< Hebrews 2 >
1 Nítorí náà, ó yẹ kí àwa máa fi iyè sí àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì gidigidi tí àwa ti gbọ́, kí a má ba à gbá wa lọ kúrò nínú wọn nígbà kan.
ato vayaM yad bhramasrotasA nApanIyAmahe tadarthamasmAbhi ryadyad azrAvi tasmin manAMsi nidhAtavyAni|
2 Nítorí bí ọ̀rọ̀ tí a tí ẹnu àwọn angẹli sọ bá sì dúró ṣinṣin, àti tí olúkúlùkù ẹ̀ṣẹ̀ sí òfin àti àìgbọ́ràn gba ìjìyà tí ó tọ́ sí i,
yato heto dUtaiH kathitaM vAkyaM yadyamogham abhavad yadi ca tallaGghanakAriNe tasyAgrAhakAya ca sarvvasmai samucitaM daNDam adIyata,
3 kín ni ohun náà tí ó mú wa lérò pé a lè bọ́ kúrò nínú ìjìyà bí a kò bá náání ìgbàlà ńlá yìí? Ìgbàlà tí Olúwa fúnra rẹ̀ kọ́kọ́ kéde, èyí tí a sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ fún wa láti ọwọ́ àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà lẹ́nu rẹ̀.
tarhyasmAbhistAdRzaM mahAparitrANam avajJAya kathaM rakSA prApsyate, yat prathamataH prabhunA proktaM tato'smAn yAvat tasya zrotRbhiH sthirIkRtaM,
4 Ọlọ́run jẹ́rìí sí i nípa àwọn iṣẹ́ àmì àti ìyanu àti oríṣìíríṣìí iṣẹ́ agbára àti nípa ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ tí a pín gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀.
aparaM lakSaNairadbhutakarmmabhi rvividhazaktiprakAzena nijecchAtaH pavitrasyAtmano vibhAgena ca yad IzvareNa pramANIkRtam abhUt|
5 Nítorí pé, kì í ṣe abẹ́ ìṣàkóso àwọn angẹli ni ó fi ayé tí ń bọ̀, tí àwa ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ sí.
vayaM tu yasya bhAvirAjyasya kathAM kathayAmaH, tat ten divyadUtAnAm adhInIkRtamiti nahi|
6 Ṣùgbọ́n ibìkan wà tí ẹnìkan tí jẹ́rìí pé “Kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣe ìrántí rẹ̀, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ìwọ fi ń bẹ̀ ẹ́ wò?
kintu kutrApi kazcit pramANam IdRzaM dattavAn, yathA, "kiM vastu mAnavo yat sa nityaM saMsmaryyate tvayA| kiM vA mAnavasantAno yat sa Alocyate tvayA|
7 Ìwọ dá a ní onírẹ̀lẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ; ìwọ fi ògo àti ọlá de e ni adé, ìwọ sì fi í jẹ olórí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,
divyadatagaNebhyaH sa kiJcin nyUnaH kRtastvayA| tejogauravarUpeNa kirITena vibhUSitaH| sRSTaM yat te karAbhyAM sa tatprabhutve niyojitaH|
8 Ìwọ fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” Ní ti fífi ohun gbogbo sábẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n àwa kò ì tí ì rí ohun kan tí ó kù tí kò sí ní abẹ́ àkóso rẹ̀. Síbẹ̀ nísinsin yìí àwa kò ì tí ì rí pé ó fi ohun gbogbo sábẹ́ ìṣàkóso rẹ̀.
caraNAdhazca tasyaiva tvayA sarvvaM vazIkRtaM||" tena sarvvaM yasya vazIkRtaM tasyAvazIbhUtaM kimapi nAvazeSitaM kintvadhunApi vayaM sarvvANi tasya vazIbhUtAni na pazyAmaH|
9 Ṣùgbọ́n àwa rí Jesu ẹni tí a rẹ̀ sílẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ fún àkókò díẹ̀, àní Jesu, ẹni tí a fi ògo àti ọlá dé ní adé nítorí ìjìyà wa; kí ó lè tọ́ ikú wò fún olúkúlùkù ènìyàn nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
tathApi divyadUtagaNebhyo yaH kiJcin nyUnIkRto'bhavat taM yIzuM mRtyubhogahetostejogauravarUpeNa kirITena vibhUSitaM pazyAmaH, yata IzvarasyAnugrahAt sa sarvveSAM kRte mRtyum asvadata|
10 Nítorí pé ó yẹ fún Ọlọ́run, nítorí nípasẹ̀ ẹni tí ohun gbogbo ṣẹ̀ wà, láti mú àwọn ọmọ púpọ̀ wá sínú ògo, láti ṣe balógun ìgbàlà wọn ni àṣepé nípa ìjìyà.
