< Hebrews 13 >

1 Kí ìfẹ́ ará kí o wà títí.
Let brotherly loue continue.
2 Ẹ má ṣe gbàgbé láti máa ṣe àlejò; nítorí pé nípa bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹlòmíràn ṣe àwọn angẹli ní àlejò láìmọ̀.
Be not forgetfull to intertaine strangers: for thereby some haue receiued Angels into their houses vnwares.
3 Ẹ máa rántí àwọn òǹdè bí ẹni tí a dè pẹ̀lú wọn, àti àwọn tí a ń pọn lójú bí ẹ̀yin tìkára yín pẹ̀lú tí ń bẹ nínú ara.
Remember them that are in bondes, as though ye were bounde with them: and them that are in affliction, as if ye were also afflicted in the body.
4 Kí ìgbéyàwó lọ́lá láàrín gbogbo ènìyàn, kí àkéte si jẹ́ aláìléèérí, nítorí àwọn àgbèrè àti àwọn panṣágà ni Ọlọ́run yóò dá lẹ́jọ́.
Mariage is honorable among all, and the bed vndefiled: but whoremongers and adulterers God will iudge.
5 Kí ọkàn yín má ṣe fà sí ìfẹ́ owó, ki ohun tí ẹ ní tó yin; nítorí òun tìkára rẹ̀ ti wí pé, “Èmi kò jẹ́ fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò jẹ́ kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
Let your conuersation be without couetousnesse, and be content with those things that ye haue, for he hath said, I will not faile thee, neither forsake thee:
6 Nítorí náà ni àwa ṣe ń fi ìgboyà wí pé, “Olúwa ni olùrànlọ́wọ́ mi, èmi kì yóò bẹ̀rù; kín ni ènìyàn lè ṣe sí mi?”
So that we may boldly say, The Lord is mine helper, neither will I feare what man can doe vnto me.
7 Ẹ máa rántí àwọn tiwọn jẹ́ aṣáájú yín, tiwọn ti sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún yín; kí ẹ máa ro òpin ìwà ayé wọn, kí ẹ sì máa ṣe àfarawé ìgbàgbọ́ wọn.
Remember them which haue the ouersight of you, which haue declared vnto you the word of God: whose faith follow, considering what hath bene the ende of their conuersation.
8 Jesu Kristi ọ̀kan náà ni lánàá, àti lónìí, àti títí láé. (aiōn g165)
Iesus Christ yesterday, and to day, the same also is for euer. (aiōn g165)
9 Ẹ má ṣe jẹ́ kí a fi onírúurú àti àjèjì ẹ̀kọ́ gbá yin kiri. Nítorí ó dára kí a mú yin lọ́kàn le nípa oore-ọ̀fẹ́, kì í ṣe nípa oúnjẹ nínú èyí tí àwọn tí ó ti rìn nínú wọn kò ní èrè.
Be not caried about with diuers and strange doctrines: for it is a good thing that the heart be stablished with grace, and not with meates, which haue not profited them that haue bene occupied therein.
10 Àwa ní pẹpẹ kan, níbi èyí tí àwọn ti ń sin àgọ́ kò ni agbára láti máa jẹ.
We haue an altar, whereof they haue no authoritie to eate, which serue in the tabernacle.
11 Nítorí nígbà tí olórí àlùfáà bá mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ẹran wá si Ibi Mímọ́ Jùlọ gẹ́gẹ́ bí ìrúbọ ẹ̀ṣẹ̀, òkú àwọn ẹran náà ni a o sun lẹ́yìn ibùdó.
For the bodies of those beastes whose blood is brought into the Holy place by the high Priest for sinne, are burnt without the campe.
12 Nítorí náà Jesu pẹ̀lú, kí ó lè fi ẹ̀jẹ̀ ara rẹ̀ sọ àwọn ènìyàn di mímọ́, ó jìyà lẹ́yìn ibodè.
Therefore euen Iesus, that he might sanctifie the people with his owne blood, suffered without the gate.
13 Nítorí náà ẹ jẹ́ kí a jáde tọ̀ ọ́ lọ lẹ́yìn ibùdó, kí a máa ru ẹ̀gàn rẹ̀.
Let vs goe foorth to him therefore out of the campe, bearing his reproch.
