< Hebrews 3 >

1 Nítorí náà ẹ̀yin ará mímọ́, alábápín ìpè ọ̀run, ẹ gba ti aposteli àti olórí àlùfáà ìjẹ́wọ́ wa rò, àní Jesu;
En conséquence, frères saints, vous qui avez part à la vocation céleste, considérez bien l'apôtre et le souverain sacrificateur de la foi que nous professons,
2 ẹni tí o ṣe olóòtítọ́ si ẹni tí ó yàn án, bí Mose pẹ̀lú tí ṣe olóòtítọ́ nínú iṣẹ́ rẹ̀ gbogbo nínú ilé Ọlọ́run.
Jésus, qui a été fidèle à Celui qui l'a établi, comme Moïse aussi l'a été dans toute sa maison.
3 Nítorí a ka ọkùnrin yìí ni yíyẹ sí ògo ju Mose lọ níwọ̀n bí ẹni tí ó kọ́ ilé ti lọ́lá ju ilé lọ.
En effet, il a été jugé digne d'une gloire d'autant supérieure à celle de Moïse, que le constructeur d'une maison est plus admiré que la maison même.
4 Láti ọwọ́ ènìyàn kan ni a sá à ti kọ́ olúkúlùkù ilé; ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ́ ohun gbogbo ni Ọlọ́run.
Il n'y a pas de maison, en effet, qui n'ait été construite par quelqu'un; or, celui qui a construit toutes choses, c'est Dieu.
5 Mose nítòótọ́ sì ṣe olóòtítọ́ nínú gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run, bí ìránṣẹ́, fún ẹ̀rí ohun tí a ó sọ̀rọ̀ wọ́n ní ìgbà ìkẹyìn.
Quant à Moïse, il a été fidèle dans toute sa maison, comme un serviteur appelé à rendre témoignage de ce qui devait être annoncé plus tard.
6 Ṣùgbọ́n Kristi jẹ́ olóòtítọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọ lórí ilé Ọlọ́run; ilé ẹni tí àwa jẹ́, bí àwa bá gbẹ́kẹ̀lé e, tí a sì di ìṣògo ìrètí wa mu ṣinṣin títí dé òpin.
Mais Christ l'est comme un fils à la tête de sa maison; et sa maison, c'est nous, pourvu que nous retenions fermement, jusqu'à la fin, la confiance et l'espérance dont nous nous glorifions.
7 Nítorí náà gẹ́gẹ́ bi Ẹ̀mí Mímọ́ tí wí: “Lónìí bí ẹ̀yin bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
C'est pourquoi, ainsi parle le Saint-Esprit: «Aujourd'hui, si vous entendez sa voix,
8 ẹ má ṣe sé ọkàn yín le, bí ìgbà ìṣọ̀tẹ̀, bí i ní ọjọ́ ìdánwò ní aginjù,
n'endurcissez pas vos coeurs, comme il arriva au jour de la révolte, au jour de la tentation dans le désert,
9 níbi tí àwọn baba yín ti dán mi wò, tí wọ́n sì rí iṣẹ́ mi ní ogójì ọdún.
lorsque vos pères me tentèrent pour me mettre à l'épreuve, eux qui avaient vu mes oeuvres pendant quarante ans!
10 Nítorí náà a mú inú bí mi si ìran náà, mo sì wí pé, ‘Nígbà gbogbo ni wọn ṣìnà ní ọkàn wọn; wọn kò sì mọ ọ̀nà mi.’
Aussi ai-je été irrité contre cette génération, et j'ai dit: Leur coeur s'égare toujours, et ils n'ont pas suivi mes voies.
11 Bí mo tí búra nínú ìbínú mi, ‘Wọn kí yóò wọ inú ìsinmi mi.’”
Et voici le serment que j'ai fait dans ma colère: Jamais ils n'entreront dans mon repos!»
12 Ẹ kíyèsára, ará, kí ọkàn búburú ti àìgbàgbọ́ má ṣe wà nínú ẹnikẹ́ni yín, ní lílọ kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run alààyè.
Frères, prenez garde que quelqu'un de vous n'ait un coeur mauvais et incrédule, et ne se sépare du Dieu vivant.
13 Ṣùgbọ́n ẹ máa gba ara yín ní ìyànjú ní ojoojúmọ́, níwọ̀n ìgbà tí a bá ń pè ní “Òní,” kí a má ba à sé ọkàn ẹnikẹ́ni nínú yín le nípa ẹ̀tàn ẹ̀ṣẹ̀.
Mais exhortez-vous les uns les autres chaque jour, aussi longtemps qu'on peut dire: «Aujourd'hui», afin qu'aucun d'entre vous ne s'endurcisse, étant séduit par le péché.
14 Nítorí àwa di alábápín pẹ̀lú Kristi, bí àwa bá di ìpilẹ̀ṣẹ̀ ìgbẹ́kẹ̀lé wa mú ṣinṣin títí dé òpin.
En effet, nous avons été rendus participants du Christ, à la condition de tenir ferme jusqu'à la fin notre assurance première,
15 Nígbà tí a ń wí pé, “Lónìí bí ẹ̀yin bá gbọ́ ohùn rẹ̀, ẹ má sé ọkàn yin le, bí ìgbà ìṣọ̀tẹ̀.”
pendant qu'il est dit encore: «Aujourd'hui, si vous entendez sa voix, n'endurcissez pas vos coeurs, comme il arriva au jour de la révolte»
16 Àwọn ta ni ó gbọ́ tí ó sì tún ṣọ̀tẹ̀? Kì í ha ṣe gbogbo àwọn tí o jáde kúrò ní Ejibiti ní abẹ́ àkóso Mose?
Qui sont, en effet, ceux qui se révoltèrent, après avoir entendu sa voix, sinon tous ceux qui étaient sortis d'Égypte, sous la conduite de Moïse?
17 Àwọn ta ni ó sì bínú sí fún ogójì ọdún? Kì í ha ṣe sí àwọn tí ó dẹ́ṣẹ̀, òkú àwọn tí ó sùn ní aginjù?
Et contre qui Dieu fut-il indigné pendant quarante ans? N'est-ce pas contre ceux qui avaient péché et dont les corps tombèrent dans le désert?
18 Àwọn wo ni ó búra fún pé wọn kì yóò wọ inú ìsinmi òun, bí kò ṣe fún àwọn tí ó ṣe àìgbọ́ràn?
Et à qui jura-t-il qu'ils n'entreraient pas dans son repos? N'est-ce pas à ceux qui avaient refusé de croire?
19 Àwa sì rí i pé wọn kò lè wọ inú rẹ̀ nítorí àìgbàgbọ́.
Nous voyons, en effet, qu'ils ne purent y entrer, à cause de leur incrédulité.

< Hebrews 3 >