< Hebrews 4 >

1 Nítorí náà, gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti ṣe ìlérí àtiwọ inú ìsinmi rẹ̀ fún wa, ẹ jẹ́ kí á bẹ̀rù, kí ẹnikẹ́ni nínú yín má ba à dàbí ẹni pé ó tí kùnà rẹ̀.
Så låt oss nu frukta, att vi icke försumme det löfte, som är, att vi skole ingå i hans rolighet; och att ibland oss icke någor tillbakablifver.
2 Nítorí tí àwa gbọ́ ìwàásù ìyìnrere, gẹ́gẹ́ bí a ti wàásù rẹ̀ fún àwọn náà pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ tí wọ́n gbọ́ kò ṣe wọ́n ní àǹfààní, nítorí tí kò dàpọ̀ mọ́ ìgbàgbọ́ nínú àwọn tí ó gbọ́ ọ.
Ty det är ock oss förkunnadt, så väl som dem; men det halp dem intet att de hörde ordet; efter de, som hörde, satte der icke tro till.
3 Nítorí pé àwa tí ó ti gbàgbọ́ wọ inú ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó tí wí, “Bí mo tí búra nínú ìbínú mi, ‘Wọn kì yóò wọ inú ìsinmi mi.’” Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí parí iṣẹ́ wọ̀nyí láti ìpìlẹ̀ ayé.
Ty vi, som trom, ingåm i rolighetena, som han sade: Såsom jag svor i mine vrede, de skola icke ingå i mina rolighet; der dock de verk fullbordad voro af verldenes begynnelse.
4 Nítorí ó ti sọ níbìkan ní ti ọjọ́ keje báyìí pé, “Ọlọ́run sì sinmi ní ọjọ́ keje kúrò nínú iṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.”
Ty han sade enstäds om den sjunde dagen alltså: Och Gud hvilade på sjunde dagen af all sin verk;
5 Àti níhìn-ín yìí pẹ̀lú ó wí pé, “Wọn kì yóò wọ inú ìsinmi mi.”
Och åter nu här: De skola icke ingå i min rolighet.
6 Nítorí náà bí ó tí jẹ́ pé, ó ku kí àwọn kan wọ inú rẹ̀, àti àwọn tí a ti wàásù ìyìnrere náà fún ní ìṣáájú kò wọ inú rẹ̀ nítorí àìgbọ́ràn.
Efter det är ännu för handene, att somlige skola der ingå, och de, som det i förstone bebådadt vardt, äro icke komne dertill, för otrons skull;
7 Àti pé, ó yan ọjọ́ kan, ó wí nínú ìwé Dafidi pé, “Lónìí,” lẹ́yìn ìgbà pípẹ́ bẹ́ẹ̀; bí a tí wí níṣàájú, “Lónìí bí ẹ̀yin bá gbọ́ ohùn rẹ̀, ẹ má ṣe sé ọkàn yín le.”
Lägger han åter en dag före, efter så lång tid, och säger genom David: I dag, såsom sagdt är, i dag, om I hören hans röst, så förhärder icke edor hjerta.
8 Nítorí, ìbá ṣe pé Joṣua tí fún wọn ní ìsinmi, òun kì bá tí sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ ìsinmi mìíràn lẹ́yìn náà,
Ty om Josue hade kommit dem till rolighet, hade han ingalunda om en annan dag sedan sagt.
9 nítorí náà ìsinmi kan kù fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run.
Derföre står Guds folke en rolighet tillbaka.
10 Nítorí pé ẹni tí ó ba bọ́ sínú ìsinmi rẹ̀, òun pẹ̀lú sinmi kúrò nínú iṣẹ́ tirẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti sinmi kúrò nínú iṣẹ́ tirẹ̀.
Ty den som ingången är uti hans rolighet, han hafver ock fått hvilo af sin verk, såsom Gud af sin.
11 Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí á múra gírí láti wọ inú ìsinmi náà, kí ẹnikẹ́ni má ba à ṣubú nípa irú àìgbàgbọ́ kan náà.
Så vinnläggom oss nu, att vi mågom inkomma uti denna roligheten, på det icke någor skall falla uti samma otros efterdömelse.
12 Nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yè, ó sì ní agbára, ó sì mu ju idàkídà olójú méjì lọ, ó sì ń gún ni, àní títí dé pínpín ọkàn àti ẹ̀mí ní yà, àti ní oríkèé àti ọ̀rá inú egungun, òun sì ni olùmọ̀ èrò inú àti ète ọkàn.
Ty Guds ord är lefvandes och kraftigt, och skarpare än något tveeggadt svärd: och går igenom, tilldess det åtskiljer själ och anda, och märg och ben; och är en domare öfver tankar och hjertans uppsåt.
13 Kò sí ẹ̀dá kan tí kò farahàn níwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n ohun gbogbo ni ó wà níhòhò tí a sì ṣípáyà fún ojú rẹ̀, níwájú ẹni tí àwa yóò jíyìn.
Och för honom är intet kreatur osynligit; utan all ting äro blott och uppenbar för hans ögon; om honom tale vi.
14 Ǹjẹ́ bí a ti ní olórí àlùfáà ńlá kan, tí ó ti la àwọn ọ̀run kọjá lọ, Jesu Ọmọ Ọlọ́run, ẹ jẹ́ kí a di ìjẹ́wọ́ wa mú ṣinṣin.
Efter vi nu hafve en stor öfversta Prest, Jesum, Guds Son, som i himmelen faren är, så låt oss hålla bekännelsen.
15 Nítorí a kò ní olórí àlùfáà tí kò lè ṣàì ba ni kẹ́dùn nínú àìlera wa, ẹni tí a ti dánwò lọ́nà gbogbo gẹ́gẹ́ bí àwa, ṣùgbọ́n òun kò dẹ́ṣẹ̀.
Ty vi hafve icke en öfversta Prest, som icke kan varkunna sig öfver vår svaghet; utan den som frestad är i all ting, lika som vi, dock utan synd.
16 Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí a wá si ibi ìtẹ́ oore-ọ̀fẹ́ pẹ̀lú ìgboyà, kí a lè rí àánú gbà, kí a sì rí oore-ọ̀fẹ́ láti máa ran ni lọ́wọ́ ní àkókò tí ó wọ̀.
Derföre låt oss trösteliga framgå till Nådastolen; att vi måge få barmhertighet, och finna nåd, på den tid oss hjelp behöfves.

< Hebrews 4 >