< Hebrews 11 >

1 Ǹjẹ́ ìgbàgbọ́ ní ìdánilójú ohun tí o ń retí, ìjẹ́rìí ohun tí a kò rí.
Or la foi est l'assurance des choses qu'on espère, la preuve de celles qu'on ne voit pas.
2 Nítorí nínú rẹ ni àwọn alàgbà àtijọ́ ní ẹ̀rí rere.
Car c'est par là que les anciens ont obtenu l'approbation.
3 Nípa ìgbàgbọ́ ni a mọ̀ pé a ti dá ayé nípa ọ̀rọ̀ Ọlọ́run; nítorí náà kì í ṣe ohun tí o hàn ni a fi dá ohun tí a ń ri. (aiōn g165)
Par la foi, nous comprenons que l'univers a été formé par la parole de Dieu, de sorte que ce que l'on voit n'a pas été fait à partir de choses visibles. (aiōn g165)
4 Nípa ìgbàgbọ́ ní Abeli rú ẹbọ sí Ọlọ́run tí ó sàn ju ti Kaini lọ, nípa èyí tí a jẹ́rìí rẹ̀ pe olódodo ni, Ọlọ́run sí ń jẹ́rìí ẹ̀bùn rẹ̀, àti nípa rẹ̀ náà, bí o ti jẹ́ pé o ti kú, síbẹ̀ o ń fọhùn.
Par la foi, Abel a offert à Dieu un sacrifice plus excellent que celui de Caïn, par lequel il a reçu le témoignage qu'il était juste, Dieu témoignant à l'égard de ses dons, et par lequel, bien que mort, il parle encore.
5 Nípa ìgbàgbọ́ ni a ṣí Enoku ní ipò padà kí o má ṣe rí ikú; a kò sì rí i mọ́, nítorí Ọlọ́run ṣí i ní ipò padà ṣáájú ìṣípò padà rẹ̀, a jẹ́rìí yìí sí i pé o wu Ọlọ́run.
C'est par la foi qu'Hénoc a été enlevé, afin qu'il ne voie pas la mort, et qu'il n'a pas été retrouvé, parce que Dieu l'a traduit. Car il lui a été rendu témoignage qu'avant sa translation il avait été bien agréable à Dieu.
6 Ṣùgbọ́n láìsí ìgbàgbọ́ kò ṣe é ṣe láti wù ú; nítorí ẹni tí ó bá ń tọ Ọlọ́run wá kò lè ṣàì gbàgbọ́ pé ó ń bẹ, àti pé òun ní olùṣẹ̀san fún àwọn tí o fi ara balẹ̀ wá a.
Sans la foi, il est impossible de lui être agréable, car celui qui s'approche de Dieu doit croire qu'il existe et qu'il est le rémunérateur de ceux qui le cherchent.
7 Nípa ìgbàgbọ́ ni Noa, nígbà ti Ọlọ́run, kìlọ̀ ohun tí a kóò tí ì rí fún un, o bẹ̀rù Ọlọ́run ó sì kan ọkọ̀ fún ìgbàlà ilé rẹ̀, nípa èyí tí ó da ayé lẹ́bi, ó sì di ajogún òdodo tí i ṣe nípa ìgbàgbọ́.
Par la foi, Noé, averti des choses qu'on ne voyait pas encore, et animé d'une crainte pieuse, a préparé un navire pour sauver sa maison, par lequel il a condamné le monde et est devenu héritier de la justice selon la foi.
8 Nípa ìgbàgbọ́ ní Abrahamu, nígbà tí a ti pé e láti jáde lọ sí ibi tí òun yóò gbà fún ilẹ̀ ìní, ó gbọ́, ó sì jáde lọ, láì mọ ibi tí òun ń rè.
C'est par la foi qu'Abraham, lorsqu'il fut appelé, obéit pour sortir vers le lieu qu'il devait recevoir en héritage. Il sortit, sans savoir où il allait.
