< Hosea 11 >

1 “Nígbà tí Israẹli wà ní ọmọdé mo fẹ́ràn rẹ̀, mo sì pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.
Ko je bil Izrael otrok, takrat sem ga ljubil in svojega sina poklical iz Egipta.
2 Bí a ti ń pe wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn rú ẹbọ sí Baali, wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.
Kakor so jih [preroki] klicali, tako so odhajali od njih. Žrtvovali so Báalom in rezanim podobam zažigali kadilo.
3 Lóòtítọ́ mo kọ́ Efraimu pẹ̀lú ní ìrìn mo di wọ́n mú ní apá, ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo ti mú wọn láradá.
Tudi Efrájima sem učil hoditi in jih držal za njihove lakte, toda niso spoznali, da sem jih jaz ozdravil.
4 Mo fi okùn ènìyàn fà wọ́n àti ìdè ìfẹ́. Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọn, Mo sì fi ara balẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.
Pritegoval sem jih s človeškimi vrvicami, z vezmi ljubezni in bil sem jim kakor tisti, ki snamejo jarem z njihovih čeljusti in jaz sem jim dajal hrano.
5 “Ṣé wọn ò wá ní padà sí Ejibiti bí. Ṣé Asiria kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bí nítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronúpìwàdà?
Ne bo se vrnil v egiptovsko deželo, temveč bo Asirec njegov kralj, ker so zavrnili, da bi se vrnili.
6 Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọn yóò si bá gbogbo irin ẹnu odi ìlú wọn jẹ́ yóò sì fi òpin sí gbogbo èrò wọn.
Meč bo ostajal na njegovih mestih in použije njegove mladike in jih požre zaradi njihovih lastnih nasvetov.
7 Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ mi bí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ Ọ̀gá-ògo jùlọ, kò ní gbé wọn ga rárá.
Moje ljudstvo je nagnjeno k odpadu od mene. Čeprav so jih klicali k Najvišjemu, ga sploh nihče ni hotel povišati.
8 “Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Efraimu? Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Israẹli? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Adma? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Seboimu? Ọkàn mi yípadà nínú mi àánú mi sì ru sókè.
Kako naj bi se ti odrekel, Efrájim? Kako naj bi te izročil, Izrael? Kako naj bi te naredil kakor Admo? Kako naj bi te postavil kakor Cebojím? Moje srce je spremenjeno znotraj mene, poleg tega so se moja kesanja razvnela.
9 Èmi kò ni mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹ, tàbí kí èmi wá sọ Efraimu di ahoro. Nítorí pé èmi ni Ọlọ́run, àní, èmi kì í ṣe ènìyàn. Ẹni mímọ́ láàrín yín, Èmi kò ní í wá nínú ìbínú.
Ne bom izvršil okrutnosti svoje jeze, ne bom se vrnil, da uničim Efrájima, kajti jaz sem Bog in ne človek, Sveti v tvoji sredi in ne bom vstopil v mesto.«
10 Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa; òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìún. Nígbà tó bá bú, àwọn ọmọ rẹ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀-oòrùn.
Hodili bodo za Gospodom, rjovel bo kakor lev. Ko bo zarjovel, potem bodo otroci pritrepetali od zahoda.
11 Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rù bí i ẹyẹ láti Ejibiti, bí i àdàbà láti Asiria, Èmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,” ni Olúwa wí.
Pritrepetali bodo kakor ptica iz Egipta in kakor golobica iz asirske dežele in postavil jih bom v njihove hiše, « govori Gospod.
12 Efraimu tí fi irọ́ yí mi ká ilé Israẹli pẹ̀lú ẹ̀tàn. Ṣùgbọ́n Juda sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́run. Ó sì ṣe olóòtítọ́ sí Ẹni mímọ́ Israẹli.
»Efrájim me obdaja z lažmi in Izraelova hiša s prevaro, toda Juda še vlada z Bogom in je zvest s svetimi.

< Hosea 11 >