< Hebrews 6 >

1 Nítorí náà, ó yẹ kí á fi àwọn ẹ̀kọ́ ìgbà tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ gba Kristi sílẹ̀, kí á tẹ̀síwájú nínú àwọn ẹ̀kọ́ tí yóò mú wa dàgbàsókè ní pípé. Láìtún ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀ máa tẹnumọ́ ẹ̀kọ́ ìpìlẹ̀ bí i ìrònúpìwàdà kúrò nínú òkú iṣẹ́ àti ìgbàgbọ́ nípa ti Ọlọ́run,
Przestańmy więc ciągle wracać do podstaw nauki o Chrystusie, a zajmijmy się sprawami bardziej zaawansowanymi. Czy wciąż mamy zajmować się tylko podstawami wiary, przypominając wam o konieczności odwrócenia się od zła i uwierzenia Bogu,
2 ti ẹ̀kọ́ àwọn bamitiisi, àti ti ìgbọ́wọ́-léni, ti àjíǹde òkú, àti tí ìdájọ́ àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
o chrzcie, nakładaniu rąk, zmartwychwstaniu oraz sądzie ostatecznym? (aiōnios g166)
3 Èyí ní àwa yóò sì ṣe bí Ọlọ́run bá fẹ́.
Zresztą, jeśli taka będzie wola Boga, to wrócimy do nauczania was tych spraw.
4 Nítorí pé, kò ṣe é ṣe fún àwọn tí a ti là lójú lẹ́ẹ̀kan, tí wọ́n sì ti tọ́ ẹ̀bùn ọ̀run wò, tí wọn sì ti di alábápín Ẹ̀mí Mímọ́,
Do nawrócenia nie da się bowiem nakłonić tych, którzy kiedyś już zostali oświeceni przez Boga, posmakowali Jego dobroci, doświadczyli działania Ducha Świętego,
5 tí wọn sì tọ́ ọ̀rọ̀ rere Ọlọ́run wò, àti agbára ayé tí ń bọ̀, (aiōn g165)
zaczęli poznawać słowo Boże i dowiedzieli się o wspaniałym, przyszłym świecie, (aiōn g165)
6 láti tún sọ wọ́n di ọ̀tun sí ìrònúpìwàdà bí wọn bá ṣubú kúrò; nítorí tí wọ́n tún kan Ọmọ Ọlọ́run mọ́ àgbélébùú sí ara wọn lọ́tun, wọ́n sì dójútì í ní gbangba.
a mimo to odwrócili się od Boga. Czyniąc to, na nowo krzyżują bowiem Syna Bożego i wystawiają Go na pośmiewisko.
7 Nítorí ilẹ̀ tí ó ń fa omi òjò tí ń rọ̀ sórí rẹ̀ nígbà gbogbo mu, tí ó sì ń hu ewébẹ̀ tí ó dára fún àwọn tí à ń tìtorí wọn ro ó pẹ̀lú, ń gba ìbùkún lọ́wọ́ Ọlọ́run.
Bóg cieszy się, gdy pole, które zostało obficie nawodnione deszczem, wydaje plon i przynosi pożytek tym, którzy je uprawiają.
8 Ṣùgbọ́n bí ó ba ń hu ẹ̀gún àti òṣùṣú yóò di kíkọ̀sílẹ̀, kò si jìnnà sí fífi gégùn ún, òpin èyí tí yóò wà fún ìjóná.
Ale gdy rodzi tylko chwasty—jest bezużyteczne, przeklęte przez Boga i ostatecznie zostanie wypalone.
9 Ṣùgbọ́n olùfẹ́, àwa ní ohun tí ó dára jù bẹ́ẹ̀ lọ, ní tiyín, àti ohun tí ó fi ara mọ́ ìgbàlà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé à ń ṣe báyìí sọ̀rọ̀.
Kochani, chociaż piszemy wam o tym, to jednak jesteśmy przekonani, że wy przynosicie dobre owoce, godne waszego zbawienia.