9 Nípa ìgbàgbọ́ ní o ṣe àtìpó ní ilẹ̀ ìlérí, bí ẹni pé ni ilẹ̀ àjèjì, o ń gbé inú àgọ́, pẹ̀lú Isaaki àti Jakọbu, àwọn ajogún ìlérí kan náà pẹ̀lú rẹ̀,
C'est par la foi qu'il vécut comme un étranger dans la terre promise, comme dans une terre qui ne lui appartenait pas, habitant sous des tentes avec Isaac et Jacob, héritiers avec lui de la même promesse.
10 nítorí tí ó ń retí ìlú tí ó ní ìpìlẹ̀; èyí tí Ọlọ́run tẹ̀dó tí ó sì kọ́.
Car il attendait la cité qui a des fondements, et dont Dieu est le constructeur et l'artisan.
11 Nípa ìgbàgbọ́ ni Sara tìkára rẹ̀ pẹ̀lú fi gba agbára láti lóyún, nígbà tí ó kọjá ìgbà rẹ̀, nítorí tí o ka ẹni tí o ṣe ìlérí sí olóòótọ́.
C'est par la foi que Sara elle-même a reçu le pouvoir de concevoir, et qu'elle a enfanté un enfant à un âge avancé, car elle a considéré comme fidèle celui qui avait promis.
12 Nítorí náà ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ṣe ti ara ọkùnrin kan jáde, àní ara ẹni tí o dàbí òkú, ọmọ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run lọ́pọ̀lọ́pọ̀, àti bí iyanrìn etí Òkun láìníye.
C'est pourquoi un seul homme a engendré autant d'enfants que les étoiles du ciel sont nombreuses, et aussi innombrables que le sable qui est au bord de la mer, et il est comme mort.
13 Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ó kú nínú ìgbàgbọ́, láìrí àwọn ìlérí náà gbà, ṣùgbọ́n tí wọn rí wọn ni òkèrè réré, tí wọ́n sì gbá wọn mú, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ pé àlejò àti àjèjì ni àwọn lórí ilẹ̀ ayé.
Tous ceux-là sont morts dans la foi, n'ayant pas reçu les promesses, mais les ayant vues et embrassées de loin, et ayant confessé qu'ils étaient étrangers et pèlerins sur la terre.
14 Nítorí pé àwọn tí o ń sọ irú ohun bẹ́ẹ̀ fihàn gbangba pé, wọn ń ṣe àfẹ́rí ìlú kan tí i ṣe tiwọn.
Car ceux qui disent de telles choses montrent clairement qu'ils cherchent un pays à eux.
15 Àti nítòótọ́, ìbá ṣe pé wọ́n fi ìlú tiwọn tí jáde wá sí ọkàn, wọn ìbá ti rí ààyè padà.
Si en effet ils avaient pensé au pays d'où ils sont partis, ils auraient eu le temps de revenir.
16 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n ń fẹ́ ìlú kan tí o dára jù bẹ́ẹ̀ lọ, èyí yìí ni ti ọ̀run, nítorí náà ojú wọn kò ti Ọlọ́run, pé kí a máa pé òun ni Ọlọ́run wọn; nítorí tí o ti pèsè ìlú kan sílẹ̀ fún wọn.
Mais maintenant ils désirent un pays meilleur, c'est-à-dire un pays céleste. C'est pourquoi Dieu n'a pas honte d'eux, d'être appelé leur Dieu, car il leur a préparé une cité.
17 Nípa ìgbàgbọ́ ni Abrahamu, nígbà tí a dán an wò láti, fi Isaaki rú ẹbọ: àní òun ẹni tí ó rí ìlérí gba múra tan láti fi ọmọ bíbí rẹ kan ṣoṣo rú ẹbọ.
Par la foi, Abraham, mis à l'épreuve, offrit Isaac. En effet, celui qui avait reçu avec joie les promesses offrait son fils unique,
18 Nípa ẹni tí wí pé, “Nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.”
à qui il avait été dit: « Ta descendance sera comptée comme celle d'Isaac »,
19 Ó sì rò ó si pé Ọlọ́run tilẹ̀ lè gbé e dìde kúrò nínú òkú, bẹ́ẹ̀ ni, bí a bá sọ ọ́ lọ́nà àpẹẹrẹ, ó gbà á padà.
concluant que Dieu est capable de ressusciter même d'entre les morts. Au sens figuré, il l'a aussi ressuscité d'entre les morts.
