< Hosea 11 >
1 “Nígbà tí Israẹli wà ní ọmọdé mo fẹ́ràn rẹ̀, mo sì pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.
Midőn fiatal volt Izraél, megszerettem; és Egyiptomból elhívtam fiamat.
2 Bí a ti ń pe wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn rú ẹbọ sí Baali, wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.
Amint hívták őket, úgy mentek el előlük; a Báaloknak áldozgatnak, a képeknek füstölögtetnek!
3 Lóòtítọ́ mo kọ́ Efraimu pẹ̀lú ní ìrìn mo di wọ́n mú ní apá, ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo ti mú wọn láradá.
Pedig én jártattam Efraimot, vevén őt karjainál; de nem tudták, hogy gyógyítgatom őket.
4 Mo fi okùn ènìyàn fà wọ́n àti ìdè ìfẹ́. Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọn, Mo sì fi ara balẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.
Emberi kötelekkel vonzottam, szeretetnek kötelékeivel, és olyan lettem nekik, mint a ki megemelinti a jármot állkapcsukon, és nyújtottam neki ételt.
5 “Ṣé wọn ò wá ní padà sí Ejibiti bí. Ṣé Asiria kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bí nítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronúpìwàdà?
Nemde Egyiptom országába fog visszatérni és Assúr lesz a királya, mert vonakodtak megtérni.
6 Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọn yóò si bá gbogbo irin ẹnu odi ìlú wọn jẹ́ yóò sì fi òpin sí gbogbo èrò wọn.
Kard csap le a városaira, megsemmisíti reteszeit és megemészti, az ő tanácsaik miatt.
7 Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ mi bí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ Ọ̀gá-ògo jùlọ, kò ní gbé wọn ga rárá.
Népem pedig azon csüng, hogy tőlem elpártol; fölfelé hívják, egyaránt nem emelkedik.
8 “Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Efraimu? Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Israẹli? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Adma? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Seboimu? Ọkàn mi yípadà nínú mi àánú mi sì ru sókè.
Hogy adnálak oda, Efraim, szolgáltatnálak ki, Izraél? hogy adnálak, mint Admát, tennélek hasonlóvá Czebójimhoz? Megfordult bennem a szívem, egészen megindult a szánalmam.
9 Èmi kò ni mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹ, tàbí kí èmi wá sọ Efraimu di ahoro. Nítorí pé èmi ni Ọlọ́run, àní, èmi kì í ṣe ènìyàn. Ẹni mímọ́ láàrín yín, Èmi kò ní í wá nínú ìbínú.
Nem teszem meg fellobbant haragomat, nem rontom meg ismét Efraimot; mert Isten vagyok s nem ember, közepetted szent és nem támadlak gerjedésben.
10 Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa; òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìún. Nígbà tó bá bú, àwọn ọmọ rẹ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀-oòrùn.
Az Örökkévaló után fognak menni, mint oroszlán fog ordítani; igenis, ő ordítani fog és remegnek a falak a tenger felől.
11 Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rù bí i ẹyẹ láti Ejibiti, bí i àdàbà láti Asiria, Èmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,” ni Olúwa wí.
Remegve jönnek mint madár Egyiptomból s mint galamb Assúr országából; letelepítem őket házaikba, úgymond az Örökkévaló.
12 Efraimu tí fi irọ́ yí mi ká ilé Israẹli pẹ̀lú ẹ̀tàn. Ṣùgbọ́n Juda sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́run. Ó sì ṣe olóòtítọ́ sí Ẹni mímọ́ Israẹli.
Körülvett engem hamissággal Efraim és csalfasággal Izraél háza; Jehúda pedig egyre állhatatos Isten mellett és a Szent iránt hűséges.