< Haggai 1 >

1 Ní ọdún kejì ọba Dariusi ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai sí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti sọ́dọ̀ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
În anul al doilea al împăratului Darius, în luna a șasea, în ziua întâi a lunii, a venit cuvântul DOMNULUI prin profetul Hagai la Zorobabel, fiul lui Șealtiel, guvernatorul lui Iuda, și către Iosua, fiul lui Ioțadac, marele preot, spunând:
2 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò tí ì tó àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’”
Astfel vorbește DOMNUL oștirilor, spunând: Acest popor spune: Nu a venit timpul, timpul să fie construită casa DOMNULUI.
3 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hagai wí pé,
Atunci a venit cuvântul DOMNULUI prin profetul Hagai, spunând:
4 “Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fúnra yín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀ṣọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”
Pentru voi [este] timpul să locuiți în casele voastre căptușite cu lemn, iar această casă stă pustiită?
5 Nísìnsinyìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
Și acum astfel zice DOMNUL oștirilor: Luați aminte la căile voastre.
6 Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀. Ẹ̀yin jẹun, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; ẹyin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”
Ați semănat mult și adunați puțin; mâncați, dar nu aveți destul; beți, dar nu sunteți îndestulați cu băutură; vă îmbrăcați, dar nimănui nu îi este cald; și cel ce câștigă un venit, câștigă venit pentru a-l pune într-o pungă spartă.
7 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
Astfel spune DOMNUL oștirilor: Luați aminte la căile voastre.
8 Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà le è dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí.
Urcați-vă la munte și aduceți lemn și construiți casa; și eu îmi voi găsi plăcerea în ea și voi fi glorificat, spune DOMNUL.
9 “Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsi i, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dahoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀.
Vă așteptați la mult și, iată, a fost puțin; și când l-ați adus acasă, eu l-am suflat. De ce? Spune DOMNUL oștirilor. Din cauza casei mele care [stă] pustiită, în timp ce voi alergați fiecare pentru propria lui casă.
10 Nítorí yín ni àwọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde.
De aceea cerul de deasupra voastră este oprit a da rouă și pământul este oprit a da rodul lui.
11 Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí àwọn òkè ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”
Și am chemat o secetă peste țară și peste munți și peste grâne și peste vinul nou și peste untdelemn și peste ceea ce dă pământul și peste oameni și peste vite și peste toată lucrarea mâinilor.
12 Nígbà náà ni Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hagai, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.
Atunci Zorobabel, fiul lui Șealtiel, și Iosua, fiul lui Ioțadac, marele preot, împreună cu toată rămășița poporului, au ascultat de vocea DOMNULUI Dumnezeului lor și de cuvintele profetului Hagai, precum DOMNUL Dumnezeul lor l-a trimis; și poporul s-a temut înaintea DOMNULUI.
13 Nígbà náà ni Hagai ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí.
Atunci a vorbit Hagai, mesagerul DOMNULUI, în mesajul DOMNULUI către popor, spunând: Eu sunt cu voi, zice DOMNUL.
14 Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli sókè, baálẹ̀ Juda àti ẹ̀mí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn,
Și DOMNUL a stârnit duhul lui Zorobabel, fiul lui Șealtiel, guvernator al lui Iuda și duhul lui Iosua, fiul lui Ioțadac, marele preot, și duhul întregii rămășițe a poporului; și ei au venit și au lucrat la casa DOMNULUI oștirilor, Dumnezeul lor,
15 ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dariusi.
În ziua a douăzeci și patra a lunii a șasea, în anul al doilea al împăratului Darius.

< Haggai 1 >