20 Nípa ìgbàgbọ́ ní Isaaki súre fún Jakọbu àti Esau ní ti ohun tí ń bọ̀.
C'est par la foi qu'Isaac a béni Jacob et Ésaü, même en ce qui concerne les choses à venir.
21 Nípa ìgbàgbọ́ ni Jakọbu, nígbà tí o ń ku lọ, ó súre fún àwọn ọmọ Josẹfu ni ọ̀kọ̀ọ̀kan; ó sì sinmi ní ìtẹríba lé orí ọ̀pá rẹ̀.
C'est par la foi que Jacob, à sa mort, bénit chacun des fils de Joseph et se prosterna, appuyé sur le sommet de son bâton.
22 Nípa ìgbàgbọ́ ni Josẹfu, nígbà tí ó ń ku lọ, ó rántí ìjáde lọ àwọn ọmọ Israẹli; ó sì pàṣẹ ní ti àwọn egungun rẹ̀.
C'est par la foi que Joseph, lorsque sa fin approcha, fit mention du départ des enfants d'Israël, et donna des instructions concernant ses ossements.
23 Nípa ìgbàgbọ́ ní àwọn òbí Mose pa a mọ́ fún oṣù mẹ́ta nígbà tí a bí i, nítorí tiwọn rí i ní arẹwà ọmọ; wọn kò sì bẹ̀rù àṣẹ ọba.
C'est par la foi que Moïse, à sa naissance, fut caché pendant trois mois par ses parents, parce qu'ils virent qu'il était un bel enfant; et ils ne craignirent pas l'ordre du roi.
24 Nípa ìgbàgbọ́ ni Mose, nígbà tí o dàgbà, ó kọ̀ ki a máa pé òun ni ọmọ ọmọbìnrin Farao;
C'est par la foi que Moïse, devenu grand, refusa d'être appelé fils de la fille de Pharaon,
25 o kúkú yàn láti máa ba àwọn ènìyàn Ọlọ́run jìyà, ju jíjẹ fàájì ẹ̀ṣẹ̀ fún ìgbà díẹ̀.
préférant partager les mauvais traitements du peuple de Dieu plutôt que de jouir pour un temps des plaisirs du péché,
26 Ó ka ẹ̀gàn Kristi si ọrọ̀ tí ó pọ̀jù àwọn ìṣúra Ejibiti lọ, nítorí tí ó ń wo èrè náà.
considérant l'opprobre du Christ comme une plus grande richesse que les trésors de l'Égypte, car il en attendait la récompense.
27 Nípa ìgbàgbọ́ ni o kọ Ejibiti sílẹ̀ láìbẹ̀rù ìbínú ọba: nítorí tí o dúró ṣinṣin bí ẹni tí ó n ri ẹni àìrí.
C'est par la foi qu'il quitta l'Égypte, sans craindre la colère du roi, car il endurait, comme s'il voyait celui qui est invisible.
28 Nípa ìgbàgbọ́ ni ó da àsè ìrékọjá sílẹ̀, àti ìbùwọ́n ẹ̀jẹ̀, kí ẹni tí ń pa àwọn àkọ́bí ọmọ má bá a fi ọwọ́ kan wọn.
C'est par la foi qu'il a gardé la Pâque et l'aspersion du sang, afin que le destructeur des premiers-nés ne les touche pas.
29 Nípa ìgbàgbọ́ ni wọn la òkun pupa kọjá bi ẹni pé ni ìyàngbẹ ilẹ̀ ni: ti àwọn ara Ejibiti dánwò, tí wọ́n sì ri.
C'est par la foi qu'ils traversèrent la mer Rouge comme sur une terre sèche. Lorsque les Égyptiens ont essayé de le faire, ils ont été engloutis.
