< Hosea 12 >

1 Efraimu ń jẹ afẹ́fẹ́; o ń lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀-oòrùn ní gbogbo ọjọ́. O sì ń gbèrú nínú irọ́ o dá májẹ̀mú pẹ̀lú Asiria o sì fi òróró olifi ránṣẹ́ sí Ejibiti.
KE ai nei ka Eperaima i ka makani, A ke hahai nei hoi ia i ka makani hikina: Hoomahuahua no ia i na la a pau i ka hoopunipuni a me ka luku ana; A hana lakou i ka berita me ko Asuria, A ua laweia'ku ka aila i Aigupita.
2 Olúwa ní ẹjọ́ kan tí yóò bá Juda rò, yóò fì ìyà jẹ Jakọbu gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ yóò sì sán fún un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
He paio hoi ko Iehova me ka Iuda, A e hoopai aku oia ia Iakoba e like me kona mau aoao; E hoouku aku kela ia ia e like me kana hana.
3 Láti inú oyún ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀, àti nípa ipá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
Iloko o ka opu hoopaa aku oia i ke kuekuewawae o kona kaikuaana, A ma kona ikaika hakaka pu ia me ke Akua.
4 Ó bá angẹli ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀, o sọkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere rẹ̀. Ó bá Olúwa ní Beteli, Ó sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
A hakaka pu ia me ka anela, a lanakila: Uwe iho la ia, a nonoi aku la ia ia: Loaa oia ia ia ma Betela, a olelo pu oia me kakou;
5 àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀.
Oia hoi, o Iehova ke Akua o na kaua; O Iehova, oia kona inoa ponoi.
6 Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀; di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo mú kí ẹ sì dúró de Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
Nolaila, e huli oe i kou Akua: E malama i ke aloha, a me ka olelo hoopono, A e hilinai mau maluna o kou Akua.
7 Oníṣòwò ń lo òsùwọ̀n èké o fẹ́ràn láti rẹ́ ni jẹ.
He kalepa no ia, ma kona lima ka mea kaupaona hoopunipuni: A makemake no ia i ka alunu.
8 Efraimu gbéraga, “Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀, pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéé tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́.”
A i iho la o Eperaima, Ua lako no nae wau, Ua loaa ia'u ka waiwai; Ma ka'u mau hana a pau aole i loaa kuu hewa, ka mea i hewa'i au.
9 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ; ẹni tí ó mu ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti; èmi yóò tún mú yín gbé nínú àgọ́ bí i ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn wọ̀n-ọn-nì.
A owau, o Iehova kou Akua, mai ka aina o Aigupita mai, E hoonoho hou aku au ia oe i na halelewa, e like me na la o ka ahaaina.
10 Mo sọ fún àwọn wòlíì, mo fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìran hàn wọ́n mo sì pa òwe láti ẹnu wòlíì wọn.”
A ua olelo aku au ma na kaula, A ua hoomahuahua i na hihio, A ua olelo aku au i na olelo nane ma ka lima o na kaula.
11 Gileadi ha burú bí? Àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ́ asán. Ǹjẹ́ wọ́n ń fi akọ màlúù rú ẹbọ ní Gilgali? Gbogbo pẹpẹ wọ́n sì dàbí ebè nínú aporo oko.
Ua hewa anei ko Gileada? Oia, ua hewa lakou; Ke kaumaha nei lakou i na bipi ma Gilegala; A o ko lakou mau kuahu, ua like me na ahu ma na auwaha o ka mahinaai.
12 Jakọbu sálọ si orílẹ̀-èdè Aramu; Israẹli sìn kí o tó fẹ́ ìyàwó ó ṣe ìtọ́jú ẹran láti fi san owó ìyàwó.
A holo aku la o Iakoba i ka aina o Suria; A hooluhi aku la o Iseraela no ka wahine, A no ka wahine malama aku la ia i na holoholona.
13 Olúwa lo wòlíì kan láti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, nípasẹ̀ wòlíì kan ó ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
A ma ke kaula i lawe mai ai o Iehova i ka Iseraela mai Aigupita mai, A ma ke kaula i malama mai ai oia ia ia.
14 Ṣùgbọ́n Efraimu ti mú un bínú gidigidi; Olúwa rẹ̀ yóò sì fi ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sí orí rẹ̀ òun yóò sì san án padà fún un nítorí ìwà ẹ̀gàn an rẹ̀.
Hoonaukiuki loa aku la o Eperaima ia ia; Nolaila e waiho aku ai ia i kona koko maluna ona, A e hoihoi aku kona Haku i kona hoowahawaha maluna ona.

< Hosea 12 >