< Hebrews 2 >

1 Nítorí náà, ó yẹ kí àwa máa fi iyè sí àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì gidigidi tí àwa ti gbọ́, kí a má ba à gbá wa lọ kúrò nínú wọn nígbà kan.
C'est une raison pour nous de faire d'autant plus attention aux choses que nous avons entendues, de peur que nous ne venions à les perdre.
2 Nítorí bí ọ̀rọ̀ tí a tí ẹnu àwọn angẹli sọ bá sì dúró ṣinṣin, àti tí olúkúlùkù ẹ̀ṣẹ̀ sí òfin àti àìgbọ́ràn gba ìjìyà tí ó tọ́ sí i,
Si la parole annoncée par les anges a été si sûre et si certaine, que toute transgression et toute désobéissance a reçu sa juste rémunération,
3 kín ni ohun náà tí ó mú wa lérò pé a lè bọ́ kúrò nínú ìjìyà bí a kò bá náání ìgbàlà ńlá yìí? Ìgbàlà tí Olúwa fúnra rẹ̀ kọ́kọ́ kéde, èyí tí a sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ fún wa láti ọwọ́ àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà lẹ́nu rẹ̀.
comment échapperons-nous, si nous négligeons un si grand salut, qui, après avoir été annoncé d'abord par le Seigneur, nous est parvenu d'une manière sûre et certaine par ceux qui ont entendu sa voix,
4 Ọlọ́run jẹ́rìí sí i nípa àwọn iṣẹ́ àmì àti ìyanu àti oríṣìíríṣìí iṣẹ́ agbára àti nípa ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ tí a pín gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀.
Dieu appuyant leur témoignage par des signes, des prodiges, des miracles divers, et par l'Esprit-Saint qu'il dispense à son gré?
5 Nítorí pé, kì í ṣe abẹ́ ìṣàkóso àwọn angẹli ni ó fi ayé tí ń bọ̀, tí àwa ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ sí.
En effet, ce n'est pas aux anges que Dieu a soumis le monde à venir dont nous parlons.
6 Ṣùgbọ́n ibìkan wà tí ẹnìkan tí jẹ́rìí pé “Kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣe ìrántí rẹ̀, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ìwọ fi ń bẹ̀ ẹ́ wò?
Or l'on a fait quelque part cette déclaration: «Qu'est-ce que l'homme, que tu te souviennes de lui, ou le Fils de l'homme, que tu en prennes soin?
7 Ìwọ dá a ní onírẹ̀lẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ; ìwọ fi ògo àti ọlá de e ni adé, ìwọ sì fi í jẹ olórí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,
Tu l'as abaissé pour un peu de temps au-dessous des anges, tu l'as couronné de gloire et d'honneur,
8 Ìwọ fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” Ní ti fífi ohun gbogbo sábẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n àwa kò ì tí ì rí ohun kan tí ó kù tí kò sí ní abẹ́ àkóso rẹ̀. Síbẹ̀ nísinsin yìí àwa kò ì tí ì rí pé ó fi ohun gbogbo sábẹ́ ìṣàkóso rẹ̀.
tu as mis toutes choses sous ses pieds.» En effet, en lui soumettant «toutes choses, Dieu n'a rien laissé qui ne lui soit soumis; mais, nous ne voyons pas encore maintenant que toutes choses lui soient soumises.
9 Ṣùgbọ́n àwa rí Jesu ẹni tí a rẹ̀ sílẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ fún àkókò díẹ̀, àní Jesu, ẹni tí a fi ògo àti ọlá dé ní adé nítorí ìjìyà wa; kí ó lè tọ́ ikú wò fún olúkúlùkù ènìyàn nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
Toutefois «celui qui a été abaissé pour un peu de temps au-dessous des anges, » Jésus, nous le voyons «couronné de gloire et d'honneur, » à cause de la mort qu'il a soufferte afin que, par la grâce de Dieu, il goûtât la mort pour tout homme.
