< Hosea 12 >
1 Efraimu ń jẹ afẹ́fẹ́; o ń lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀-oòrùn ní gbogbo ọjọ́. O sì ń gbèrú nínú irọ́ o dá májẹ̀mú pẹ̀lú Asiria o sì fi òróró olifi ránṣẹ́ sí Ejibiti.
Efraim szél után jár, keleti szelet kerget, egész nap hazugságot és pusztítást szaporít; szövetséget is kötnek Assúrral, olajat is visznek Egyiptomnak.
2 Olúwa ní ẹjọ́ kan tí yóò bá Juda rò, yóò fì ìyà jẹ Jakọbu gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ yóò sì sán fún un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
De pöre van az Örökkévalónak Jehúdával és büntetnie kell Jákóbot útjai szerint, cselekedetei szerint fizet majd neki.
3 Láti inú oyún ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀, àti nípa ipá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
Az anyaméhben sarkon fogta a testvérét s erejében küzdött Istennel.
4 Ó bá angẹli ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀, o sọkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere rẹ̀. Ó bá Olúwa ní Beteli, Ó sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
Küzdött angyal ellen és győzött, sírt és könyörgött neki: Bét-Élben fogja őt találni, s ott beszél majd velünk.
5 àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀.
És az Örökkévaló, a seregek Istene, Örökkévaló az ő neve!
6 Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀; di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo mú kí ẹ sì dúró de Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
Te pedig térj meg Istenedhez: szeretetet és jogosságot őrizz és remélj Istenedhez mindig.
7 Oníṣòwò ń lo òsùwọ̀n èké o fẹ́ràn láti rẹ́ ni jẹ.
Kanaán – kezében csalfa mérleg van, fosztogatni szeret.
8 Efraimu gbéraga, “Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀, pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéé tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́.”
Azt mondta Efraim: Csakugyan meggazdagodtam, vagyonra tettem szert: mind a fáradozásaim nem szereznek: nekem bűnt, a mely vétek.
9 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ; ẹni tí ó mu ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti; èmi yóò tún mú yín gbé nínú àgọ́ bí i ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn wọ̀n-ọn-nì.
Én pedig vagyok az Örökkévaló, a te Istened, Egyiptom országától fogva, még lakatlak téged sátrakban, mint az ünnepidő napjaiban.
10 Mo sọ fún àwọn wòlíì, mo fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìran hàn wọ́n mo sì pa òwe láti ẹnu wòlíì wọn.”
Beszéltem a prófétákhoz, és én szaporítottam a látomást és a próféták által szóltam hasonlatokban.
11 Gileadi ha burú bí? Àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ́ asán. Ǹjẹ́ wọ́n ń fi akọ màlúù rú ẹbọ ní Gilgali? Gbogbo pẹpẹ wọ́n sì dàbí ebè nínú aporo oko.
Ha Gileád hamisság, csakugyan semmisséggé lesznek; Gilgálban ökröket áldoztak, oltáraik is olyanok mint a kőhalmok a mező barázdáin.
12 Jakọbu sálọ si orílẹ̀-èdè Aramu; Israẹli sìn kí o tó fẹ́ ìyàwó ó ṣe ìtọ́jú ẹran láti fi san owó ìyàwó.
Elmenekült Jákób Arám mezőségére és szolgált Izraél egy asszonyért és egy asszonyért juhokat őrzött.
13 Olúwa lo wòlíì kan láti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, nípasẹ̀ wòlíì kan ó ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
És próféta által hozta fel az Örökkévaló Izraélt Egyiptomból, és próféta által őriztetett.
14 Ṣùgbọ́n Efraimu ti mú un bínú gidigidi; Olúwa rẹ̀ yóò sì fi ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sí orí rẹ̀ òun yóò sì san án padà fún un nítorí ìwà ẹ̀gàn an rẹ̀.
Bosszantott Efraim keserűen: vérontását reá veti és gyalázatát megfizeti neki az Ura!