< Hosea 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
Wach Jehova Nyasaye mane obiro ne Hosea wuod Beeri e ndalo loch Uzia, gi Jotham gi Ahaz kod Hezekia, ruodhi mag Juda, e ndalo loch Jeroboam wuod Jehoash ruodh Israel.
2 Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
Kane Jehova Nyasaye ochako miyo Hosea wachne monego owachi, Jehova Nyasaye nowachone niya, “Dhiyo ikend dhako ma jachode kendo inywol kode nyithindo mag dwanyruokne, nikech piny oseketho kotimo richo mar chode marachie moloyo mi giseweyo Jehova Nyasaye.”
3 Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
Omiyo Hosea nodhi mokendo Gomer nyar Diblaim, mine omako ich monywolone wuowi.
4 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
Eka Jehova Nyasaye nowachone Hosea niya, “Chak nyathi nying ni Jezreel nikech achiegni kumo dhood Jehu kuom nek mane otimore Jezreel kendo adhi tieko pinyruoth mar Israel.
5 Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
E odiechiengno abiro ketho atungʼ mar pinyruodh Israel e Holo mar Jezreel.”
6 Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
Gomer ne omako ich kendo mi onywolo nyathi ma nyako. Eka Jehova Nyasaye nowachone Hosea niya, “Luonge ni Lo-Ruhama nimar ok abi achak anyis hera ni dhood Israel kata mana ngʼwononegi.
7 Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
Kata kamano, abiro nyiso herana ne dhood Juda kendo abiro resogi to ok abi resogi gi atungʼ, kata ligangla kata gige lweny kata gi farese kata gi jomoidho farese, to an Jehova Nyasaye ma Nyasachgi ema anaresgi.”
8 Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
Bangʼ kane Gomer oseweyo dhodho Lo-Ruhama, nonywolo nyathi machielo ma wuowi.
9 Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
Eka Jehova Nyasaye nowacho niya, “Luonge ni Lo-Ami nimar ok un joga, An bende ok An Nyasachu.
10 “Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
“To kata obedo kamano, jo-Israel nobed mathoth ka kwoyo manie dho nam ma ok nyal pim kata kwano. Kama ne owachnegi ni, ‘Ok un joga,’ ibiro luongogi ni ‘yawuot Nyasaye mangima.’
11 Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.
Jo-Juda gi jo-Israel nochak riwre kendo giniyier jatelo achiel kendo giniwuogi ka gia e pinje mane ginie wasumbini nimar odiechiengʼ mar Jezreel nobed maduongʼ miwuoro.”

< Hosea 1 >