< Hebrews 8 >
1 Nísinsin yìí, kókó ohun tí à ń sọ nìyí. Àwa ní irú olórí àlùfáà bẹ́ẹ̀, tí ó jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún ìtẹ́ Ọláńlá nínú àwọn ọ̀run,
ⲁ̅⳿ⲡⲕⲉⲫⲁⲗⲉⲟⲛ ⲇⲉ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲏⲉⲧⲉⲛϫⲱ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲟⲩⲁⲣⲭⲏⲉⲣⲉⲩⲥ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲉⲧⲉⲛⲧⲁⲛ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲫⲏⲉⲧⲁϥϩⲉⲙⲥⲓ ⲥⲁⲟⲩ⳿ⲓⲛⲁⲙ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲑⲣⲟⲛⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲙⲉⲧⲛⲓϣϯ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ.
2 Ìránṣẹ́ ibi mímọ́, àti ti àgọ́ tòótọ́, tí Olúwa pa, kì í ṣe ènìyàn.
ⲃ̅⳿ⲛⲣⲉϥϯⲫⲱϣⲉⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲏⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⲛⲉⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ϯ⳿ⲥⲕⲏⲛⲏ ⳿ⲙⲙⲏⲓ ⲑⲏ ⲉⲧⲁ Ⲡ⳪ ⲧⲁϫⲣⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲣⲱⲙⲓ ⲁⲛ.
3 Nítorí a fi olórí àlùfáà kọ̀ọ̀kan jẹ láti máa mú ẹ̀bùn wá láti máa rú ẹbọ, nítorí náà ó ṣe pàtàkì fún eléyìí náà láti ní nǹkan tí ó máa fi sílẹ̀.
ⲅ̅ⲁⲣⲭⲏⲉⲣⲉⲩⲥ ⲅⲁⲣ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉϣⲁⲩⲭⲁϥ ⲉⲑⲣⲉϥ⳿ⲉⲛ ⲧⲁⲓⲟ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⲛⲉⲙ ϣⲟⲩϣⲱⲟⲩϣⲓ ⲉⲑⲃⲉⲫⲁⲓ ⲟⲩⲁⲛⲁⲅⲕⲉⲟⲛ ⲡⲉ ⲉⲑⲣⲉ ⲟⲩⲉⲛⲭⲁⲓ ϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲫⲁⲓ ⲉⲑⲣⲉϥ⳿ⲉⲛϥ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ.
4 Tí ó bá jẹ́ pé ó wà ní ayé ni, òun kì bá ti jẹ́ àlùfáà, nítorí pé àwọn ọkùnrin tí ó ń fi ẹ̀bùn sílẹ̀ ti wà bí òfin ṣe là á sílẹ̀.
ⲇ̅ⲓⲥϫⲉ ⲙⲉⲛ ⲟⲩⲛ ⲛⲁϥϩⲓϫⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⲓⲉ ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲩⲏⲃ ⲁⲛ ⲡⲉ ⲉⲩϣⲟⲡ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲏⲉⲧⲉⲛ ⲇⲱⲣⲟⲛ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⲕⲁⲧⲁ ⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ.
5 Àwọn ẹni tí ń jọ́sìn nínú pẹpẹ kan tí ó jẹ́ àpẹẹrẹ àti òjìji ohun tí ń bẹ ní ọ̀run. Ìdí abájọ nìyí tí a fi kìlọ̀ fún Mose nígbà tí ó fẹ́ kọ́ àgọ́, nítorí ó wí pé, “Kíyèsí i, kí ìwọ kí ó ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ wọn, ti a fi hàn ọ́ ni orí òkè.”
ⲉ̅ⲛⲁⲓ ⲉⲧϣⲉⲙϣⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲥⲙⲟⲧ ⲛⲉⲙ ⲟⲩϧⲏ ⲓⲃⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲁ ⳿ⲧⲫⲉ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲁⲩⲧⲁⲙⲉ ⲙⲱ⳿ⲩⲥⲏⲥ ⲉϥⲛⲁϫⲱⲕ ⳿ⲛϯ⳿ⲥⲕⲏⲛⲏ ⳿ⲁⲛⲁⲩ ⲅⲁⲣ ⲡⲉϫⲁϥ ⲉⲕ⳿ⲉⲑⲁⲙⲓⲟ ⳿ⲛϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲕⲁⲧⲁ ⲡⲓⲧⲩⲡⲟⲥ ⲉⲧⲁⲩⲧⲁⲙⲟⲕ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓⲧⲱⲟⲩ.
6 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí o ti gba iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí ó ni ọlá jù, níwọ̀n bí o ti jẹ pé alárinà májẹ̀mú tí o dára jù ní i ṣe, èyí tí a fi ṣe òfin lórí ìlérí tí o sàn jù bẹ́ẹ̀ lọ.
ⲋ̅ϯⲛⲟⲩ ⲇⲉ ⲁ ⲧⲟⲧϥ ϯⲙⲁϯ ⳿ⲉⲟⲩⲫⲁϣⲛⲓ ⲉⲥⲥⲟⲧⲡ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲟⲛ ⲉⲧⲉϥⲟⲓ ⳿ⲙⲙⲉⲥⲓⲧⲏ ⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲇⲓ⳿ⲁⲑⲏⲕⲏ ⲉⲥⲥⲟⲧⲡ ⲑⲏ ⲉⲧⲁⲩⲥⲉⲙⲛⲏ ⲧⲥ ⳿ⲛⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ϩⲁⲛⲱϣ ⲉⲩⲥⲱⲧⲡ.
