< Hosea 10 >

1 Israẹli jẹ́ igi àjàrà tó gbilẹ̀ ó ń so èso fún ara rẹ̀. Bí èso rẹ̀ ṣe ń pọ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó ń kọ́ pẹpẹ sí i bí ilẹ̀ rẹ̀ ṣe ń ṣe rere o bu ọlá fún òkúta ìyàsọ́tọ̀ ère rẹ̀.
Isiraeli aarĩ ta mũthabibũ watheeremaga, nake agĩĩciarĩra maciaro. O ũrĩa maciaro make maingĩhaga-rĩ, noguo nake aakaga igongona nyingĩ; o ũrĩa bũrũri wake wagaacagĩra-rĩ, noguo aagemagia mahiga make marĩa maamũre ma kũhooyagwo.
2 Ọkàn wọn kún fún ìtànjẹ báyìí wọ́n gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn. Olúwa yóò wó pẹpẹ wọn palẹ̀ yóò sì pa gbogbo òkúta ìyàsọ́tọ̀ wọn run.
Ngoro ciao nĩ cia maheeni, na rĩu no nginya marĩhio wĩhia wao. Jehova nĩakamomora igongona ciao, na athũkangie mahiga macio mao maamũre ma kũhooyagwo.
3 Nígbà náà ni wọn yóò wí pé, “A kò ní ọba nítorí tí a kò bọ̀wọ̀ fún Olúwa ṣùgbọ́n bí a tilẹ̀ ní ọba, kí ni yóò ṣe fún wa?”
Ningĩ nĩmakoiga atĩrĩ, “Tũtirĩ na mũthamaki, tondũ tũtiigana gũtĩĩa Jehova. No o na korwo twarĩ na mũthamaki-rĩ, nĩ atĩa angĩahotire gũtwĩkĩra?”
4 Wọ́n ṣe ìlérí púpọ̀, wọ́n ṣe ìbúra èké, wọ́n da májẹ̀mú; báyìí ni ìdájọ́ hù sókè bí igi ìwọ̀ ni aporo oko, bi i koríko májèlé láàrín oko tí a ro.
Meranagĩra ciĩranĩro nyingĩ, na makehĩta mĩĩhĩtwa ya maheeni, na magathondeka irĩkanĩro; nĩ ũndũ ũcio maciira makunũkaga ta mahuti marĩ ũrogi marĩa mameraga hianyũ-inĩ.
5 Àwọn ènìyàn tí ń gbé Samaria bẹ̀rù nítorí ère abo màlúù tó wà ní Beti-Afeni. Àwọn ènìyàn rẹ̀ yóò ṣọ̀fọ̀ le e lórí bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà rẹ̀. Gbogbo àwọn tó láyọ̀ sì dídán rẹ̀, nítorí tí a ti mú lọ sí ìgbèkùn.
Andũ arĩa matũũraga Samaria metangaga nĩ ũndũ wa mũhianano wa njaũ ĩrĩa ya Bethi-Aveni. Amu andũ akuo nĩmakamĩcakaĩra, na noguo athĩnjĩri-ngai a mĩhianano ĩyo mageeka arĩa makenagĩra riiri wayo, tondũ nĩyeheretio kuuma kũrĩ o, ĩgathaamĩrio kũndũ kũngĩ.
6 A ó gbé lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn fún ọba ńlá a ó dójútì Efraimu; ojú yóò ti Israẹli nítorí ìgbìmọ̀ rẹ̀.
Nayo ĩgaatwarwo Ashuri, ĩtuĩke kĩheo kũrĩ mũthamaki ũcio mũnene. Efiraimu nĩagaconorithio; Isiraeli nake nĩagaconoka nĩ ũndũ wa mĩhianano ĩyo yake ya mĩtĩ.
7 Bí igi tó léfòó lórí omi ni Samaria àti àwọn ọba rẹ yóò sàn lọ.
Samaria na mũthamaki wakuo magaathererio ta karũhonge karĩ igũrũ wa maaĩ, maniinwo.
8 Àwọn ibi gíga tí ẹ tí ń hùwà búburú ni a o parun, èyí ni ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli. Ẹ̀gún ọ̀gàn àti ẹ̀gún òṣùṣú yóò hù jáde, yóò sì bo àwọn pẹpẹ wọn. Wọn yóò sọ fún àwọn òkè gíga pé, “Bò wá mọ́lẹ̀!” àti fún àwọn òkè kéékèèké pé, “Ṣubú lù wá!”
Kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru gwĩkagĩrwo waganu nĩgũkanangwo, na nĩkuo kwene wĩhia wa Isiraeli. Mĩigua na mahiũ ma nyeki-inĩ nĩcio igaakũra kuo, nacio ihumbĩre igongona ciao. Nao andũ nĩmakeera irĩma atĩrĩ, “Tũhumbĩrei!” na macooke meere tũrĩma atĩrĩ, “Tũgwĩrei!”
9 “Láti ìgbà Gibeah, ni ó ti ṣẹ̀, ìwọ Israẹli, ìwọ sì tún wà níbẹ̀. Ǹjẹ́ ogun kò lé ẹ̀yin aṣebi ni Gibeah bá bí?
“Wee Isiraeli-rĩ, kuuma o matukũ-inĩ ma Gibea ũtũũrĩte wĩhagia, na ũguo noguo ũtũũraga. Githĩ mbaara ndĩakinyĩire eeki ũũru kũu Gibea?
10 Nígbà tó bá tẹ́ mi lọ́rùn, èmi yóò fi ìyà jẹ wọ́n; Orílẹ̀-èdè yóò kó ra wọn jọ, wọ́n ó sì dojúkọ wọn, láti fi wọn sínú ìdè nítorí ìlọ́po ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Rĩrĩa niĩ ngenda, nĩngamaherithia; ndũrĩrĩ nĩigacookanĩrĩra, imokĩrĩre nĩguo imoohe imatahe nĩ ũndũ wa mehia mao kũingĩha.
11 Efraimu jẹ́ ọmọ abo màlúù tí a tí kọ́, to si fẹ́ràn láti máa pa ọkà; lórí ọrun rẹ̀ tó lẹ́wà ni èmi ó dí ẹrù wúwo lé. Èmi yóò mú kí a gun Efraimu bí ẹṣin Juda yóò tú ilẹ̀, Jakọbu yóò sì fọ́ ògúlùtu rẹ̀.
Efiraimu nĩ moori menyerie wĩra ĩrĩa yendete gũkonyora ngano; nĩ ũndũ ũcio nĩngamĩoha icooki ngingo-inĩ yayo thaka. Nĩngatwarithia Efiraimu, Juda no nginya agaacimba na mũraũ, nake Jakubu no nginya agaacimba gĩtira.
12 Ẹ gbin òdòdó fún ara yín, kí ẹ sì ká èso ìfẹ́ àìlópin. Ẹ tu ilẹ̀ yín tí a kò ro, nítorí pé ó ti tó àsìkò láti wá Olúwa, títí tí yóò fi dé, tí yóò sì rọ òjò òdodo lé yín lórí.
Rĩu-rĩ, mwĩhaandĩrei ũhoro wa ũthingu, nĩguo mwĩgethere maciaro ma wendo ũtathiraga, na mũciimbe mĩgũnda yanyu ya ngamba; nĩgũkorwo ihinda nĩ ikinyu rĩa kũrongooria Jehova, nginya rĩrĩa agooka, oirie mbura ya ũthingu igũrũ rĩanyu.
13 Ṣùgbọ́n ẹ tí gbin búburú ẹ si ka ibi, ẹ ti jẹ èso èké nítorí ẹ tí gbẹ́kẹ̀lé agbára yín àti àwọn ọ̀pọ̀ jagunjagun yín,
No rĩrĩ, inyuĩ mũhaandĩte waganu, mũkagetha ũũru; inyuĩ mũrĩĩte maciaro ma maheeni. Tondũ mwĩhokaga hinya wanyu inyuĩ ene, o na wa njamba cianyu nyingĩ cia ita-rĩ,
14 ariwo ogun yóò bo àwọn ènìyàn yín kí gbogbo odi agbára yín ba le parun. Gẹ́gẹ́ bí Ṣalmani ṣe pa Beti-Arbeli run lọ́jọ́ ogun, nígbà tí a gbé àwọn ìyá ṣánlẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn.
mũrurumo wa mbaara nĩũgokĩrĩra andũ aku. Nĩ ũndũ ũcio ciikaro ciaku iria nũmu nĩikaanangwo, o ta ũrĩa Shalimani aanangire Bethi-Arabeli mũthenya ũrĩa wa mbaara, rĩrĩa manyina ma twana maatungumanirio thĩ hamwe na twana twao.
15 Báyìí ni a o sì ṣe sí ọ, ìwọ Beteli, nítorí pé ìwà búburú yín ti pọ̀jù. Ní àfẹ̀mọ́júmọ́ ọjọ́ náà, a o pa ọba Israẹli run pátápátá.
Ũguo noguo ũgeekwo wee Betheli, nĩ ũndũ wa waganu waku mũnene. Rĩrĩa mũthenya ũcio ũgaakĩa-rĩ, mũthamaki wa Isiraeli nĩakaniinwo biũ.

< Hosea 10 >