< Hebrews 2 >
1 Nítorí náà, ó yẹ kí àwa máa fi iyè sí àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì gidigidi tí àwa ti gbọ́, kí a má ba à gbá wa lọ kúrò nínú wọn nígbà kan.
Powinniśmy zatem jeszcze bardziej trzymać się prawd, które usłyszeliśmy, abyśmy nie zeszli z właściwej drogi.
2 Nítorí bí ọ̀rọ̀ tí a tí ẹnu àwọn angẹli sọ bá sì dúró ṣinṣin, àti tí olúkúlùkù ẹ̀ṣẹ̀ sí òfin àti àìgbọ́ràn gba ìjìyà tí ó tọ́ sí i,
Skoro bowiem spełniły się słowa przekazane przez aniołów i każde przestępstwo oraz nieposłuszeństwo zostało ukarane,
3 kín ni ohun náà tí ó mú wa lérò pé a lè bọ́ kúrò nínú ìjìyà bí a kò bá náání ìgbàlà ńlá yìí? Ìgbàlà tí Olúwa fúnra rẹ̀ kọ́kọ́ kéde, èyí tí a sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ fún wa láti ọwọ́ àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà lẹ́nu rẹ̀.
to czy zlekceważenie tak wspaniałego zbawienia mogłoby nam ujść na sucho? Najpierw zostało ono ogłoszone przez Pana, a potem potwierdzone przez tych, którzy je od Niego usłyszeli.
4 Ọlọ́run jẹ́rìí sí i nípa àwọn iṣẹ́ àmì àti ìyanu àti oríṣìíríṣìí iṣẹ́ agbára àti nípa ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ tí a pín gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀.
Bóg poświadczył, że ta wieść o zbawieniu jest prawdą, dokonując niezwykłych czynów i cudów oraz udzielając ludziom darów Ducha Świętego, zgodnie ze swoją wolą.
5 Nítorí pé, kì í ṣe abẹ́ ìṣàkóso àwọn angẹli ni ó fi ayé tí ń bọ̀, tí àwa ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ sí.
Przyszły świat, o którym mówimy, nie będzie przecież zarządzany przez aniołów.
6 Ṣùgbọ́n ibìkan wà tí ẹnìkan tí jẹ́rìí pé “Kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣe ìrántí rẹ̀, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ìwọ fi ń bẹ̀ ẹ́ wò?
Gdzieś w Piśmie napisane jest przecież: „Kim jest człowiek, że o nim pamiętasz? I kim syn człowieczy, że się o niego troszczysz?
7 Ìwọ dá a ní onírẹ̀lẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ; ìwọ fi ògo àti ọlá de e ni adé, ìwọ sì fi í jẹ olórí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,
Uczyniłeś go niewiele mniejszym od aniołów, ukoronowałeś go czcią i chwałą,
8 Ìwọ fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” Ní ti fífi ohun gbogbo sábẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n àwa kò ì tí ì rí ohun kan tí ó kù tí kò sí ní abẹ́ àkóso rẹ̀. Síbẹ̀ nísinsin yìí àwa kò ì tí ì rí pé ó fi ohun gbogbo sábẹ́ ìṣàkóso rẹ̀.
wszystko złożyłeś u jego stóp”. Podporządkowanie „wszystkiego” człowiekowi oznacza, że nic nie pozostało poza zasięgiem jego władzy. Teraz jeszcze tego nie dostrzegamy,
9 Ṣùgbọ́n àwa rí Jesu ẹni tí a rẹ̀ sílẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ fún àkókò díẹ̀, àní Jesu, ẹni tí a fi ògo àti ọlá dé ní adé nítorí ìjìyà wa; kí ó lè tọ́ ikú wò fún olúkúlùkù ènìyàn nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
ale widzimy Jezusa, który—na krótki czas—stał się „niewiele mniejszy od aniołów”. On, dzięki temu, że za nas umarł, został „ukoronowany czcią i chwałą”. Dzięki Bożej łasce Chrystus doświadczył bowiem cierpienia za każdego człowieka na ziemi.
