< Hebrews 10 >
1 Nítorí tí òfin jẹ́ òjìji àwọn ohun rere ti ń bọ̀ tí kì í ṣe àwòrán tòótọ́ fún àwọn òtítọ́ náà, wọn kò lè fi ẹbọ kan náà tí wọn ń rú nígbà gbogbo lọ́dọọdún mu àwọn tí ń wá jọ́sìn di pípé.
Kutsal Yasa'da gelecek iyi şeylerin aslı yoktur, sadece gölgesi vardır. Bu nedenle Yasa, her yıl sürekli aynı kurbanları sunarak Tanrı'ya yaklaşanları asla yetkinliğe erdiremez.
2 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, a kì ìbá tí dẹ́kun àti máa rú wọn, nítorí àwọn ti ń sìn ki ìbá tí ní ìmọ̀ ẹ̀ṣẹ̀, nígbà tí a bá ti wẹ̀ wọ́n mọ́ lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo.
Erdirebilseydi, kurban sunmaya son verilmez miydi? Çünkü tapınanlar bir kez günahlarından arındıktan sonra artık günahlılık duygusu kalmazdı.
3 Ṣùgbọ́n nínú ẹbọ wọ̀nyí ni a ń ṣe ìrántí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́dọọdún.
Ancak o kurbanlar insanlara yıldan yıla günahlarını anımsatıyor.
4 Nítorí ko ṣe é ṣe fún ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù àti ti ewúrẹ́ láti mú ẹ̀ṣẹ̀ kúrò.
Çünkü boğalarla tekelerin kanı günahları ortadan kaldıramaz.
5 Nítorí náà nígbà tí Kristi wá sí ayé, ó wí pé, “Ìwọ kò fẹ́ ẹbọ àti ọrẹ, ṣùgbọ́n ara ni ìwọ ti pèsè fún mi,
Bunun için Mesih dünyaya gelirken şöyle diyor: “Kurban ve sunu istemedin, Ama bana bir beden hazırladın.
6 ẹbọ sísun àti ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ ni ìwọ kò ní inú dídùn sí.
Yakmalık sunudan ve günah sunusundan Hoşnut olmadın.
7 Nígbà náà ni mo wí pé, ‘Kíyèsi i (nínú ìwé kíká ni a gbé kọ ọ́ nípa ti èmi) mo dé láti ṣe ìfẹ́ rẹ, Ọlọ́run.’”
O zaman şöyle dedim: ‘Kutsal Yazı tomarında Benim için yazıldığı gibi, Senin isteğini yapmak üzere, Ey Tanrı, işte geldim.’”
8 Nígbà tí o wí ni ìṣáájú pé, “Ìwọ kò fẹ́ ẹbọ àti ọrẹ àti ẹbọ sísun, àti ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò ni inú dídùn si wọn” (àwọn èyí tí a ń rú gẹ́gẹ́ bí òfin).
Mesih ilkin, “Kurban, sunu, yakmalık sunu, günah sunusu istemedin ve bunlardan hoşnut olmadın” dedi. Oysa bunlar Yasa'nın bir gereği olarak sunulur.
9 Nígbà náà ni ó wí pé, “Kíyèsi i, mo de láti ṣe ìfẹ́ rẹ Ọlọ́run.” Ó mú ti ìṣáájú kúrò, kí a lè fi ìdí èkejì múlẹ̀.
Sonra, “Senin isteğini yapmak üzere işte geldim” dedi. Yani ikinciyi geçerli kılmak için birinciyi ortadan kaldırıyor.
10 Nípa ìfẹ́ náà ni a ti sọ wá di mímọ́ nípa ẹbọ ti Jesu Kristi fi ara rẹ̀ rú lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo.
Tanrı'nın bu isteği uyarınca, İsa Mesih'in bedeninin ilk ve son kez sunulmasıyla kutsal kılındık.
11 Àti olúkúlùkù àlùfáà sì ń dúró lójoojúmọ́ láti ṣiṣẹ́ ìsìn, ó sì ń ṣe ẹbọ kan náà nígbàkígbà, tí kò lè mú ẹ̀ṣẹ̀ kúrò láé.
Her kâhin her gün ayakta durup görevini yapar ve günahları asla ortadan kaldıramayan aynı kurbanları tekrar tekrar sunar.
12 Ṣùgbọ́n òun, lẹ́yìn ìgbà tí o ti rú ẹbọ kan fún ẹ̀ṣẹ̀ títí láé, o jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún Ọlọ́run;
Oysa Mesih günahlar için sonsuza dek geçerli tek bir kurban sunduktan sonra Tanrı'nın sağında oturdu.
