< Hebrews 7 >

1 Nítorí Melkisedeki yìí, ọba Salẹmu, àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, ẹni tí ó pàdé Abrahamu bí ó ti ń padà bọ̀ láti ibi pípa àwọn ọba, tí ó sì súre fún un,
En effet, ce Melchisédec, roi de Salem, sacrificateur du Dieu Très-Haut, qui alla au-devant d'Abraham, lorsqu'il revenait de la défaite des rois, et qui le bénit;
2 ẹni tí Abrahamu sì pín ìdámẹ́wàá ohun gbogbo fún. Ní ọ̀nà èkínní orúkọ rẹ̀ túmọ̀ sí “ọba òdodo”; àti lẹ́yìn náà pẹ̀lú, “ọba Salẹmu,” tí í ṣe “ọba àlàáfíà.”
auquel Abraham donna la dîme de tout; qui, d'après la signification de son nom, était, premièrement roi de justice, et qui, de plus, était, roi de Salem, c'est-à-dire, roi de paix;
3 Láìní baba, láìní ìyá, láìní ìtàn ìran, bẹ́ẹ̀ ni kò ní ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ tàbí òpin ọjọ́ ayé; ṣùgbọ́n a ṣe é bí Ọmọ Ọlọ́run; ó wà ní àlùfáà títí.
sans père, sans mère, sans généalogie; qui n'a ni commencement de jours, ni fin de vie, et qui est ainsi rendu semblable au Fils de Dieu, — ce Melchisédec demeure sacrificateur à perpétuité.
4 Ǹjẹ́ ẹ gbà á rò bí ọkùnrin yìí ti pọ̀ tó, ẹni tí Abrahamu baba ńlá fi ìdámẹ́wàá nínú àwọn àṣàyàn ìkógun fún.
Considérez combien grand est celui à qui Abraham lui-même, le patriarche, donna une dîme prise sur le meilleur du butin.
5 Àti nítòótọ́ àwọn tí ó jẹ́ ọmọ Lefi, tí o gba oyè àlùfáà, wọ́n ní àṣẹ láti máa gba ìdámẹ́wàá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí òfin, èyí yìí, lọ́wọ́ àwọn arákùnrin wọn, bí ó tilẹ̀ ti jẹ́ pé, wọn ti inú Abrahamu jáde.
Ceux des fils de Lévi qui reçoivent la sacrificature, ont, l'ordre, d'après la loi, de lever la dîme sur le peuple, c'est-à-dire sur leurs frères, qui pourtant sont issus eux-mêmes d'Abraham.
6 Ṣùgbọ́n òun ẹni tí a kò tilẹ̀ pìtàn ìran rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ wọn wá, gba ìdámẹ́wàá lọ́wọ́ Abrahamu, ó sì súre fún ẹni tí ó gba ìlérí,
Mais lui, qui n'était pas de la même famille, reçut d'Abraham la dîme et bénit celui qui possédait les promesses.
7 láìsí ìjiyàn rárá ẹni kò tó ẹni tí à ń súre fún láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ju ni.
Or, sans contredit, c'est l'inférieur qui est béni par le supérieur.
8 Ni apá kan, àwọn ẹni kíkú gba ìdámẹ́wàá; ṣùgbọ́n níbẹ̀, ẹni tí a jẹ́rìí rẹ̀ pé o ń bẹ láààyè nì.
De plus, ici, ce sont des hommes mortels qui prélèvent la dîme; là, c'est celui au sujet duquel l'Écriture atteste qu'il est, vivant.
9 Àti bí a ti lè wí, Lefi pàápàá tí ń gba ìdámẹ́wàá, ti san ìdámẹ́wàá nípasẹ̀ Abrahamu.
Et l'on peut dire que ce Lévi, qui prélève la dîme, l'a payée lui-même dans la personne d'Abraham;
10 Nítorí o sá à sì ń bẹ ní inú baba rẹ̀, nígbà ti Melkisedeki pàdé rẹ̀.
car il était encore dans les reins de son père, lorsque Melchisédec vint au-devant du patriarche.
11 Ǹjẹ́ ìbá ṣe pé pípé ń bẹ nípa oyè àlùfáà Lefi (nítorí pé lábẹ́ rẹ̀ ni àwọn ènìyàn gba òfin), kín ni ó sì tún kù mọ́ tí àlùfáà mìíràn ìbá fi dìde ní títẹ̀lé àpẹẹrẹ tí Melkisedeki, tí a kò si wí pé ní títẹ̀lé àpẹẹrẹ tí Aaroni?
Si la perfection avait pu être atteinte par le sacerdoce lévitique — car la législation donnée au peuple a pour base ce sacerdoce, — qu'était-il encore besoin qu'il parût un autre sacrificateur, institué selon l'ordre de Melchisédec, et non selon l'ordre d'Aaron?
12 Nítorí pé bí a ti ń pààrọ̀ iṣẹ́ àlùfáà, a kò sì lè ṣàì máa pààrọ̀ òfin.
Le sacerdoce étant changé, il doit y avoir nécessairement, un changement de loi.
13 Nítorí ẹni tí à ń sọ̀rọ̀ nǹkan wọ̀nyí nípa rẹ̀ jẹ́ ẹ̀yà mìíràn, láti inú èyí tí ẹnikẹ́ni kò tì jọ́sìn rí níbi pẹpẹ.
En effet, celui à qui s'appliquent ces paroles appartient, à une autre tribu, dont aucun membre n'a été attaché au service de l'autel.