7 Nítorí ìbá ṣe pé májẹ̀mú ìṣáájú nì kò ní àbùkù, ǹjẹ́ a kì bá ti wá ààyè fún èkejì.
ⲍ̅⳿ⲉⲛⲁⲣⲉ ϯϩⲟⲩⲓϯ ⲅⲁⲣ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲧⲁⲣⲓⲕⲓ ⲛⲁⲩⲛⲁⲕⲱϯ ⲁⲛ ⲡⲉ ⳿ⲛⲥⲁ ⳿ⲫⲙⲁ ⳿ⲛϯⲙⲁϩⲃ̅ϯ.
8 Nítorí tí ó rí àbùkù lára wọn, ó wí pé, “Ìgbà kan ń bọ̀, ni Olúwa wí, tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
ⲏ̅ⲉϥϫⲉⲙ ⲁⲣⲓⲕⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲓⲥ ϩⲁⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲥⲉⲛⲁⲏⲟⲩ ⲡⲉϫⲉ Ⲡ⳪ ϯⲛⲁϫⲱⲕ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⳿ⲡⲏⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡⲓⲥ̅ⲗ̅ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⳿ⲡⲏⲓ ⳿ⲛⲓⲟⲩⲇⲁ ⳿ⲛⲟⲩⲇⲓ⳿ⲁⲑⲏⲕⲏ ⳿ⲙⲃⲉⲣⲓ.
9 Kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mú tí mo ti bá àwọn baba baba wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́ láti mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, nítorí wọn kò jẹ́ olóòtítọ́ sí májẹ̀mú mi èmi kò sì ta wọ́n nu, ni Olúwa wí.
ⲑ̅ⲕⲁⲧⲁ ϯⲇⲓ⳿ⲁⲑⲏⲕⲏ ⲁⲛ ⳿ⲉⲧⲁⲓⲥⲉⲙⲛⲏⲧⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲟⲩⲓⲟϯ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲉⲧⲁⲓⲁⲙⲁϩⲓ ⳿ⲛⲧⲟⲩϫⲓϫ ⳿ⲉ⳿ⲉⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⳿ⲛⲭⲏⲙⲓ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲟⲩⲟϩⲓ ϧⲉⲛ ⲧⲁⲇⲓ⳿ⲁⲑⲏⲕⲏ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲇⲉ ⲁⲓⲉⲣⲁⲙⲉⲗⲉⲥ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲡⲉϫⲉ Ⲡ⳪.
10 Nítorí èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, ni Olúwa wí. Èmi ó fi òfin mi sí inú wọn, èmi ó sì kọ wọ́n sí ọkàn wọn, èmi ó sì máa jẹ́ Ọlọ́run fún wọn, wọn ó sì máa jẹ́ ènìyàn fún mi.
ⲓ̅ϫⲉ ⲑⲁⲓ ⲧⲉ ⲧⲁⲇⲓ⳿ⲁⲑⲏⲕⲏ ⳿ⲉϯⲛⲁⲥⲉⲙⲛⲏ ⲧⲥ ⲛⲉⲙ ⳿ⲡⲏⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡⲓⲥ̅ⲗ̅ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲛⲁⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲡⲉϫⲉ Ⲡ⳪ ⲉⲓ⳿ⲉϯ ⳿ⲛⲛⲁ ⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲟⲩⲙⲉⲩⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲓ⳿ⲉ⳿ⲥϧⲏⲧⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲟⲩϩⲏⲧ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲉⲓ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲟⲩϯ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ϩⲱⲟⲩ ⲉⲩ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲛⲏⲓ ⲉⲩⲗⲁⲟⲥ.
11 Olúkúlùkù kò ní tún máa kọ́ ara ìlú rẹ̀, tàbí olúkúlùkù arákùnrin rẹ̀, pé, ‘Mọ Olúwa,’ nítorí pé gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí, láti kékeré dé àgbà.
ⲓ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲛⲉ ⳿ⲫⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲫⲟⲩⲁⲓ ϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛⲛⲉϥⲣⲉⲙ⳿ⲙⲃⲁⲕⲓ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲉϥⲥⲟⲛ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲥⲟⲩⲉⲛ Ⲡ⳪ ϫⲉ ⲥⲉⲛⲁⲥⲟⲩⲱⲛⲧ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲡⲟⲩⲕⲟⲩϫⲓ ϣⲁ ⲡⲟⲩⲛⲓϣϯ.
12 Nítorí pé èmi ó ṣàánú fún àìṣòdodo wọn, àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn àti àìṣedéédéé wọn lèmi ki yóò sì rántí mọ́.”
ⲓ̅ⲃ̅ϫⲉ ϯⲛⲁⲭⲱ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲙⲉⲧϭⲓ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲛⲁⲉⲣ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ϫⲉ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲛⲟⲃⲓ.
13 Ní èyí tí ó wí pé, májẹ̀mú títún ó ti sọ ti ìṣáájú di ti láéláé. Ṣùgbọ́n èyí tí ó ń di i ti láéláé tí ó sì ń gbó, o múra àti di asán.
ⲓ̅ⲅ̅ϧⲉⲛ ⳿ⲡϫⲓⲛϫⲟⲥ ϫⲉ ⲟⲩⲃⲉⲣⲓ ⲓⲉ ⲁϥⲉⲣ ϯϩⲟⲩⲓϯ ⳿ⲛⲁⲡⲁⲥ ⲫⲏ ⲇⲉ ⳿ⲉϣⲁϥⲉⲣⲁⲡⲁⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲉⲣϧⲉⲗⲗⲟ ⳿ϥϧⲉⲛⲧ ⳿ⲉ⳿ⲡⲧⲁⲕⲟ