< Hosea 11 >

1 “Nígbà tí Israẹli wà ní ọmọdé mo fẹ́ràn rẹ̀, mo sì pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.
Då Israel ung var, hade jag honom kär, och kallade honom, min son, utur Egypten.
2 Bí a ti ń pe wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn rú ẹbọ sí Baali, wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.
Men när man nu kallar honom, så vända de sig bort, och offra Baalim, och röka inför beläte.
3 Lóòtítọ́ mo kọ́ Efraimu pẹ̀lú ní ìrìn mo di wọ́n mú ní apá, ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo ti mú wọn láradá.
Jag tog Ephraim i hans arm, och ledde honom; men de hafva nu förgätit, huru jag halp dem.
4 Mo fi okùn ènìyàn fà wọ́n àti ìdè ìfẹ́. Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọn, Mo sì fi ara balẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.
Jag lät dem draga ett lustigt ok, och gå med mjuka tömmar: och jag tog oket utaf dem, och gaf dem foder;
5 “Ṣé wọn ò wá ní padà sí Ejibiti bí. Ṣé Asiria kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bí nítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronúpìwàdà?
På det han ju icke skulle vända sig åt Egypti land igen. Så är nu Assur vorden deras Konung; ty de ville intet omvända sig.
6 Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọn yóò si bá gbogbo irin ẹnu odi ìlú wọn jẹ́ yóò sì fi òpin sí gbogbo èrò wọn.
Derföre skall svärdet komma öfver deras städer, och skall förtära och uppfräta deras bommar, för deras anslags skull.
7 Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ mi bí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ Ọ̀gá-ògo jùlọ, kò ní gbé wọn ga rárá.
Mitt folk hafver ingen lust till att vända sig till mig och ehuru man predikar dem, så skickar sig dock ingen till att höra.
8 “Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Efraimu? Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Israẹli? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Adma? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Seboimu? Ọkàn mi yípadà nínú mi àánú mi sì ru sókè.
Hvad skall jag göra af dig, Ephraim? Huru skall jag dock plåga dig, Israel? Skall jag icke med rätto göra såsom Adama, och tillpynta dig lika som Zeboim? Men mitt hjerta hafver ett annat sinne; min barmhertighet är så brinnande;
9 Èmi kò ni mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹ, tàbí kí èmi wá sọ Efraimu di ahoro. Nítorí pé èmi ni Ọlọ́run, àní, èmi kì í ṣe ènìyàn. Ẹni mímọ́ láàrín yín, Èmi kò ní í wá nínú ìbínú.
Att jag icke göra vill efter mina grymma vrede, eller vända mig till att jag platt förderfvar Ephraim; ty jag är Gud, och icke menniska, och är den Helige ibland dig dock skall mitt rike icke vara i stadenom.
10 Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa; òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìún. Nígbà tó bá bú, àwọn ọmọ rẹ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀-oòrùn.
Då skall man efterfölja Herran, och han skall ryta såsom ett lejon; och när han ryter, så skola de förskräcka sig, som vesterut äro.
11 Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rù bí i ẹyẹ láti Ejibiti, bí i àdàbà láti Asiria, Èmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,” ni Olúwa wí.
Och de uti Egypten skola ock förskräckas, såsom en fogel; och de i Assurs land, lika som dufvor; och jag vill sätta dem uti sin hus, säger Herren.
12 Efraimu tí fi irọ́ yí mi ká ilé Israẹli pẹ̀lú ẹ̀tàn. Ṣùgbọ́n Juda sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́run. Ó sì ṣe olóòtítọ́ sí Ẹni mímọ́ Israẹli.
Uti Ephraim är allstädes afguderi emot mig, och i Israels hus falsk Gudstjenst; men Juda håller sig ännu fast intill Gud, och till den rätta heliga Gudstjensten.

< Hosea 11 >