30 Nípa ìgbàgbọ́ ni àwọn odi Jeriko wo lulẹ̀, lẹ́yìn ìgbà tí a yí wọn ká ni ọjọ́ méje.
C'est par la foi que les murs de Jéricho sont tombés après avoir été encerclés pendant sept jours.
31 Nípa ìgbàgbọ́ ni Rahabu panṣágà kò ṣègbé pẹ̀lú àwọn tí kò gbọ́rọ̀ nígbà tí o tẹ́wọ́gbà àwọn àmì ní àlàáfíà.
C'est par la foi que Rahab la prostituée n'a pas péri avec les désobéissants, ayant reçu les espions en paix.
32 Èwo ni èmi o sì tún máa wí sí i? Nítorí pé ìgbà yóò kùnà fún mi láti sọ ti Gideoni, àti Baraki, àti Samsoni, àti Jefta; àti Dafidi, àti Samuẹli, àti ti àwọn wòlíì,
Que dirai-je encore? Car le temps me manquerait si je parlais de Gédéon, de Barak, de Samson, de Jephté, de David, de Samuel et des prophètes -
33 àwọn ẹni nípasẹ̀ ìgbàgbọ́ tiwọn ṣẹ́gun ilẹ̀ ọba, tí wọn ṣiṣẹ́ òdodo, tiwọn gba ìlérí, tiwọn dí àwọn kìnnìún lénu,
qui, par la foi, ont soumis des royaumes, exercé la justice, obtenu des promesses, fermé la gueule des lions,
34 tí wọ́n pa agbára iná, tí wọ́n bọ́ lọ́wọ́ ojú idà, tí a sọ di alágbára nínú àìlera, tí wọ́n dí akọni nínú ìjà, wọ́n lé ogun àwọn àjèjì sá.
éteint la puissance du feu, échappé au tranchant de l'épée, se sont fortifiés à partir de leur faiblesse, sont devenus puissants à la guerre et ont mis en fuite les armées étrangères.
35 Àwọn obìnrin ri òkú wọn gbà nípa àjíǹde: a sì da àwọn ẹlòmíràn lóró, wọ́n kọ̀ láti gba ìdásílẹ̀; kí wọn ba lè rí àjíǹde tí o dára jù gbà.
Des femmes ont reçu leurs morts par résurrection. D'autres ont été torturés, n'acceptant pas leur délivrance, afin d'obtenir une meilleure résurrection.
36 Àwọn ẹlòmíràn sì rí ìjìyà ẹ̀sín, àti nínà, àti ju bẹ́ẹ̀ lọ, ti ìdè àti ti túbú.
D'autres ont été éprouvés par la moquerie et la flagellation, et même par les liens et la prison.
37 A sọ wọ́n ni òkúta, a fi ayùn rẹ́ wọn sì méjì, a dán wọn wò a fi idà pa wọn, wọ́n rìn káàkiri nínú awọ àgùntàn àti nínú awọ ewúrẹ́; wọn di aláìní, olùpọ́njú, ẹni tí a ń da lóró;
Ils ont été lapidés. On les a sciés. Ils ont été tentés. Ils ont été tués par l'épée. Ils allaient et venaient, vêtus de peaux de brebis et de peaux de chèvres, dans la misère, l'affliction, les mauvais traitements,
38 àwọn ẹni tí ayé ko yẹ fún. Wọ́n ń kiri nínú aṣálẹ̀, àti lórí òkè, àti nínú ihò àti nínú abẹ́ ilẹ̀.
eux dont le monde n'était pas digne, errant dans les déserts, les montagnes, les cavernes et les trous de la terre.
39 Gbogbo àwọn wọ̀nyí tí a jẹ́rìí rere sí nípa ìgbàgbọ́, wọn kò sì rí ìlérí náà gbà,
Tous ceux-là, après avoir été recommandés pour leur foi, n'ont pas reçu la promesse,
40 nítorí Ọlọ́run ti pèsè ohun tí ó dára jù sílẹ̀ fún wa, pé láìsí wa, kí a má ṣe wọn pé.
Dieu ayant prévu quelque chose de meilleur à notre égard, afin que, sans nous, ils ne soient pas parfaits.

< Hebrews 11 >