10 Nítorí pé ó yẹ fún Ọlọ́run, nítorí nípasẹ̀ ẹni tí ohun gbogbo ṣẹ̀ wà, láti mú àwọn ọmọ púpọ̀ wá sínú ògo, láti ṣe balógun ìgbàlà wọn ni àṣepé nípa ìjìyà.
Puisque Celui pour qui et par qui sont toutes choses, voulait conduire un grand nombre de fils à la gloire, il était convenable qu'il élevât par des souffrances au plus haut degré de perfection et de gloire l’auteur de leur salut;
11 Nítorí àti ẹni tí ń sọ ni di mímọ́ àti àwọn tí a ń sọ di mímọ́, láti ọ̀dọ̀ ẹnìkan ṣoṣo ni gbogbo wọn ti wá, nítorí èyí ni kò ṣe tijú láti pè wọ́n ni arákùnrin.
car celui qui sanctifie, aussi bien que ceux qui sont sanctifiés, sont tous issus d'un même Père. C'est pour ce motif que Jésus n'a point honte de les appeler «frères, »
12 Àti wí pé, “Èmi ó sọ̀rọ̀ orúkọ rẹ̀ fún àwọn ará mi, ni àárín ìjọ ni èmi yóò kọrin ìyìn rẹ̀.”
quand il dit: «J'annoncerai ton nom à mes frères, je te célébrerai en pleine assemblée; »
13 Àti pẹ̀lú, “Èmi yóò gbẹ́kẹ̀ mi lé e.” Àti pẹ̀lú, “Kíyèsi í, èmi rèé, èmi àti àwọn ọmọ tí Ọlọ́run fi fún mi.”
et encore: «Pour moi, je mettrai ma confiance en Lui; » et encore: «Me voici, moi et les enfants que tu m'as donnés.»
14 Ǹjẹ́ ni ìwọ̀n bí àwọn ọmọ tí ṣe alábápín ará àti ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni òun pẹ̀lú sì ṣe alábápín nínú ohun kan náà; kí ó lè ti ipa ikú rẹ̀ pa ẹni tí ó ní agbára ikú run, èyí ni èṣù.
Puis donc que ces «enfants» ont tous en partage le sang et la chair, lui aussi y a participé également, afin d'anéantir par la mort même, la puissance de celui qui a l'empire de la mort, c’est-à-dire, du diable,
15 Kí o sì lè gba gbogbo àwọn tí ó tìtorí ìbẹ̀rù ikú wà lábẹ́ ìdè lọ́jọ́ ayé wọn gbogbo kúrò lọ́wọ́ ìbẹ̀rù.
et de délivrer ainsi tous ceux que la crainte de la mort tenait dans la servitude pendant toute leur vie;
16 Nítorí pé, nítòótọ́, kì í ṣe àwọn angẹli ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún, ṣùgbọ́n àwọn irú-ọmọ Abrahamu ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún.
car ce n'est point aux anges assurément qu'il vient en aide, mais à la postérité d'Abraham.
17 Nítorí náà, ó yẹ pé nínú ohun gbogbo kí ó dàbí àwọn ará rẹ̀, kí ó lè jẹ́ aláàánú àti olóòtítọ́ alábojútó Àlùfáà nínú ohun tí i ṣe ti Ọlọ́run, kí o lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn.
Voilà pourquoi il devait être rendu semblable à tous égards à ses frères, pour qu'il pût être compatissant, et, dans leurs rapports avec Dieu, un souverain sacrificateur digne de confiance, pour faire l'expiation pour les péchés du peuple:
18 Nítorí níwọ̀n bí òun tìkára rẹ̀ ti jìyà tí a sì ti dán an wò, òun ní agbára láti ran àwọn tí a ń dánwò lọ́wọ́.
c'est parce qu'il a souffert en ayant été lui-même tenté, qu'il peut secourir ceux qui sont tentés.

< Hebrews 2 >