< Hosea 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
آحاز و حزقیا پادشاهان یهودا و در ایام یربعام بن یوآش پادشاه اسرائیل، بر هوشع بن بئیری نازل شد.۱
2 Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
ابتدای کلام خداوند به هوشع. خداوند به هوشع گفت: «برو و زنی زانیه و اولاد زناکار برای خود بگیر زیرا که این زمین از خداوند برگشته، سخت زناکار شده‌اند.»۲
3 Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
پس رفت و جومر دختردبلایم را گرفت و او حامله شده، پسری برایش زایید.۳
4 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
و خداوند وی را گفت: «او را یزرعیل نام بنه زیرا که بعد از اندک زمانی انتقام خون یزرعیل را از خاندان ییهو خواهم گرفت و مملکت خاندان اسرائیل را تلف خواهم ساخت.۴
5 Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
و در آن روزکمان اسرائیل را در وادی یزرعیل خواهم شکست.»۵
6 Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
پس بار دیگر حامله شده، دختری زایید و اووی را گفت: «او را لوروحامه نام بگذار، زیرا باردیگر بر خاندان اسرائیل رحمت نخواهم فرمود، بلکه ایشان را از میان بالکل خواهم برداشت.۶
7 Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
لیکن بر خاندان یهودا رحمت خواهم فرمود وایشان را به یهوه خدای ایشان نجات خواهم داد وایشان را به کمان و شمشیر و جنگ و اسبان وسواران نخواهم رهانید.»۷
8 Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
و چون لوروحامه را از شیر بازداشته بود، حامله شده، پسری زایید.۸
9 Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
و او گفت: «نام او رالوعمی بخوان زیرا که شما قوم من نیستید و من (خدای ) شما نیستم.۹
10 “Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
لیکن شماره بنی‌اسرائیل مثل ریگ دریا خواهد بود که نتوان پیمود و نتوان شمرد و در مکانی که به ایشان گفته می‌شد شماقوم من نیستید، در آنجا گفته خواهد شد پسران خدای حی می‌باشید.۱۰
11 Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.
و بنی یهودا وبنی‌اسرائیل با هم جمع خواهند شد و یک رئیس به جهت خود نصب نموده، از آن زمین برخواهندآمد زیرا که روز یزرعیل، روز عظیمی خواهدبود.»۱۱

< Hosea 1 >