aparaJca yasmai yena ca kRtsnaM vastu sRSTaM vidyate bahusantAnAnAM vibhavAyAnayanakAle teSAM paritrANAgrasarasya duHkhabhogena siddhIkaraNamapi tasyopayuktam abhavat|
11 Nítorí àti ẹni tí ń sọ ni di mímọ́ àti àwọn tí a ń sọ di mímọ́, láti ọ̀dọ̀ ẹnìkan ṣoṣo ni gbogbo wọn ti wá, nítorí èyí ni kò ṣe tijú láti pè wọ́n ni arákùnrin.
yataH pAvakaH pUyamAnAzca sarvve ekasmAdevotpannA bhavanti, iti hetoH sa tAn bhrAtRn vadituM na lajjate|
12 Àti wí pé, “Èmi ó sọ̀rọ̀ orúkọ rẹ̀ fún àwọn ará mi, ni àárín ìjọ ni èmi yóò kọrin ìyìn rẹ̀.”
tena sa uktavAn, yathA, "dyotayiSyAmi te nAma bhrAtRNAM madhyato mama| parantu samite rmadhye kariSye te prazaMsanaM||"
13 Àti pẹ̀lú, “Èmi yóò gbẹ́kẹ̀ mi lé e.” Àti pẹ̀lú, “Kíyèsi í, èmi rèé, èmi àti àwọn ọmọ tí Ọlọ́run fi fún mi.”
punarapi, yathA, "tasmin vizvasya sthAtAhaM|" punarapi, yathA, "pazyAham apatyAni ca dattAni mahyam IzvarAt|"
14 Ǹjẹ́ ni ìwọ̀n bí àwọn ọmọ tí ṣe alábápín ará àti ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni òun pẹ̀lú sì ṣe alábápín nínú ohun kan náà; kí ó lè ti ipa ikú rẹ̀ pa ẹni tí ó ní agbára ikú run, èyí ni èṣù.
teSAm apatyAnAM rudhirapalalaviziSTatvAt so'pi tadvat tadviziSTo'bhUt tasyAbhiprAyo'yaM yat sa mRtyubalAdhikAriNaM zayatAnaM mRtyunA balahInaM kuryyAt
15 Kí o sì lè gba gbogbo àwọn tí ó tìtorí ìbẹ̀rù ikú wà lábẹ́ ìdè lọ́jọ́ ayé wọn gbogbo kúrò lọ́wọ́ ìbẹ̀rù.
ye ca mRtyubhayAd yAvajjIvanaM dAsatvasya nighnA Asan tAn uddhArayet|
16 Nítorí pé, nítòótọ́, kì í ṣe àwọn angẹli ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún, ṣùgbọ́n àwọn irú-ọmọ Abrahamu ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún.
sa dUtAnAm upakArI na bhavati kintvibrAhImo vaMzasyaivopakArI bhavatI|
17 Nítorí náà, ó yẹ pé nínú ohun gbogbo kí ó dàbí àwọn ará rẹ̀, kí ó lè jẹ́ aláàánú àti olóòtítọ́ alábojútó Àlùfáà nínú ohun tí i ṣe ti Ọlọ́run, kí o lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn.
ato hetoH sa yathA kRpAvAn prajAnAM pApazodhanArtham IzvaroddezyaviSaye vizvAsyo mahAyAjako bhavet tadarthaM sarvvaviSaye svabhrAtRNAM sadRzIbhavanaM tasyocitam AsIt|
18 Nítorí níwọ̀n bí òun tìkára rẹ̀ ti jìyà tí a sì ti dán an wò, òun ní agbára láti ran àwọn tí a ń dánwò lọ́wọ́.
yataH sa svayaM parIkSAM gatvA yaM duHkhabhogam avagatastena parIkSAkrAntAn upakarttuM zaknoti|