10 Nítorí pé ó yẹ fún Ọlọ́run, nítorí nípasẹ̀ ẹni tí ohun gbogbo ṣẹ̀ wà, láti mú àwọn ọmọ púpọ̀ wá sínú ògo, láti ṣe balógun ìgbàlà wọn ni àṣepé nípa ìjìyà.
W ten sposób Bóg, który wszystko stworzył i do którego wszystko należy, doprowadził do chwały wiele swoich dzieci. Jezusa zaś, poprzez cierpienie, uczynił doskonałym przywódcą, dającym im zbawienie.
11 Nítorí àti ẹni tí ń sọ ni di mímọ́ àti àwọn tí a ń sọ di mímọ́, láti ọ̀dọ̀ ẹnìkan ṣoṣo ni gbogbo wọn ti wá, nítorí èyí ni kò ṣe tijú láti pè wọ́n ni arákùnrin.
Chrystus i ci, których pojednał z Bogiem, mają jednego Ojca. Dlatego nie wstydzi się On nazwać ich swoimi braćmi, mówiąc:
12 Àti wí pé, “Èmi ó sọ̀rọ̀ orúkọ rẹ̀ fún àwọn ará mi, ni àárín ìjọ ni èmi yóò kọrin ìyìn rẹ̀.”
„Opowiem moim braciom o wspaniałości Twojego imienia. Będę Cię wielbił wśród Twojego ludu”.
13 Àti pẹ̀lú, “Èmi yóò gbẹ́kẹ̀ mi lé e.” Àti pẹ̀lú, “Kíyèsi í, èmi rèé, èmi àti àwọn ọmọ tí Ọlọ́run fi fún mi.”
Powiedział również: „Będę Mu ufał”, a także „Oto Ja i dzieci, które dał Mi Bóg”.
14 Ǹjẹ́ ni ìwọ̀n bí àwọn ọmọ tí ṣe alábápín ará àti ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni òun pẹ̀lú sì ṣe alábápín nínú ohun kan náà; kí ó lè ti ipa ikú rẹ̀ pa ẹni tí ó ní agbára ikú run, èyí ni èṣù.
Skoro Boże dzieci są ludźmi z krwi i kości, On również przybrał ludzkie ciało, aby umierając na krzyżu pokonać diabła, który miał władzę nad śmiercią.
15 Kí o sì lè gba gbogbo àwọn tí ó tìtorí ìbẹ̀rù ikú wà lábẹ́ ìdè lọ́jọ́ ayé wọn gbogbo kúrò lọ́wọ́ ìbẹ̀rù.
W ten sposób wyzwolił tych, którzy przez całe życie byli zniewoleni strachem przed śmiercią.
16 Nítorí pé, nítòótọ́, kì í ṣe àwọn angẹli ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún, ṣùgbọ́n àwọn irú-ọmọ Abrahamu ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún.
Przyszedł On bowiem na świat nie po to, aby pomóc aniołom, ale potomkom Abrahama.
17 Nítorí náà, ó yẹ pé nínú ohun gbogbo kí ó dàbí àwọn ará rẹ̀, kí ó lè jẹ́ aláàánú àti olóòtítọ́ alábojútó Àlùfáà nínú ohun tí i ṣe ti Ọlọ́run, kí o lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn.
Musiał się całkowicie upodobnić do ludzi, aby stać się pełnym miłości, wiernym kapłanem i złożyć Bogu ofiarę za ich grzechy.
18 Nítorí níwọ̀n bí òun tìkára rẹ̀ ti jìyà tí a sì ti dán an wò, òun ní agbára láti ran àwọn tí a ń dánwò lọ́wọ́.
A dzięki temu, że sam cierpiał i był kuszony, może teraz pomagać tym, którzy przechodzą przez takie same próby.