< Hebrews 12 >

1 Nítorí náà bí a ti fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ tí o kún fún àwọn ẹlẹ́rìí tó báyìí yí wa ká, ẹ jẹ́ kí a pa ohun ìdíwọ́ gbogbo tì sí apá kan, àti ẹ̀ṣẹ̀ tí o rọrùn láti di mọ́ wa, kí a sì máa fi sùúrù súré ìje tí a gbé ka iwájú wa,
Alltså, då vi nu hava omkring oss en så stor hop av vittnen, må ock vi lägga av allt som är oss till hinder, och särskilt synden, som så hårt omsnärjer oss, och med uthållighet löpa framåt i den tävlingskamp som är oss förelagd.
2 kí a máa wo Jesu Olùpilẹ̀ṣẹ̀ àti aláṣepé ìgbàgbọ́ wa; ẹni nítorí ayọ̀ tí a gbé ka iwájú rẹ, tí o faradà àgbélébùú láìka ìtìjú sí, tí ó sì jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún ìtẹ́ Ọlọ́run.
Och må vi därvid se på Jesus, trons hövding och fullkomnare, på honom, som i stället för att taga den glädje som låg framför honom, utstod korsets lidande och aktade smäleken för intet, och som nu sitter på högra sidan om Guds tron.
3 Máa ro ti ẹni tí ó faradà irú ìsọ̀rọ̀-òdì yìí láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ si ara rẹ̀, kí ẹ má ba á rẹ̀wẹ̀sì ni ọkàn yín, kí àárẹ̀ si mu yín.
Ja, på honom, som har utstått så mycken gensägelse av syndare, på honom mån I tänka, så att I icke tröttnen och uppgivens i edra själar.
4 Ẹ̀yin kò sá à tí ì kọ ojú ìjà si ẹ̀ṣẹ̀ títí dé títa ẹ̀jẹ̀ yín sílẹ̀ nínú ìjàkadì yín.
Ännu haven I icke stått emot ända till blods, i eder kamp mot synden.
5 Ẹ̀yin sì ti gbàgbé ọ̀rọ̀ ìyànjú tí ó n ba yin sọ̀rọ̀ bí ọmọ pé, “Ọmọ mi, ma ṣe aláìnání ìbáwí Olúwa, kí o má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì nígbà tí a bá ń ti ọwọ́ rẹ̀ ba ọ wí,
Och I haven alldeles förgätit den förmaningens röst som talar med eder, såsom man talar med söner: »Min son, förkasta icke Herrens aga, och giv dig icke över, när du tuktas av honom.
6 nítorí pé ẹni ti Olúwa fẹ́, òun ni i bá wí, a sì máa na olúkúlùkù ọmọ tí òun tẹ́wọ́gbà.”
Ty den Herren älskar, den agar han, och han straffar med riset var son som han har kär.»
7 Ẹ máa ní sùúrù lábẹ́ ìbáwí, Ọlọ́run bá wa lò bí ọmọ ni; nítorí pé ọmọ wo ni ń bẹ ti baba kì í bá wí?
Det är till eder fostran som I fån utstå lidande; Gud handlar med eder såsom med söner. Ty var finnes den son som icke bliver agad av sin fader?
8 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin ba wà láìsí ìbáwí, nínú èyí tí gbogbo ènìyàn ti jẹ alábápín, ǹjẹ́ ọmọ àlè ni yín, ẹ kì í sì ṣe ọmọ.
Om I lämnadens utan aga, medan alla andra finge sin del därav, så voren I oäkta söner och icke äkta.
9 Pẹ̀lúpẹ̀lú àwa ni baba wa nípa ti ara tí o ń tọ́ wa, àwa sì ń bu ọlá fún wọn: kò ha yẹ kí a kúkú tẹríba fún Baba àwọn ẹ̀mí, kí a sì yè?
Vidare: vi hava haft köttsliga fäder, som agade oss, och vi visade försyn för dem; skola vi då icke mycket mer vara underdåniga andarnas Fader, så att vi få leva?
