< Hosea 12 >

1 Efraimu ń jẹ afẹ́fẹ́; o ń lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀-oòrùn ní gbogbo ọjọ́. O sì ń gbèrú nínú irọ́ o dá májẹ̀mú pẹ̀lú Asiria o sì fi òróró olifi ránṣẹ́ sí Ejibiti.
Ephraïm se nourrit de vent, et chasse le vent d'est. Il multiplie sans cesse les mensonges et la désolation. Ils font une alliance avec l'Assyrie, et le pétrole est transporté en Égypte.
2 Olúwa ní ẹjọ́ kan tí yóò bá Juda rò, yóò fì ìyà jẹ Jakọbu gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ yóò sì sán fún un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
Yahvé a également une controverse avec Juda, et punira Jacob selon ses voies; il lui rendra selon ses actes.
3 Láti inú oyún ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀, àti nípa ipá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
Dans le ventre de sa mère, il a pris son frère par le talon, et dans sa vie d'homme, il s'est disputé avec Dieu.
4 Ó bá angẹli ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀, o sọkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere rẹ̀. Ó bá Olúwa ní Beteli, Ó sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
En effet, il a lutté avec l'ange et l'a emporté; il pleura, et lui fit des supplications. Il l'a trouvé à Bethel, et là il a parlé avec nous...
5 àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀.
même Yahvé, le Dieu des armées. Yahvé est son nom de renom!
6 Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀; di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo mú kí ẹ sì dúró de Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
C'est pourquoi, tournez-vous vers votre Dieu. Gardez la bonté et la justice, et attendez sans cesse votre Dieu.
7 Oníṣòwò ń lo òsùwọ̀n èké o fẹ́ràn láti rẹ́ ni jẹ.
Un marchand a dans sa main des balances malhonnêtes. Il aime frauder.
8 Efraimu gbéraga, “Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀, pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéé tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́.”
Ephraïm dit: « Certes, je me suis enrichi. Je me suis trouvé de la richesse. Dans toute ma richesse, ils ne trouveront en moi aucune iniquité qui soit un péché. »
9 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ; ẹni tí ó mu ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti; èmi yóò tún mú yín gbé nínú àgọ́ bí i ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn wọ̀n-ọn-nì.
« Mais moi, je suis Yahvé, ton Dieu, depuis le pays d'Égypte. Je vous ferai à nouveau habiter dans des tentes, comme aux jours de la fête solennelle.
10 Mo sọ fún àwọn wòlíì, mo fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìran hàn wọ́n mo sì pa òwe láti ẹnu wòlíì wọn.”
J'ai aussi parlé aux prophètes, et j'ai multiplié les visions; et par le ministère des prophètes, j'ai utilisé des paraboles.
11 Gileadi ha burú bí? Àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ́ asán. Ǹjẹ́ wọ́n ń fi akọ màlúù rú ẹbọ ní Gilgali? Gbogbo pẹpẹ wọ́n sì dàbí ebè nínú aporo oko.
Si Galaad est méchant, ils sont sûrement sans valeur. A Gilgal, on sacrifie des taureaux. En effet, leurs autels sont comme des tas dans les sillons du champ.
12 Jakọbu sálọ si orílẹ̀-èdè Aramu; Israẹli sìn kí o tó fẹ́ ìyàwó ó ṣe ìtọ́jú ẹran láti fi san owó ìyàwó.
Jacob s'enfuit dans le pays d'Aram. Israël a servi pour avoir une femme. Comme épouse, il s'occupait de troupeaux.
13 Olúwa lo wòlíì kan láti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, nípasẹ̀ wòlíì kan ó ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
C'est par un prophète que Yahvé a fait monter Israël hors d'Égypte, et par un prophète, il a été préservé.
14 Ṣùgbọ́n Efraimu ti mú un bínú gidigidi; Olúwa rẹ̀ yóò sì fi ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sí orí rẹ̀ òun yóò sì san án padà fún un nítorí ìwà ẹ̀gàn an rẹ̀.
Ephraïma provoqué la colère avec amertume. Son sang restera donc sur lui, et son Seigneur lui rendra son mépris.

< Hosea 12 >