< Hebrews 1 >

1 Ní ìgbà àtijọ́, Ọlọ́run bá àwọn baba ńlá wa sọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì ní ọ̀pọ̀ ìgbà àti ní onírúurú ọ̀nà,
purā ya īśvarō bhaviṣyadvādibhiḥ pitr̥lōkēbhyō nānāsamayē nānāprakāraṁ kathitavān
2 ṣùgbọ́n ní ìgbà ìkẹyìn yìí Ọlọ́run ń bá wa sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ Ọmọ rẹ̀ Jesu Kristi, ẹni tí ó fi ṣe ajogún ohun gbogbo, nípasẹ̀ ẹni tí ó dá gbogbo ayé yìí àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. (aiōn g165)
sa ētasmin śēṣakālē nijaputrēṇāsmabhyaṁ kathitavān| sa taṁ putraṁ sarvvādhikāriṇaṁ kr̥tavān tēnaiva ca sarvvajaganti sr̥ṣṭavān| (aiōn g165)
3 Ọmọ tí í ṣe ìtànṣán ògo Ọlọ́run àti àwòrán òun tìkára rẹ̀, tí ó sì ń fi ọ̀rọ̀ agbára rẹ̀ mú ohun gbogbo dúró. Lẹ́yìn tí ó ti ṣe ìwẹ̀nù ẹ̀ṣẹ̀ wa tan, ó wá jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún Ọláńlá ní òkè.
sa putrastasya prabhāvasya pratibimbastasya tattvasya mūrttiścāsti svīyaśaktivākyēna sarvvaṁ dhattē ca svaprāṇairasmākaṁ pāpamārjjanaṁ kr̥tvā ūrddhvasthānē mahāmahimnō dakṣiṇapārśvē samupaviṣṭavān|
4 Nítorí náà, ó sì ti fi bẹ́ẹ̀ di ẹni tí ó ga ní ipò ju angẹli lọ, bí ó ti jogún orúkọ èyí tí ó tayọ̀ tiwọn.
divyadūtagaṇād yathā sa viśiṣṭanāmnō 'dhikārī jātastathā tēbhyō'pi śrēṣṭhō jātaḥ|
5 Nítorí kò sí ọ̀kan nínú àwọn angẹli tí Ọlọ́run fi ìgbà kan sọ fún pé: “Ìwọ ni ọmọ mi; lónìí ni mo bí ọ”? Àti pẹ̀lú pé, “Èmi yóò jẹ́ baba fún un, Òun yóò sì jẹ́ ọmọ mi”?
yatō dūtānāṁ madhyē kadācidīśvarēṇēdaṁ ka uktaḥ? yathā, "madīyatanayō 'si tvam adyaiva janitō mayā|" punaśca "ahaṁ tasya pitā bhaviṣyāmi sa ca mama putrō bhaviṣyati|"
6 Àti pẹ̀lú, nígbà tí Ọlọ́run rán àkọ́bí rẹ̀ wá si ayé wa yìí. Ó pàṣẹ pé, “Ẹ jẹ́ kí gbogbo àwọn angẹli Ọlọ́run foríbalẹ̀ fún un.”
aparaṁ jagati svakīyādvitīyaputrasya punarānayanakālē tēnōktaṁ, yathā, "īśvarasya sakalai rdūtairēṣa ēva praṇamyatāṁ|"
7 Àti nípa ti àwọn angẹli, ó wí pé, “Ẹni tí ó dá àwọn angẹli rẹ̀ ní ẹ̀mí, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ọwọ́ iná.”
dūtān adhi tēnēdam uktaṁ, yathā, "sa karōti nijān dūtān gandhavāhasvarūpakān| vahniśikhāsvarūpāṁśca karōti nijasēvakān||"
8 Ṣùgbọ́n ó sọ nípa tí Ọmọ rẹ̀ pé, “Ìtẹ́ rẹ, Ọlọ́run, láé àti láéláé ni, ọ̀pá aládé òdodo ni ọ̀pá ìjọba rẹ. (aiōn g165)
kintu putramuddiśya tēnōktaṁ, yathā, "hē īśvara sadā sthāyi tava siṁhāsanaṁ bhavēt| yāthārthyasya bhavēddaṇḍō rājadaṇḍastvadīyakaḥ| (aiōn g165)
9 Ìwọ fẹ́ òdodo, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kórìíra iṣẹ́ búburú; nítorí èyí ni Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ ṣe fi àmì òróró ayọ̀ yàn ọ tí ó gbé ọ ju àwọn ẹgbẹ́ rẹ lọ.”
puṇyē prēma karōṣi tvaṁ kiñcādharmmam r̥tīyasē| tasmād ya īśa īśastē sa tē mitragaṇādapi| adhikāhlādatailēna sēcanaṁ kr̥tavān tava||"
10 Ó tún sọ pé, “Ní àtètèkọ́ṣe, ìwọ Olúwa, ìwọ fi ìdí ayé sọlẹ̀, àwọn ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ ara rẹ.
punaśca, yathā, "hē prabhō pr̥thivīmūlam ādau saṁsthāpitaṁ tvayā| tathā tvadīyahastēna kr̥taṁ gaganamaṇḍalaṁ|
11 Wọn yóò ṣègbé, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà síbẹ̀ gbogbo wọn ni yóò di àkísà bí ẹ̀wù.
imē vinaṁkṣyatastvantu nityamēvāvatiṣṭhasē| idantu sakalaṁ viśvaṁ saṁjariṣyati vastravat|
12 Ní kíká ni ìwọ yóò ká wọn bí aṣọ, bí ìpààrọ̀ aṣọ ni a ó sì pààrọ̀ wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ fúnra rẹ̀ kì yóò yípadà àti pé ọdún rẹ kì yóò ní òpin.”
saṅkōcitaṁ tvayā tattu vastravat parivartsyatē| tvantu nityaṁ sa ēvāsī rnirantāstava vatsarāḥ||"
13 Èwo nínú àwọn angẹli ní a gbọ́ pé Ọlọ́run fi ìgbà kan wí fún pé, “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ”?
aparaṁ dūtānāṁ madhyē kaḥ kadācidīśvarēṇēdamuktaḥ? yathā, "tavārīn pādapīṭhaṁ tē yāvannahi karōmyahaṁ| mama dakṣiṇadigbhāgē tāvat tvaṁ samupāviśa||"
14 Kì í ha á ṣe ẹ̀mí tí ń jíṣẹ́ ni àwọn angẹli í ṣe bí; tí a rán lọ síta láti máa ṣiṣẹ́ fún àwọn tí yóò jogún ìgbàlà?
yē paritrāṇasyādhikāriṇō bhaviṣyanti tēṣāṁ paricaryyārthaṁ prēṣyamāṇāḥ sēvanakāriṇa ātmānaḥ kiṁ tē sarvvē dūtā nahi?

< Hebrews 1 >