10 Nítorí wọ́n tọ́ wa fún ọjọ́ díẹ̀ bí o bá ti dára lójú wọn; ṣùgbọ́n Òun tọ́ wa fún èrè wa, kí àwa lè ṣe alábápín ìwà mímọ́ rẹ̀.
De förra agade oss ju för en kort tid, såsom det syntes dem gott, men denne agar oss för vårt verkliga gagn, för att vi skola få del av hans helighet.
11 Gbogbo ìbáwí kò dàbí ohun ayọ̀ nísinsin yìí bí kò ṣe ìbànújẹ́; ṣùgbọ́n níkẹyìn yóò so èso àlàáfíà fún àwọn tí a tọ́ nípa rẹ̀, àní èso òdodo.
Väl synes alla aga för tillfället vara icke till glädje, utan till sorg; men efteråt bär den, för dem som hava blivit fostrade därmed, en fridsfrukt som är rättfärdighet.
12 Nítorí náà, ẹ na ọwọ́ tí ó rọ, àti eékún àìlera,
Alltså: »stärken maktlösa händer och vacklande knän»,
13 “Kí ẹ sì ṣe ipa ọ̀nà tí ó tọ́ fún ẹsẹ̀ yin,” kí èyí tí ó rọ má bá a kúrò lórí ike ṣùgbọ́n kí a kúkú wò ó sàn.
och »gören räta stigar för edra fötter», så att den fot som haltar icke vrides ur led, utan fastmer bliver botad.
14 Ẹ máa lépa àlàáfíà pẹ̀lú ènìyàn gbogbo, àti ìwà mímọ́, láìsí èyí yìí kò sí ẹni tí yóò rí Olúwa.
Faren efter frid med alla och efter helgelse; ty utan helgelse får ingen se Herren.
15 Ẹ máa kíyèsára kí ẹnikẹ́ni má ṣe kùnà Oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run; kí gbòǹgbò ìkorò kan máa ba hù sókè kí ó sì yọ yín lẹ́nu, ọ̀pọ̀lọpọ̀ a sì ti ipa rẹ̀ di àìmọ́.
Och sen till, att ingen går miste om Guds nåd, och att ingen giftig rot skjuter skott och bliver till fördärv, så att menigheten därigenom bliver besmittad;
16 Kí o má bá à si àgbèrè kan tàbí aláìwà-bí-Ọlọ́run bi Esau, ẹni tí o tìtorí òkèlè oúnjẹ kan ta ogún ìbí rẹ̀.
sen till, att ingen är en otuktig människa eller ohelig såsom Esau, han som för en enda maträtt sålde sin förstfödslorätt.
17 Nítorí ẹ̀yin mọ pé lẹ́yìn náà, nígbà tí ó fẹ́ láti jogún ìbùkún náà, a kọ̀ ọ́, nítorí kò ri ààyè ìrònúpìwàdà, bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi omijé wa a gidigidi.
I veten ju att han ock sedermera blev avvisad, när han på grund av arvsrätt ville få välsignelsen; han kunde nämligen icke vinna någon ändring, fastän han med tårar sökte därefter.
18 Nítorí ẹ̀yin kò wá òkè tí a lè fi ọwọ́ kàn, àti ti iná ti ń jó, àti ti ìṣúdudu àti òkùnkùn, àti ìjì.
Ty I haven icke kommit till ett berg som man kan taga på, ett som »brann i eld», icke till »töcken och mörker» och storm,
19 Àti ìró ìpè, àti ohùn ọ̀rọ̀, èyí tí àwọn tí o gbọ́ bẹ̀bẹ̀ pé, kí a má ṣe sọ ọ̀rọ̀ sí i fún wọn mọ́,
icke till »basunljud» och till en »röst» som talade så, att de som hörde den bådo att intet ytterligare skulle talas till dem.
20 nítorí pé wọn kò lè gba ohun tí ó paláṣẹ, “Bí o tilẹ̀ jẹ ẹranko ni ó fi ara kan òkè náà, a ó sọ ọ́ ni òkúta.”
Ty de kunde icke härda ut med det påbud som gavs dem: »Också om det är ett djur som kommer vid berget, skall det stenas.»
