 Efraimu gbéraga, “Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀, pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéé tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́.”
I Efraim powiedział: Ale wzbogaciłem się, zdobyłem dla siebie bogactwo. We wszystkich moich trudach nie znajdą przy mnie nieprawości, co byłoby grzechem.
9 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ; ẹni tí ó mu ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti; èmi yóò tún mú yín gbé nínú àgọ́ bí i ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn wọ̀n-ọn-nì.
Jednak ja jestem PAN, twój Bóg, od wyjścia z ziemi Egiptu. Jeszcze sprawię, że będziecie mieszkać w namiotach, jak za dni uroczystych świąt.
10 Mo sọ fún àwọn wòlíì, mo fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìran hàn wọ́n mo sì pa òwe láti ẹnu wòlíì wọn.”
Mówiłem przez proroków, mnożyłem widzenia i przez proroków podawałem przypowieści.
11 Gileadi ha burú bí? Àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ́ asán. Ǹjẹ́ wọ́n ń fi akọ màlúù rú ẹbọ ní Gilgali? Gbogbo pẹpẹ wọ́n sì dàbí ebè nínú aporo oko.
Czy tylko w Gileadzie była nieprawość i marność? I w Gilgal składają ofiary z wołów, owszem, ich ołtarzów pełno jak stosów [kamieni] w bruzdach na polach.
12 Jakọbu sálọ si orílẹ̀-èdè Aramu; Israẹli sìn kí o tó fẹ́ ìyàwó ó ṣe ìtọ́jú ẹran láti fi san owó ìyàwó.
Tam uciekł Jakub do ziemi Syrii, gdzie Izrael służył za żonę i za żonę strzegł [stada].
13 Olúwa lo wòlíì kan láti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, nípasẹ̀ wòlíì kan ó ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
Ale PAN przez proroka wyprowadził Izraela z Egiptu i przez proroka był strzeżony.
14 Ṣùgbọ́n Efraimu ti mú un bínú gidigidi; Olúwa rẹ̀ yóò sì fi ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sí orí rẹ̀ òun yóò sì san án padà fún un nítorí ìwà ẹ̀gàn an rẹ̀.
Lecz Efraim pobudził [PANA] do gorzkiego gniewu. Dlatego na niego wyleje się jego krew i jego Pan odpłaci mu za jego zniewagę.