13 láti ìgbà náà, ó retí títí a o fi àwọn ọ̀tá rẹ̀ ṣe àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀.
O zamandan beri düşmanlarının, kendi ayaklarının altına serilmesini bekliyor.
14 Nítorí nípa ẹbọ kan a ti mú àwọn tí a sọ di mímọ́ pé títí láé.
Çünkü kutsal kılınanları tek bir sunuyla sonsuza dek yetkinliğe erdirmiştir.
15 Ẹ̀mí Mímọ́ sì ń jẹ́rìí fún wa pẹ̀lú, nítorí lẹ́yìn tí ó wí pé,
Kutsal Ruh da bu konuda bize tanıklık ediyor. Önce diyor ki,
16 “Èyí ni májẹ̀mú ti èmi o ba wọn dá lẹ́hìn àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, ni Olúwa wí. Èmi o fi òfin mi sí wọn ní ọkàn, inú wọn pẹ̀lú ni èmi o sì kọ wọn sí.”
“Rab, ‘O günlerden sonra Onlarla yapacağım antlaşma şudur: Yasalarımı yüreklerine koyacağım, Zihinlerine yazacağım’ diyor.”
17 Ó tún sọ wí pé: “Ẹ̀ṣẹ̀ wọn àti àìṣedéédéé wọn lèmi kì yóò sì rántí mọ́.”
Sonra şunu ekliyor: “Onların günahlarını ve suçlarını artık anmayacağım.”
18 Ṣùgbọ́n níbi tí ìmúkúrò ìwọ̀nyí bá gbé wà, ìrúbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ kò sí mọ́.
Bunların bağışlanması durumunda artık günah için sunuya gerek yoktur.
19 Ará, ǹjẹ́ bí a ti ní ìgboyà láti wọ inú Ibi Mímọ́ Jùlọ nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ Jesu,
Bu nedenle, ey kardeşler, İsa'nın kanı sayesinde perdede, yani kendi bedeninde bize açtığı yeni ve diri yoldan kutsal yere girmeye cesaretimiz vardır.
20 nípa ọ̀nà títún àti ààyè, tí o yà sí mímọ́ fún wa, àti láti kọjá aṣọ ìkélé èyí yìí ní, ara rẹ̀;
21 àti bí a ti ni àlùfáà gíga lórí ilé Ọlọ́run;
Tanrı'nın evinden sorumlu büyük bir kâhinimiz bulunmaktadır.
22 ẹ jẹ́ kí a fi òtítọ́ ọkàn súnmọ́ tòsí ni ẹ̀kún ìgbàgbọ́, kí a sì wẹ ọkàn wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀rí ọkàn búburú, kí a sì fi omi mímọ́ wẹ ara wa nù.
Öyleyse yüreklerimiz serpmeyle kötü vicdandan arınmış, bedenlerimiz temiz suyla yıkanmış olarak, imanın verdiği tam güvenceyle, yürekten bir içtenlikle Tanrı'ya yaklaşalım.
23 Ẹ jẹ́ kí a di ìjẹ́wọ́ ìrètí wa mu ṣinṣin ni àìṣiyèméjì, nítorí pé olóòtítọ́ ní ẹni tí o ṣe ìlérí.
Açıkça benimsediğimiz umuda sımsıkı tutunalım. Çünkü vaat eden Tanrı güvenilirdir.
24 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ara wa wò láti ru ara wa sí ìfẹ́ àti sí iṣẹ́ rere,
Birbirimizi sevgi ve iyi işler için nasıl gayrete getirebileceğimizi düşünelim.
25 kí a ma máa kọ ìpéjọpọ̀ ara wa sílẹ̀, gẹ́gẹ́ bi àṣà àwọn ẹlòmíràn; ṣùgbọ́n kí a máa gba ara ẹni níyànjú pẹ̀lúpẹ̀lú bí ẹ̀yin ti rí i pé ọjọ́ náà ń súnmọ́ etílé.
Bazılarının alıştığı gibi, bir araya gelmekten vazgeçmeyelim; o günün yaklaştığını gördükçe birbirimizi daha da çok yüreklendirelim.
26 Nítorí bí àwa ba mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí àwa bá ti gba ìmọ̀ òtítọ́ kò tún sí ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ mọ́.
Gerçeği öğrenip benimsedikten sonra, bile bile günah işlemeye devam edersek, günahlar için artık kurban kalmaz; geriye sadece yargının dehşetli beklenişi ve düşmanları yiyip bitirecek kızgın ateş kalır.