21 Ìran náà sì lẹ́rù to bẹ́ẹ̀ tí Mose wí pé, “Ẹ̀rù ba mi gidigidi mo sì wárìrì.”
Och så förskräcklig var den syn man såg, att Moses sade: »Jag är förskräckt och bävar.»
22 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wá sí òkè Sioni, àti sí ìlú Ọlọ́run alààyè, ti Jerusalẹmu ti ọ̀run, àti si ẹgbẹ́ àwọn angẹli àìníye,
Nej, I haven kommit till Sions berg och den levande Gudens stad, det himmelska Jerusalem, och till änglar i mångtusental,
23 si àjọ ńlá tí ìjọ àkọ́bí tí a ti kọ orúkọ wọn ni ọ̀run, àti sọ́dọ̀ Ọlọ́run onídàájọ́ gbogbo ènìyàn, àti sọ́dọ̀ àwọn ẹ̀mí olóòtítọ́ ènìyàn tí a ṣe ni àṣepé,
till en högtidsskara och församling av förstfödda söner som äro uppskrivna i himmelen, och till en domare som är allas Gud, och till fullkomnade rättfärdigas andar,
24 àti sọ́dọ̀ Jesu alárinà májẹ̀mú tuntun, àti si ibi ẹ̀jẹ̀ ìbùwọ́n ni, ti ń sọ̀rọ̀ ohun tí ó dára ju ti Abeli lọ.
och till ett nytt förbunds medlare, Jesus, och till ett stänkelseblod som talar bättre än Abels blod.
25 Kíyèsi i, kí ẹ má ṣe kọ̀ ẹni tí ń kìlọ̀. Nítorí bí àwọn wọ̀nyí kò bá bọ́ nígbà tí wọn kọ̀ ẹni ti ń kìlọ̀ ni ayé, mélòó mélòó ni àwa kì yóò bọ́, bí àwa ba pẹ̀yìndà sí ẹni tí ń kìlọ̀ láti ọ̀run wá,
Sen till, att I icke visen ifrån eder honom som talar. Ty om dessa icke kunde undfly, när de visade ifrån sig honom som här på jorden kungjorde Guds vilja, huru mycket mindre skola då vi kunna det, om vi vända oss ifrån honom som kungör sin vilja från himmelen?
26 ohùn ẹni tí ó mi ayé nígbà náà, ṣùgbọ́n nísinsin yìí o ti ṣe ìlérí, wí pé, “Lẹ́ẹ̀kan sí i èmi ki yóò mi kìkì ayé nìkan, ṣùgbọ́n ọ̀run pẹ̀lú.”
Hans röst kom då jorden att bäva; men nu har han lovat och sagt: »Ännu en gång skall jag komma icke allenast jorden, utan ock himmelen att bäva.»
27 Àti ọ̀rọ̀ yìí, “Lẹ́ẹ̀kan sí i,” ìtumọ̀ rẹ̀ ni, mímú àwọn ohun wọ̀nyí ti a ń mì kúrò, bí ohun tí a ti dá, kí àwọn ohun tí a kò lè mì lè wà síbẹ̀.
Dessa ord »ännu en gång» giva till känna att de ting, som kunna bäva, skola, eftersom de äro skapade, bliva förvandlade, för att de ting, som icke kunna bäva, skola bliva beståndande.
28 Nítorí náà bí àwa tí ń gbà ilẹ̀ ọba ti a kò lè mì, ẹ jẹ́ kí a dá ọpẹ́ nípa èyí ti a fi lè máa sin Ọlọ́run ni ìtẹ́wọ́gbà pẹ̀lú ọ̀wọ̀ àti ìbẹ̀rù rẹ̀.
Därför, då vi nu skola undfå ett rike som icke kan bäva, så låtom oss vara tacksamma. På det sättet tjäna vi Gud, honom till behag, med helig fruktan och räddhåga.
29 Nítorí pé, “Ọlọ́run wa, iná ti ń jó ni run ni.”
Ty »vår Gud är en förtärande eld».

< Hebrews 12 >