10 Nítorí Ọlọ́run kì í ṣe aláìṣòdodo tí yóò fi gbàgbé iṣẹ́ yin àti ìfẹ́ tí ẹ̀yin fihàn sí orúkọ rẹ̀, nípa iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí ẹ ti ṣe fún àwọn ènìyàn mímọ́, tí ẹ sì tún ń ṣe.
Bóg zaś nie postępuje niesprawiedliwie i On nie zapomni o waszej pracy oraz miłości, jaką Mu okazaliście i nadal okazujecie, pomagając innym wierzącym.
11 Àwa sì fẹ́ kí olúkúlùkù yín máa fi irú àìsimi kan náà hàn, fún ẹ̀kún ìdánilójú ìrètí títí dé òpin.
Pragniemy, aby każdy z was był tak gorliwy aż do końca, czyli do dnia, w którym spełni się to, na co teraz z nadzieją czekamy.
12 Kí ẹ má ṣe di onílọ̀ra, ṣùgbọ́n aláfarawé àwọn tí wọn ti ipa ìgbàgbọ́ àti sùúrù jogún àwọn ìlérí.
Nie chcemy bowiem, abyście obniżali sobie poprzeczkę, ale pragniemy, byście naśladowali tych, którzy dzięki wierze i cierpliwości otrzymali od Boga wszystko, co obiecał.
13 Nítorí nígbà tí Ọlọ́run ṣe ìlérí fún Abrahamu, bí kò ti rí ẹni tí ó pọ̀jù òun láti fi búra, ó fi ara rẹ̀ búra, wí pé,
Gdy Bóg składał obietnicę Abrahamowi, powołał się na samego siebie, nie było bowiem nikogo większego niż On.
14 “Nítòótọ́ ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i.”
Obietnica ta brzmiała następująco: „Obdarzę cię wielkim szczęściem i sprawię, że twój ród stanie się wielki”.
15 Bẹ́ẹ̀ náà sì ni, lẹ́yìn ìgbà tí Abrahamu fi sùúrù dúró, ó ri ìlérí náà gbà.
Abraham okazał cierpliwość i doczekał się spełnienia tej obietnicy.
16 Nítorí ènìyàn a máa fi ẹni tí ó pọ̀jù wọ́n lọ búra: ìbúra náà a sì fi òpin sí gbogbo ìjiyàn wọn fún ìfẹ̀sẹ̀ múlẹ̀ ọ̀rọ̀.
Ludzie, chcąc rozwiązać jakiś spór, przysięgają na kogoś większego od siebie.
17 Nínú èyí tí Ọlọ́run, ẹni tí ń fẹ́ gidigidi láti fi àìlèyípadà ète rẹ̀ hàn fún àwọn ajogún ìlérí náà, ó fi ìbúra sáàrín wọn.
Dlatego Bóg, chcąc pokazać, że Jego obietnica jest niepodważalna, również złożył przysięgę.
18 Pé, nípa ohun àìlèyípadà méjì, nínú èyí tí kò le ṣe é ṣe fún Ọlọ́run láti ṣèké, kí a lè mú àwa tí ó ti sá sábẹ́ ààbò rẹ̀ ní ọkàn lè láti di ìrètí tí a gbé kalẹ̀ níwájú wa mú ṣinṣin.
A Bóg nie może złamać swojej obietnicy lub przysięgi! Dzięki temu zapewnieniu możemy więc uchwycić się Jego obietnicy, wierząc, że ją spełni.
19 Èyí tí àwa níbi ìdákọ̀ró ọkàn fún ọkàn wa, ìrètí tí ó dájú tí ó sì dúró ṣinṣin, tí ó sì wọ inú ilé lọ lẹ́yìn aṣọ ìkélé;
Nadzieja ta jest dla naszej duszy jak kotwica dla statku—jest bowiem niewzruszona, mocna i zaczepiona za zasłoną nieba.
20 níbi tí Jesu, aṣáájú wa ti wọ̀ lọ fún wa, òun sì ni a fi jẹ alábojútó àlùfáà títí láé ní ipasẹ̀ Melkisedeki. (aiōn g165)
Tam właśnie wszedł Jezus, nasz reprezentant, na wieki stając się najwyższym kapłanem na wzór Melchizedeka. (aiōn g165)

< Hebrews 6 >