< Hosea 12 >

1 Efraimu ń jẹ afẹ́fẹ́; o ń lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀-oòrùn ní gbogbo ọjọ́. O sì ń gbèrú nínú irọ́ o dá májẹ̀mú pẹ̀lú Asiria o sì fi òróró olifi ránṣẹ́ sí Ejibiti.
Ko ta Eparaima kai ko te hau, e whaia ana e ia te hau marangai: i nga ra katoa e whakanuia ana e ia te teka me te whakangaro; e whakarite kawenata ana ratou ki te Ahiriana, a e kawea ana he hinu ki Ihipa.
2 Olúwa ní ẹjọ́ kan tí yóò bá Juda rò, yóò fì ìyà jẹ Jakọbu gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ yóò sì sán fún un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
Na he whakawa ta Ihowa ki a Hura, ka utaina ano e ia ki runga ki a Hakopa nga mea rite ki ona ara; ka rite ki ana mahi tana utu ki a ia.
3 Láti inú oyún ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀, àti nípa ipá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
I roto i te kopu i hopukia e ia tona tuakana ki te rekereke; a i a ia ka tangata i kaha ia ki te Atua;
4 Ó bá angẹli ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀, o sọkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere rẹ̀. Ó bá Olúwa ní Beteli, Ó sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
Ae ra, i kaha ia ki te anahera, a taea ana e ia: i tangi ia, i inoi ki a ia: i tutaki ia ki a ia ki Peteere, a korero ana ia ki a tatou i reira;
5 àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀.
Ara a Ihowa, te Atua o nga mano; ko Ihowa tona maharatanga.
6 Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀; di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo mú kí ẹ sì dúró de Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
Na reira tahuri koe ki tou Atua: puritia te mahi tohu me te tika, tatari tonu ki tou Atua.
7 Oníṣòwò ń lo òsùwọ̀n èké o fẹ́ràn láti rẹ́ ni jẹ.
He kaihokohoko ia, kei tona ringa nga pauna tinihanga: e aroha ana ia ki te tukino.
8 Efraimu gbéraga, “Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀, pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéé tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́.”
I mea ano a Eparaima, He pono kua whai taonga ahau, kua kitea e ahau he rawa moku: i aku mahi katoa e kore e kitea e ratou he kino, ara he hara ki ahau.
9 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ; ẹni tí ó mu ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti; èmi yóò tún mú yín gbé nínú àgọ́ bí i ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn wọ̀n-ọn-nì.
Na ko Ihowa ahau, ko tou Atua, no te whenua o Ihipa mai ra ano; tenei ake ka meinga ano koe e ahau kia noho teneti; kia pera me to nga ra o te hakari nui.
10 Mo sọ fún àwọn wòlíì, mo fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìran hàn wọ́n mo sì pa òwe láti ẹnu wòlíì wọn.”
Kua korero ano ahau ki nga poropiti, a kua whakamahangia e ahau nga whakakitenga; na te mahi minita a nga poropiti i korero ai ahau i nga kupu whakarite.
11 Gileadi ha burú bí? Àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ́ asán. Ǹjẹ́ wọ́n ń fi akọ màlúù rú ẹbọ ní Gilgali? Gbogbo pẹpẹ wọ́n sì dàbí ebè nínú aporo oko.
Ko te hara ranei a Kireara? ina, he mea teka kau ratou; e patu kau ana ratou ki Kirikara hei whakahere: ae ra, he rite a ratou aata ki nga puranga i nga moa o nga mara.
12 Jakọbu sálọ si orílẹ̀-èdè Aramu; Israẹli sìn kí o tó fẹ́ ìyàwó ó ṣe ìtọ́jú ẹran láti fi san owó ìyàwó.
I rere ano a Hakopa ki te mara a Arame, a mahi ana a Iharaira hei utu wahine; hei utu wahine i tiaki hipi ai ia.
13 Olúwa lo wòlíì kan láti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, nípasẹ̀ wòlíì kan ó ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
I kawea mai ano e Ihowa, ara e te poropiti, a Iharaira i Ihipa, na te poropiti ano ia i ora ai.
14 Ṣùgbọ́n Efraimu ti mú un bínú gidigidi; Olúwa rẹ̀ yóò sì fi ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sí orí rẹ̀ òun yóò sì san án padà fún un nítorí ìwà ẹ̀gàn an rẹ̀.
I whakapataritari a Eparaima ki a ia, kawa rawa: mo reira ka waiho e ia tona toto i runga i a ia, ka meinga ano tona ingoa kino e tona ariki kia hoki atu ki a ia.

< Hosea 12 >