27 Bí kò ṣe ìrètí ìdájọ́ tí ó ba ni lẹ́rù, àti ti ìbínú ti o múná, tí yóò pa àwọn ọ̀tá run.
28 Ẹnikẹ́ni tí ó ba gan òfin Mose, ó kú láìsí àánú nípa ẹ̀rí ẹni méjì tàbí mẹ́ta.
Musa'nın Yasası'nı hiçe sayan, iki ya da üç tanığın sözüyle acımasızca öldürülür.
29 Mélòó mélòó ni ẹ rò pé a o jẹ ẹni náà ní ìyà kíkan, ẹni tí o tẹ Ọmọ Ọlọ́run mọ́lẹ̀ tí ó sì ti ka ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú ti a fi sọ ọ́ di mímọ́ si ohun àìmọ́, tí ó sì ti kẹ́gàn ẹ̀mí oore-ọ̀fẹ́.
Eğer bir kimse Tanrı Oğlu'nu ayaklar altına alır, kendisini kutsal kılan antlaşma kanını bayağı sayar ve lütufkâr Ruh'a hakaret ederse, bundan ne kadar daha ağır bir cezaya layık görülecek sanırsınız?
30 Nítorí àwa mọ ẹni tí o wí pé, Ẹ̀san ni ti èmi, Olúwa wí pé, “Èmi ó gbẹ̀san.” Àti pẹ̀lú, “Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.”
Çünkü, “Öç benimdir, karşılığını ben vereceğim” ve yine, “Rab halkını yargılayacak” diyeni tanıyoruz.
31 Ohun ẹ̀rù ni láti ṣubú sí ọwọ́ Ọlọ́run alààyè.
Diri Tanrı'nın eline düşmek korkunç bir şeydir.
32 Ṣùgbọ́n ẹ rántí ọjọ́ ìṣáájú nínú èyí tí, nígbà tí a ti sí yin lójú, ẹ fi ara da wàhálà ńlá ti ìjìyà;
Sizlerse aydınlandıktan sonra acılarla dolu büyük bir mücadeleye dayandığınız o ilk günleri anımsayın.
33 lápákan, nígbà tí a sọ yín di ìran wíwò nípa ẹ̀gàn àti ìpọ́njú; àti lápákan, nígbà tí ẹ̀yin di ẹgbẹ́ àwọn tí a ṣe bẹ́ẹ̀ si.
Bazen sitemlere, sıkıntılara uğrayıp seyirlik oldunuz, bazen de aynı durumda olanlarla dayanışma içine girdiniz.
34 Nítorí ẹ̀yin bá àwọn tí ó wà nínú ìdè kẹ́dùn, ẹ sì fi ayọ̀ gba ìkólọ ẹrù yin, nítorí ẹ̀yin mọ nínú ara yin pé, ẹ ni ọrọ̀ tí ó wà títí, tí ó sì dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.
Hem hapistekilerin dertlerine ortak oldunuz, hem de daha iyi ve kalıcı bir malınız olduğunu bilerek mallarınızın yağma edilmesini sevinçle karşıladınız.
35 Nítorí náà ẹ má ṣe gbé ìgboyà yín sọnù, èyí ti o ni èrè ńlá.
Onun için cesaretinizi yitirmeyin; bu cesaretin ödülü büyüktür.
36 Nítorí ẹ̀yin kò le ṣe aláìní sùúrù, nítorí ìgbà tí ẹ̀yin bá ti ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run tan kí ẹ̀yin le gba ìlérí náà.
Çünkü Tanrı'nın isteğini yerine getirmek ve vaat edilene kavuşmak için dayanma gücüne ihtiyacınız vardır.
37 Nítorí, “Ni ìwọ̀n ìgbà díẹ̀ sí i, ẹni náà ti ń bọ̀ yóò dé, kí yóò sì jáfara.
Artık, “Gelecek olan pek yakında gelecek Ve gecikmeyecek.
38 Ṣùgbọ́n, “Olódodo ni yóò yè nípa ìgbàgbọ́. Ṣùgbọ́n bí o ba fàsẹ́yìn, ọkàn mi kò ní inú dídùn sí i.”
Doğru adamım, imanla yaşayacaktır. Ama geri çekilirse, ondan hoşnut olmayacağım.”
39 Ṣùgbọ́n àwa kò sí nínú àwọn tí ń fàsẹ́yìn sínú ègbé; bí kò ṣe nínú àwọn tí o gbàgbọ́ sí ìgbàlà ọkàn.
Bizler geri çekilip mahvolanlardan değiliz; iman edip canlarının kurtuluşuna kavuşanlardanız.