< Hosea 10 >

1 Israẹli jẹ́ igi àjàrà tó gbilẹ̀ ó ń so èso fún ara rẹ̀. Bí èso rẹ̀ ṣe ń pọ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó ń kọ́ pẹpẹ sí i bí ilẹ̀ rẹ̀ ṣe ń ṣe rere o bu ọlá fún òkúta ìyàsọ́tọ̀ ère rẹ̀.
Israël est une vigne dépouillée. On lui avait prodigué les fruits: à mesure que ses fruits augmentaient, il multipliait les autels; plus son pays était prospère, plus ils érigeaient de belles stèles.
2 Ọkàn wọn kún fún ìtànjẹ báyìí wọ́n gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn. Olúwa yóò wó pẹpẹ wọn palẹ̀ yóò sì pa gbogbo òkúta ìyàsọ́tọ̀ wọn run.
Leur cœur s’est partagé, ils en portent la peine maintenant; Lui-même abattra leurs autels, ruinera leurs stèles.
3 Nígbà náà ni wọn yóò wí pé, “A kò ní ọba nítorí tí a kò bọ̀wọ̀ fún Olúwa ṣùgbọ́n bí a tilẹ̀ ní ọba, kí ni yóò ṣe fún wa?”
Ils disent bien à présent: "De roi, nous n’en avons point! Car nous ne craignons pas l’Eternel, et le roi, à quoi peut-il nous servir?"
4 Wọ́n ṣe ìlérí púpọ̀, wọ́n ṣe ìbúra èké, wọ́n da májẹ̀mú; báyìí ni ìdájọ́ hù sókè bí igi ìwọ̀ ni aporo oko, bi i koríko májèlé láàrín oko tí a ro.
Ils débitent de vains discours, des serments frauduleux, contractent des alliances, et le droit est comme une plante vénéneuse poussant dans les sillons des champs.
5 Àwọn ènìyàn tí ń gbé Samaria bẹ̀rù nítorí ère abo màlúù tó wà ní Beti-Afeni. Àwọn ènìyàn rẹ̀ yóò ṣọ̀fọ̀ le e lórí bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà rẹ̀. Gbogbo àwọn tó láyọ̀ sì dídán rẹ̀, nítorí tí a ti mú lọ sí ìgbèkùn.
Pour le veau de Beth-Awên, les habitants de Samarie tremblent; oui, ses fidèles sont en deuil à son sujet, ainsi que ses prêtres qui naguère se réjouissaient en lui; car le voilà dépouillé de son éclat.
6 A ó gbé lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn fún ọba ńlá a ó dójútì Efraimu; ojú yóò ti Israẹli nítorí ìgbìmọ̀ rẹ̀.
Lui-même, on le transporte en Assyrie, comme présent au roi Protecteur; Ephraïm en recueille la honte, Israël est confus de sa résolution.
7 Bí igi tó léfòó lórí omi ni Samaria àti àwọn ọba rẹ yóò sàn lọ.
Samarie est réduite à rien de même que son roi, tel un morceau de bois à la surface de l’eau.
8 Àwọn ibi gíga tí ẹ tí ń hùwà búburú ni a o parun, èyí ni ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli. Ẹ̀gún ọ̀gàn àti ẹ̀gún òṣùṣú yóò hù jáde, yóò sì bo àwọn pẹpẹ wọn. Wọn yóò sọ fún àwọn òkè gíga pé, “Bò wá mọ́lẹ̀!” àti fún àwọn òkè kéékèèké pé, “Ṣubú lù wá!”
Les hauts-lieux criminels, le péché visible d’Israël, sont détruits; des ronces et des chardons poussent sur leurs autels. Alors ils diront aux montagnes: "Recouvrez-nous!" et aux collines: "Tombez sur nous!"
9 “Láti ìgbà Gibeah, ni ó ti ṣẹ̀, ìwọ Israẹli, ìwọ sì tún wà níbẹ̀. Ǹjẹ́ ogun kò lé ẹ̀yin aṣebi ni Gibeah bá bí?
Plus qu’aux jours de Ghibea, tu as prévariqué, ô Israël! S’Ils s’étaient trouvés là, n’auraient-ils pas été atteints à Ghibea par la guerre dirigée contre les fils de l’iniquité?
10 Nígbà tó bá tẹ́ mi lọ́rùn, èmi yóò fi ìyà jẹ wọ́n; Orílẹ̀-èdè yóò kó ra wọn jọ, wọ́n ó sì dojúkọ wọn, láti fi wọn sínú ìdè nítorí ìlọ́po ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Au gré de mon désir, je veux les châtier; ils verront des peuples s’attrouper contre eux, pour s’être attachés à leurs deux péchés.
11 Efraimu jẹ́ ọmọ abo màlúù tí a tí kọ́, to si fẹ́ràn láti máa pa ọkà; lórí ọrun rẹ̀ tó lẹ́wà ni èmi ó dí ẹrù wúwo lé. Èmi yóò mú kí a gun Efraimu bí ẹṣin Juda yóò tú ilẹ̀, Jakọbu yóò sì fọ́ ògúlùtu rẹ̀.
Ephraïm est une génisse bien dressée, aimant à fouler le blé; mais moi, je passerai sur son cou superbe, je ferai atteler Ephraïm; il faudra que Juda laboure, que Jacob traîne la herse.
12 Ẹ gbin òdòdó fún ara yín, kí ẹ sì ká èso ìfẹ́ àìlópin. Ẹ tu ilẹ̀ yín tí a kò ro, nítorí pé ó ti tó àsìkò láti wá Olúwa, títí tí yóò fi dé, tí yóò sì rọ òjò òdodo lé yín lórí.
Faites vos semailles selon la justice et vous moissonnerez selon la loi d’amour; tracez-vous des sillons. C’Est l’heure de se mettre en quête de l’Eternel, pour qu’il vienne verser sur vous le salut.
13 Ṣùgbọ́n ẹ tí gbin búburú ẹ si ka ibi, ẹ ti jẹ èso èké nítorí ẹ tí gbẹ́kẹ̀lé agbára yín àti àwọn ọ̀pọ̀ jagunjagun yín,
Mais vous avez cultivé l’iniquité et récolté le mal; vous avez mangé le fruit de la tromperie; car tu as eu confiance en ta conduite, dans la multitude de tes guerriers.
14 ariwo ogun yóò bo àwọn ènìyàn yín kí gbogbo odi agbára yín ba le parun. Gẹ́gẹ́ bí Ṣalmani ṣe pa Beti-Arbeli run lọ́jọ́ ogun, nígbà tí a gbé àwọn ìyá ṣánlẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn.
Aussi le tumulte de la guerre éclatera-t-il contre tes troupes, et toutes tes forteresses seront-elles ruinées, comme Salmân a détruit Beth-Arbêl au jour du combat, où les mères furent écrasées avec leurs enfants.
15 Báyìí ni a o sì ṣe sí ọ, ìwọ Beteli, nítorí pé ìwà búburú yín ti pọ̀jù. Ní àfẹ̀mọ́júmọ́ ọjọ́ náà, a o pa ọba Israẹli run pátápátá.
Voilà le sort que vous prépare Béthel, à cause de l’excès de votre perversité. Dès le lever de l’aurore, c’en est complètement fini du roi d’Israël.

< Hosea 10 >