< Hebrews 4 >

1 Nítorí náà, gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti ṣe ìlérí àtiwọ inú ìsinmi rẹ̀ fún wa, ẹ jẹ́ kí á bẹ̀rù, kí ẹnikẹ́ni nínú yín má ba à dàbí ẹni pé ó tí kùnà rẹ̀.
Bójmyż się tedy, aby snać zaniedbawszy obietnicy o wejściu do odpocznienia jego, nie zdał się kto z was być upośledzony.
2 Nítorí tí àwa gbọ́ ìwàásù ìyìnrere, gẹ́gẹ́ bí a ti wàásù rẹ̀ fún àwọn náà pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ tí wọ́n gbọ́ kò ṣe wọ́n ní àǹfààní, nítorí tí kò dàpọ̀ mọ́ ìgbàgbọ́ nínú àwọn tí ó gbọ́ ọ.
Albowiem i nam zwiastowana jest Ewangielija jako i onym; ale im nie pomogło słowo, które słyszeli, przeto iż nie było złączone z wiarą tych, którzy słyszeli.
3 Nítorí pé àwa tí ó ti gbàgbọ́ wọ inú ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó tí wí, “Bí mo tí búra nínú ìbínú mi, ‘Wọn kì yóò wọ inú ìsinmi mi.’” Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí parí iṣẹ́ wọ̀nyí láti ìpìlẹ̀ ayé.
Albowiem wnijdziemy do odpocznienia, którzyśmy uwierzyli, jako powiedział: Przetożem przysiągł w gniewie moim, że nie wnijdą do odpocznienia mojego; choć dokonane są dzieła Boże od założenia świata.
4 Nítorí ó ti sọ níbìkan ní ti ọjọ́ keje báyìí pé, “Ọlọ́run sì sinmi ní ọjọ́ keje kúrò nínú iṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.”
Albowiem tak powiedział na jednem miejscu o siódmym dniu: I odpoczął Bóg dnia siódmego od wszystkich spraw swoich.
5 Àti níhìn-ín yìí pẹ̀lú ó wí pé, “Wọn kì yóò wọ inú ìsinmi mi.”
A tu zasię: Że nie wnijdą do odpocznienia mego.
6 Nítorí náà bí ó tí jẹ́ pé, ó ku kí àwọn kan wọ inú rẹ̀, àti àwọn tí a ti wàásù ìyìnrere náà fún ní ìṣáájú kò wọ inú rẹ̀ nítorí àìgbọ́ràn.
Ponieważ tedy to zostaje, że niektórzy wchodzą do niego, a ci, którym pierwej zwiastowano, nie weszli dla niedowiarstwa,
7 Àti pé, ó yan ọjọ́ kan, ó wí nínú ìwé Dafidi pé, “Lónìí,” lẹ́yìn ìgbà pípẹ́ bẹ́ẹ̀; bí a tí wí níṣàájú, “Lónìí bí ẹ̀yin bá gbọ́ ohùn rẹ̀, ẹ má ṣe sé ọkàn yín le.”
Zasię naznacza dzień niektóry: Dziś, mówiąc przez Dawida po tak długim czasie (jako powiedziano): Dziś, jeźlibyście głos jego usłyszeli, nie zatwardzajcież serc waszych.
8 Nítorí, ìbá ṣe pé Joṣua tí fún wọn ní ìsinmi, òun kì bá tí sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ ìsinmi mìíràn lẹ́yìn náà,
Albowiem jeźliby im Jozue odpocznienie sprawił, nie mówiłby był potem o inszym dniu.
9 nítorí náà ìsinmi kan kù fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run.
A tak zostaje jeszcze odpocznienie ludowi Bożemu.
10 Nítorí pé ẹni tí ó ba bọ́ sínú ìsinmi rẹ̀, òun pẹ̀lú sinmi kúrò nínú iṣẹ́ tirẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti sinmi kúrò nínú iṣẹ́ tirẹ̀.
Albowiem ktobykolwiek wszedł do odpocznienia jego i on także odpoczął od spraw swoich, jako i Bóg od swoich.
11 Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí á múra gírí láti wọ inú ìsinmi náà, kí ẹnikẹ́ni má ba à ṣubú nípa irú àìgbàgbọ́ kan náà.
Starajmyż się tedy, abyśmy weszli do onego odpocznienia, żeby kto nie wpadł w tenże przykład niedowiarstwa.
12 Nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yè, ó sì ní agbára, ó sì mu ju idàkídà olójú méjì lọ, ó sì ń gún ni, àní títí dé pínpín ọkàn àti ẹ̀mí ní yà, àti ní oríkèé àti ọ̀rá inú egungun, òun sì ni olùmọ̀ èrò inú àti ète ọkàn.
Boć żywe jest słowo Boże i skuteczne, i przeraźliwsze nad wszelki miecz po obu stronach ostry, i przenikające aż do rozdzielenia i duszy, i ducha, i stawów, i szpików, i rozeznawające myśli i zdania serdeczne.
13 Kò sí ẹ̀dá kan tí kò farahàn níwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n ohun gbogbo ni ó wà níhòhò tí a sì ṣípáyà fún ojú rẹ̀, níwájú ẹni tí àwa yóò jíyìn.
A nie masz żadnego stworzenia, które by nie było jawne przed obliczem jego; owszem wszystkie rzeczy obnażone są i odkryte oczom tego, o którym mówimy.
14 Ǹjẹ́ bí a ti ní olórí àlùfáà ńlá kan, tí ó ti la àwọn ọ̀run kọjá lọ, Jesu Ọmọ Ọlọ́run, ẹ jẹ́ kí a di ìjẹ́wọ́ wa mú ṣinṣin.
Przetoż mając najwyższego kapłana wielkiego, który przeniknął niebiosa, Jezusa, Syna Bożego, trzymajmyż się tego wyznania.
15 Nítorí a kò ní olórí àlùfáà tí kò lè ṣàì ba ni kẹ́dùn nínú àìlera wa, ẹni tí a ti dánwò lọ́nà gbogbo gẹ́gẹ́ bí àwa, ṣùgbọ́n òun kò dẹ́ṣẹ̀.
Albowiem nie mamy najwyższego kapłana, który by nie mógł z nami cierpieć krewkości naszych, lecz skuszonego we wszystkiem na podobieństwo nas, oprócz grzechu.
16 Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí a wá si ibi ìtẹ́ oore-ọ̀fẹ́ pẹ̀lú ìgboyà, kí a lè rí àánú gbà, kí a sì rí oore-ọ̀fẹ́ láti máa ran ni lọ́wọ́ ní àkókò tí ó wọ̀.
Przystąpmyż tedy z ufnością do tronu łaski, abyśmy dostąpili miłosierdzia i łaskę znaleźli ku pomocy czasu przygodnego.

< Hebrews 4 >