14 Nítorí pé àwa kò ní ìlú tí o wa títí níhìn-ín, ṣùgbọ́n àwa ń wá èyí tí ń bọ.
For here haue we no continuing citie: but we seeke one to come.
15 Ǹjẹ́ nípasẹ̀ rẹ̀, ẹ jẹ́ kí a máa rú ẹbọ ìyìn si Ọlọ́run nígbà gbogbo, èyí yìí ni èso ètè wa, tí ń jẹ́wọ́ orúkọ rẹ̀.
Let vs therefore by him offer the sacrifice of prayse alwaies to God, that is, the fruite of the lippes, which confesse his Name.
16 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe gbàgbé láti máa ṣoore àti láti máa pín fun ni nítorí irú ẹbọ wọ̀nyí ni inú Ọlọ́run dùn sí jọjọ.
To doe good, and to distribute forget not: for with such sacrifices God is pleased.
17 Ẹ máa gbọ́ ti àwọn tí ń ṣe olórí yín, kí ẹ sì máa tẹríba fún wọ́n, nítorí wọn ń ṣọ́ ẹ̀ṣọ́ nítorí ọkàn yín, bí àwọn ti yóò ṣe ìṣirò, kí wọn lè fi ayọ̀ ṣe èyí, kì í ṣe pẹ̀lú ìbànújẹ́, nítorí èyí yìí yóò jẹ àìlérè fún yín.
Obey them that haue the ouersight of you, and submit your selues: for they watche for your soules, as they that must giue accountes, that they may doe it with ioy, and not with griefe: for that is vnprofitable for you.
18 Ẹ máa gbàdúrà fún wa, nítorí àwa gbàgbọ́ pé àwa ni ẹ̀rí ọkàn rere, a sì ń fẹ́ láti máa hùwà títọ́ nínú ohun gbogbo.
Pray for vs: for we are assured that we haue a good conscience in all things, desiring to liue honestly.
19 Ṣùgbọ́n èmi ń bẹ̀ yín gidigidi sí i láti máa ṣe èyí, kí a ba lè tètè fi mi fún yín padà.
And I desire you somewhat the more earnestly, that yee so doe, that I may be restored to you more quickly.
20 Ǹjẹ́ Ọlọ́run àlàáfíà, ẹni tí o tún mu olùṣọ́-àgùntàn ńlá ti àwọn àgùntàn, ti inú òkú wá, nípa ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú ayérayé, àní Olúwa wa Jesu. (aiōnios g166)
The God of peace that brought againe from the dead our Lord Iesus, the great shepheard of the sheepe, through the blood of the euerlasting Couenant, (aiōnios g166)
21 Kí ó mú yín pé nínú iṣẹ́ rere gbogbo láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣiṣẹ́ ohun tí i ṣe ìtẹ́wọ́gbà níwájú rẹ̀ nínú yín nípasẹ̀ Jesu Kristi; ẹni tí ògo wà fún láé àti láéláé. Àmín. (aiōn g165)
Make you perfect in all good workes, to doe his will, working in you that which is pleasant in his sight through Iesus Christ, to whom be praise for euer and euer, Amen. (aiōn g165)
22 Èmi sì ń bẹ̀ yín ará, ẹ gbà ọ̀rọ̀ ìyànjú mi; nítorí ìwé kúkúrú ni mo kọ sí yín.
I beseeche you also, brethren, suffer the wordes of exhortation: for I haue written vnto you in fewe wordes.
23 Ẹ mọ pé a sá titu Timotiu arákùnrin wa sílẹ̀; bí ó ba tètè dé, èmí pẹ̀lú rẹ̀ yóò rí yín, àti gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́.
Knowe that our brother Timotheus is deliuered, with whome (if hee come shortly) I will see you.
24 Ẹ ki gbogbo àwọn tí ń ṣe olórí yín, àti gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́. Àwọn tí o ti Itali wá ki yín.
Salute all them that haue the ouersight of you, and all the Saintes. They of Italie salute you.
25 Kí oore-ọ̀fẹ́ wà pẹ̀lú gbogbo yín.
Grace be with you all, Amen. ‘Written to the Hebrewes from Italie, and sent by Timotheus.’

< Hebrews 13 >