< Hebrews 3 >
1 Nítorí náà ẹ̀yin ará mímọ́, alábápín ìpè ọ̀run, ẹ gba ti aposteli àti olórí àlùfáà ìjẹ́wọ́ wa rò, àní Jesu;
Przetoż, bracia święci, powołania niebieskiego uczestnicy! obaczcie Apostoła i najwyższego kapłana wyznania naszego, Chrystusa Jezusa,
2 ẹni tí o ṣe olóòtítọ́ si ẹni tí ó yàn án, bí Mose pẹ̀lú tí ṣe olóòtítọ́ nínú iṣẹ́ rẹ̀ gbogbo nínú ilé Ọlọ́run.
Wiernego temu, który go postanowił, jako i Mojżesz był we wszystkim domu jego.
3 Nítorí a ka ọkùnrin yìí ni yíyẹ sí ògo ju Mose lọ níwọ̀n bí ẹni tí ó kọ́ ilé ti lọ́lá ju ilé lọ.
Albowiem tem większej chwały ten nad Mojżesza godzien, im większą cześć ma budownik domu, niżeli sam dom.
4 Láti ọwọ́ ènìyàn kan ni a sá à ti kọ́ olúkúlùkù ilé; ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ́ ohun gbogbo ni Ọlọ́run.
Bo każdy dom bywa budowany od kogo; ale który wszystkie rzeczy zbudował, Bóg jest.
5 Mose nítòótọ́ sì ṣe olóòtítọ́ nínú gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run, bí ìránṣẹ́, fún ẹ̀rí ohun tí a ó sọ̀rọ̀ wọ́n ní ìgbà ìkẹyìn.
A byłci Mojżesz wiernym we wszystkim domu jego, jako sługa, na świadectwo tego, co potem miało być mówione.
6 Ṣùgbọ́n Kristi jẹ́ olóòtítọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọ lórí ilé Ọlọ́run; ilé ẹni tí àwa jẹ́, bí àwa bá gbẹ́kẹ̀lé e, tí a sì di ìṣògo ìrètí wa mu ṣinṣin títí dé òpin.
Ale Chrystus jako syn nad domem swoim panuje, którego domem my jesteśmy, jeźli tylko tę pewną ufność i tę chwałę nadziei aż do końca stateczną zachowamy.
7 Nítorí náà gẹ́gẹ́ bi Ẹ̀mí Mímọ́ tí wí: “Lónìí bí ẹ̀yin bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
Przetoż jako mówi Duch Święty: Dziś, jeźlibyście głos jego usłyszeli,
8 ẹ má ṣe sé ọkàn yín le, bí ìgbà ìṣọ̀tẹ̀, bí i ní ọjọ́ ìdánwò ní aginjù,
Nie zatwardzajcież serc waszych, jako w rozdrażnieniu, w dzień onego pokuszenia na puszczy.
9 níbi tí àwọn baba yín ti dán mi wò, tí wọ́n sì rí iṣẹ́ mi ní ogójì ọdún.
Gdzie mię kusili ojcowie wasi i doświadczali mię, i widzieli sprawy moje przez czterdzieści lat.
10 Nítorí náà a mú inú bí mi si ìran náà, mo sì wí pé, ‘Nígbà gbogbo ni wọn ṣìnà ní ọkàn wọn; wọn kò sì mọ ọ̀nà mi.’
Dlategom się rozgniewał na ten naród i rzekłem: Ci zawsze błądzą sercem, a oni nie poznawają dróg moich.
11 Bí mo tí búra nínú ìbínú mi, ‘Wọn kí yóò wọ inú ìsinmi mi.’”
Jakom przysiągł w gniewie moim, że nie wnijdą do odpocznienia mojego.
12 Ẹ kíyèsára, ará, kí ọkàn búburú ti àìgbàgbọ́ má ṣe wà nínú ẹnikẹ́ni yín, ní lílọ kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run alààyè.
Patrzcież, bracia! by snać nie było w którym z was serce złe i niewierne, które by odstępowało od Boga żywego;
13 Ṣùgbọ́n ẹ máa gba ara yín ní ìyànjú ní ojoojúmọ́, níwọ̀n ìgbà tí a bá ń pè ní “Òní,” kí a má ba à sé ọkàn ẹnikẹ́ni nínú yín le nípa ẹ̀tàn ẹ̀ṣẹ̀.
Ale napominajcie jedni drugich na każdy dzień, póki się Dziś nazywa, aby kto z was nie był zatwardzony oszukaniem grzechu.
14 Nítorí àwa di alábápín pẹ̀lú Kristi, bí àwa bá di ìpilẹ̀ṣẹ̀ ìgbẹ́kẹ̀lé wa mú ṣinṣin títí dé òpin.
Albowiem staliśmy się uczestnikami Chrystusa, jeźliże tylko początek tego gruntu aż do końca stateczny zachowamy.
15 Nígbà tí a ń wí pé, “Lónìí bí ẹ̀yin bá gbọ́ ohùn rẹ̀, ẹ má sé ọkàn yin le, bí ìgbà ìṣọ̀tẹ̀.”
Przetoż póki bywa rzeczone: Dziś, jeźlibyście głos jego usłyszeli, nie zatwardzajcież serc waszych, jako w onem rozdrażnieniu.
16 Àwọn ta ni ó gbọ́ tí ó sì tún ṣọ̀tẹ̀? Kì í ha ṣe gbogbo àwọn tí o jáde kúrò ní Ejibiti ní abẹ́ àkóso Mose?
Albowiem niektórzy usłyszawszy, rozdrażnili Pana, ale nie wszyscy, którzy byli wyszli z Egiptu przez Mojżesza.
17 Àwọn ta ni ó sì bínú sí fún ogójì ọdún? Kì í ha ṣe sí àwọn tí ó dẹ́ṣẹ̀, òkú àwọn tí ó sùn ní aginjù?
A na którychże się gniewał przez czterdzieści lat? Izali nie na tych, którzy grzeszyli, których ciała poległy na puszczy?
18 Àwọn wo ni ó búra fún pé wọn kì yóò wọ inú ìsinmi òun, bí kò ṣe fún àwọn tí ó ṣe àìgbọ́ràn?
A którymże przysiągł, że nie mieli wnijść do odpocznienia jego? Azaż nie tym, którzy byli nieposłusznymi?
19 Àwa sì rí i pé wọn kò lè wọ inú rẹ̀ nítorí àìgbàgbọ́.
I widzimy, iż tam nie mogli wnijść dla niedowiarstwa.