< Hosea 11 >

1 “Nígbà tí Israẹli wà ní ọmọdé mo fẹ́ràn rẹ̀, mo sì pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.
Der Israel var ung, da havde jeg ham kær, og fra Ægypten kaldte jeg min Søn.
2 Bí a ti ń pe wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn rú ẹbọ sí Baali, wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.
Som de kaldte paa dem, saa gik de bort fra deres Ansigt, og til Baalerne ofre de, og for de udskaarne Billeder gøre de Røgelse.
3 Lóòtítọ́ mo kọ́ Efraimu pẹ̀lú ní ìrìn mo di wọ́n mú ní apá, ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo ti mú wọn láradá.
Og jeg, jeg lærte Efraim at gaa, tog dem paa Arm; men de vilde ikke vide, at jeg havde lægt dem.
4 Mo fi okùn ènìyàn fà wọ́n àti ìdè ìfẹ́. Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọn, Mo sì fi ara balẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.
Med Menneskesnore, med Kærligheds Baand drog jeg dem, og jeg var dem som de, der skyde Aaget over deres Kæver op; og jeg rakte ham Føde.
5 “Ṣé wọn ò wá ní padà sí Ejibiti bí. Ṣé Asiria kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bí nítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronúpìwàdà?
Han skal ikke vende tilbage til Ægyptens Land; men Assur, han skal være hans Konge, thi de vægrede sig ved at vende om.
6 Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọn yóò si bá gbogbo irin ẹnu odi ìlú wọn jẹ́ yóò sì fi òpin sí gbogbo èrò wọn.
Og Sværdet skal hvirvle om i hans Stæder og tilintetgøre hans Portstænger og fortære, og det for deres Raads Skyld.
7 Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ mi bí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ Ọ̀gá-ògo jùlọ, kò ní gbé wọn ga rárá.
Mit Folk hælder til Frafald fra mig; og kalder man dem opad, saa stræber ingen af dem opad.
8 “Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Efraimu? Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Israẹli? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Adma? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Seboimu? Ọkàn mi yípadà nínú mi àánú mi sì ru sókè.
Dog, hvorledes skal jeg kunne hengive dig, Efraim? og lade dig fare, Israel? hvorledes skal jeg kunne gøre ved dig som ved Adma, behandle dig som Zeboim? mit Hjerte har vendt sig i mig, og min Medlidenhed er i heftig Bevægelse.
9 Èmi kò ni mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹ, tàbí kí èmi wá sọ Efraimu di ahoro. Nítorí pé èmi ni Ọlọ́run, àní, èmi kì í ṣe ènìyàn. Ẹni mímọ́ láàrín yín, Èmi kò ní í wá nínú ìbínú.
Jeg vil ikke fuldbyrde min brændende Vrede, jeg vil ikke komme igen og ødelægge Efraim; thi jeg er Gud og ikke et Menneske, den Hellige midt iblandt dig, og jeg vil ikke komme med glødende Harme.
10 Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa; òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìún. Nígbà tó bá bú, àwọn ọmọ rẹ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀-oòrùn.
Efter Herren skulle de vandre, som en Løve skal han brøle; thi han skal brøle, og Børn skulle komme skælvende fra Havet af.
11 Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rù bí i ẹyẹ láti Ejibiti, bí i àdàbà láti Asiria, Èmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,” ni Olúwa wí.
De skulle komme skælvende som en Fugl fra Ægypten og som en Due fra Assurs Land; og jeg vil lade dem bo i deres Huse, siger Herren.
12 Efraimu tí fi irọ́ yí mi ká ilé Israẹli pẹ̀lú ẹ̀tàn. Ṣùgbọ́n Juda sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́run. Ó sì ṣe olóòtítọ́ sí Ẹni mímọ́ Israẹli.
Efraim har omringet mig med Løgn, og Israels Hus med Svig, og Juda svæver fremdeles ustyrligt om hos Gud og hos deri trofaste Hellige.

< Hosea 11 >