14 Nítorí ó hàn gbangba pé láti inú ẹ̀yà Juda ni Olúwa wa ti dìde; nípa ẹ̀yà yìí Mose kò sọ ohunkóhun ní ti àwọn àlùfáà.
Car il est notoire que notre Seigneur est issu de Juda, tribu dont, Moïse n'a rien dit, en ce qui touche le sacerdoce.
15 Ó sì tún hàn gbangba ju bẹ́ẹ̀ lọ bí ó ti jẹ pé àlùfáà mìíràn dìde ní àpẹẹrẹ ti Melkisedeki.
Tout cela devient encore plus évident, quand nous voyons s'élever, à la ressemblance de Melchisédec, un autre sacrificateur,
16 Èyí tí a fi jẹ́, kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí ìlànà òfin nípa ti ara, bí kò ṣe nípa agbára ti ìyè àìlópin.
établi non d'après la règle d'une ordonnance charnelle, mais par la puissance d'une vie impérissable.
17 Nítorí a jẹ́rìí pé: “Ìwọ ni àlùfáà títí láé ní ipasẹ̀ ti Melkisedeki.” (aiōn g165)
Voici, en effet, le témoignage qui lui est rendu: «Tu es sacrificateur pour l'éternité, selon l'ordre de Melchisédec.» (aiōn g165)
18 Nítorí a mú òfin ìṣáájú kúrò nítorí àìlera àti àìlérè rẹ̀.
Ainsi, l'ordonnance antérieure a été abolie à cause de son impuissance et de son inutilité.
19 (Nítorí òfin kò mú ohunkóhun pé), a sì mú ìrètí tí ó dára jù wá nípa èyí tí àwa ń súnmọ́ Ọlọ́run.
En effet, la loi n'a rien amené à la perfection, et à sa place a été introduite une meilleure espérance, grâce à laquelle nous nous approchons de Dieu.
20 Níwọ́n bí ó sì ti ṣe pé kì í ṣe ní àìbúra ni. Nítorí àwọn àlùfáà tẹ́lẹ̀ jẹ oyè láìsí ìbúra,
De plus, ce changement ne s'est pas accompli sans serment.
21 ṣùgbọ́n ti òun jẹ́ pẹ̀lú ìbúra nígbà tí Ọlọ́run wí fún un pé, “Olúwa búra, kí yóò sì yí padà: ‘Ìwọ ni àlùfáà kan títí láé.’” (aiōn g165)
Les autres sacrificateurs furent institués sans serment; mais lui, il l'a été avec serment, par celui qui lui a dit: «Le Seigneur l'a juré, et il ne s'en repentira point: tu es sacrificateur pour l'éternité!» (aiōn g165)
22 Níwọ́n bẹ́ẹ̀ ni Jesu ti di onígbọ̀wọ́ májẹ̀mú tí ó dára jù.
Aussi Jésus est-il devenu le garant d'une alliance de beaucoup supérieure à la première.
23 Àti nítòótọ́ àwọn púpọ̀ ní a ti fi jẹ àlùfáà, nítorí wọn kò lè wà títí nítorí ikú.
En outre, il y a eu un grand nombre de sacrificateurs, parce que la mort les empêchait de conserver toujours leurs fonctions.
24 Ṣùgbọ́n òun, nítorí tí o wà títí láé, ó ní oyè àlùfáà tí a kò lè rọ̀ ní ipò. (aiōn g165)
Mais lui, parce qu'il subsiste éternellement, possède le sacerdoce qui ne se transforme point. (aiōn g165)
25 Nítorí náà ó sì le gbà wọ́n là pẹ̀lú títí dé òpin, ẹni tí ó bá tọ Ọlọ́run wá nípasẹ̀ rẹ̀, nítorí tí o ń bẹ láààyè títí láé láti máa bẹ̀bẹ̀ fún wọn.
Et c'est pour cela qu'il peut sauver parfaitement ceux qui s'approchent de Dieu par lui, étant toujours vivant pour intercéder en leur faveur.
26 Nítorí pé irú olórí àlùfáà bẹ́ẹ̀ ni o yẹ wá, mímọ́, àìlẹ́gàn, àìléèérí, tí a yà sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, tí a sì gbéga ju àwọn ọ̀run lọ.
C'était bien là le souverain sacrificateur qu'il nous fallait, saint, innocent, exempt de souillure, séparé des pécheurs, et élevé au-dessus des cieux.
27 Ẹni tí kò ní láti máa rú ẹbọ lójoojúmọ́, bí àwọn olórí àlùfáà, fún ẹ̀ṣẹ̀ ti ara rẹ̀ náà, àti lẹ́yìn náà fún tí àwọn ènìyàn; nítorí èyí ni tí ó ṣe lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, nígbà tí ó fi ara rẹ̀ rú ẹbọ.
Il n'a pas besoin, comme les autres souverains sacrificateurs, d'offrir tous les jours des sacrifices, d'abord pour ses propres péchés, ensuite pour ceux du peuple: il a fait cela une fois pour toutes, en s'offrant lui-même.
28 Nítorí pé òfin a máa fi àwọn ènìyàn tí ó ní àìlera jẹ olórí àlùfáà; ṣùgbọ́n nípa ọ̀rọ̀ ti ìbúra, tí ó ṣe lẹ́yìn òfin, ó fi ọmọ jẹ; ẹni tí a sọ di pípé títí láé. (aiōn g165)
Car la loi établit comme souverains sacrificateurs des hommes sujets à la faiblesse; mais la parole du serment qui a été fait après la loi, établit le Fils, qui est parvenu pour toujours à la perfection. (aiōn g165)

< Hebrews 7 >