< Hosea 10 >

1 Israẹli jẹ́ igi àjàrà tó gbilẹ̀ ó ń so èso fún ara rẹ̀. Bí èso rẹ̀ ṣe ń pọ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó ń kọ́ pẹpẹ sí i bí ilẹ̀ rẹ̀ ṣe ń ṣe rere o bu ọlá fún òkúta ìyàsọ́tọ̀ ère rẹ̀.
Izrael jest macicą próżną, owoc przynosi sobie; czem więcej miewał owocu swego, tem więcej nabudował ołtarzów; a czem obfitsza jest ziemia jego, tem więcej nastawiał obrazów.
2 Ọkàn wọn kún fún ìtànjẹ báyìí wọ́n gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn. Olúwa yóò wó pẹpẹ wọn palẹ̀ yóò sì pa gbogbo òkúta ìyàsọ́tọ̀ wọn run.
Rozdziela się serce ich, przetoż winnymi są; on pokruszy ołtarze ich, i obrazy ich popsuje.
3 Nígbà náà ni wọn yóò wí pé, “A kò ní ọba nítorí tí a kò bọ̀wọ̀ fún Olúwa ṣùgbọ́n bí a tilẹ̀ ní ọba, kí ni yóò ṣe fún wa?”
Ponieważ mówią: Nie mamy króla, nawet nie boimy się Pana, a król nam co uczyni?
4 Wọ́n ṣe ìlérí púpọ̀, wọ́n ṣe ìbúra èké, wọ́n da májẹ̀mú; báyìí ni ìdájọ́ hù sókè bí igi ìwọ̀ ni aporo oko, bi i koríko májèlé láàrín oko tí a ro.
Mówią słowa, przysięgając kłamliwie, gdy czynią przymierze; i wzrośnie sąd jako jad na zagonach polnych.
5 Àwọn ènìyàn tí ń gbé Samaria bẹ̀rù nítorí ère abo màlúù tó wà ní Beti-Afeni. Àwọn ènìyàn rẹ̀ yóò ṣọ̀fọ̀ le e lórí bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà rẹ̀. Gbogbo àwọn tó láyọ̀ sì dídán rẹ̀, nítorí tí a ti mú lọ sí ìgbèkùn.
Dla jałowic Bet Aweńskich zatrwożą się obywatele Samaryjscy, gdy kwilić będą nad nim, lud jego, i popije go, (którzy się więc radowali z niego) przeto, że sława jego odchodzi od niego.
6 A ó gbé lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn fún ọba ńlá a ó dójútì Efraimu; ojú yóò ti Israẹli nítorí ìgbìmọ̀ rẹ̀.
Nawet i sam do Assyryi zaprowadzony będzie za dar królowi Jareb; zawstydzi się Efraim, i zasroma się Izrael za radę swoję.
7 Bí igi tó léfòó lórí omi ni Samaria àti àwọn ọba rẹ yóò sàn lọ.
Wycięty będzie król Samaryjski, jako piana na wierzchu wody.
8 Àwọn ibi gíga tí ẹ tí ń hùwà búburú ni a o parun, èyí ni ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli. Ẹ̀gún ọ̀gàn àti ẹ̀gún òṣùṣú yóò hù jáde, yóò sì bo àwọn pẹpẹ wọn. Wọn yóò sọ fún àwọn òkè gíga pé, “Bò wá mọ́lẹ̀!” àti fún àwọn òkè kéékèèké pé, “Ṣubú lù wá!”
I będą wyżyny Awenu wytracone, grzech Izraelski; ciernie i oset wyrośnie na ołtarzach ich; a rzekną górom: Przykryjcie nas; a pagórkom: Upadnijcie na nas.
9 “Láti ìgbà Gibeah, ni ó ti ṣẹ̀, ìwọ Israẹli, ìwọ sì tún wà níbẹ̀. Ǹjẹ́ ogun kò lé ẹ̀yin aṣebi ni Gibeah bá bí?
Ode dni Gabaa grzeszyłeś, Izraelu! tam się ostali, nie zachwyciła ich w Gabaa bitwa przeciwko synom nieprawości podniesiona.
10 Nígbà tó bá tẹ́ mi lọ́rùn, èmi yóò fi ìyà jẹ wọ́n; Orílẹ̀-èdè yóò kó ra wọn jọ, wọ́n ó sì dojúkọ wọn, láti fi wọn sínú ìdè nítorí ìlọ́po ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Przetoż ich pokarzę według upodobania mego; bo się zbiorą na nich narody, aby byli karani dla dwojakich nieprawości swoich.
11 Efraimu jẹ́ ọmọ abo màlúù tí a tí kọ́, to si fẹ́ràn láti máa pa ọkà; lórí ọrun rẹ̀ tó lẹ́wà ni èmi ó dí ẹrù wúwo lé. Èmi yóò mú kí a gun Efraimu bí ẹṣin Juda yóò tú ilẹ̀, Jakọbu yóò sì fọ́ ògúlùtu rẹ̀.
Bo Efraim jest jako jałowica wyuczona, kocha się w młóceniu, chociażem Ja następował na cudny kark jej, abym do jazdy używał Efraima, Juda aby orał, a Jakób aby włóczył.
12 Ẹ gbin òdòdó fún ara yín, kí ẹ sì ká èso ìfẹ́ àìlópin. Ẹ tu ilẹ̀ yín tí a kò ro, nítorí pé ó ti tó àsìkò láti wá Olúwa, títí tí yóò fi dé, tí yóò sì rọ òjò òdodo lé yín lórí.
I mówiłem: Siejcie sobie ku sprawiedliwości; żnijcie ku miłosierdziu, orzcie sobie nowinę; bo czas jest szukać Pana, aż przyjdzie, i spuści na was sprawiedliwość jako deszcz.
13 Ṣùgbọ́n ẹ tí gbin búburú ẹ si ka ibi, ẹ ti jẹ èso èké nítorí ẹ tí gbẹ́kẹ̀lé agbára yín àti àwọn ọ̀pọ̀ jagunjagun yín,
Aleście orali niepobożność, żęliście nieprawość, jedliście owoc kłamstwa; albowiem ufasz w drodze swej i w mnóstwie mocarzów twoich.
14 ariwo ogun yóò bo àwọn ènìyàn yín kí gbogbo odi agbára yín ba le parun. Gẹ́gẹ́ bí Ṣalmani ṣe pa Beti-Arbeli run lọ́jọ́ ogun, nígbà tí a gbé àwọn ìyá ṣánlẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn.
Dlategoż powstanie rozruch między ludem twoim, a wszystkie zamki twoje poburzone będą, tak jako poburzył Salman Bet Arbel w dzień bitwy; matki z synami roztrącone będą.
15 Báyìí ni a o sì ṣe sí ọ, ìwọ Beteli, nítorí pé ìwà búburú yín ti pọ̀jù. Ní àfẹ̀mọ́júmọ́ ọjọ́ náà, a o pa ọba Israẹli run pátápátá.
Oto tak wam uczyni Betel dla wielkiej złości waszej; król Izraelski na świtaniu do szczętu zgładzony będzie.

< Hosea 10 >