< Haggai 1 >

1 Ní ọdún kejì ọba Dariusi ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai sí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti sọ́dọ̀ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
Na rĩrĩ, mwaka-inĩ wa keerĩ wa gũthamaka kwa Dario, mũthenya wa mbere wa mweri wa gatandatũ, ndũmĩrĩri ya Jehova nĩyakinyĩire Zerubabeli mũrũ wa Shealitieli, mwathi wa bũrũri wa Juda, na kũrĩ Joshua mũrũ wa Jehozadaki, mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene, na kanua ka mũnabii Hagai makĩĩrwo atĩrĩ,
2 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò tí ì tó àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’”
Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga atĩrĩ, “Andũ aya moigaga atĩrĩ, ‘Ihinda ti ikinyu rĩa gwakĩra Jehova nyũmba.’”
3 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hagai wí pé,
Ningĩ ndũmĩrĩri ya Jehova ĩgĩũka na kanua ka mũnabii Hagai ĩkĩũria atĩrĩ,
4 “Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fúnra yín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀ṣọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”
“Anga nĩ ihinda rĩanyu inyuĩ ene rĩa gũikara nyũmba iria ngʼemie na mbaũ rĩrĩa nyũmba ĩno yakwa ĩikarĩte ĩrĩ nyanangĩku?”
5 Nísìnsinyìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
Na rĩrĩ, Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga atĩrĩ, “Mwĩcũraniei wega ũrĩa mĩthiĩre yanyu ĩtariĩ.
6 Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀. Ẹ̀yin jẹun, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; ẹyin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”
Mũhaandĩte irio nyingĩ, no mũkagetha o tũnini. Mũrĩĩaga no mũtihũũnaga. Mũnyuuaga no mũtinyootokaga. Mwĩhumbaga nguo no mũtiiguaga ũrugarĩ. Ningĩ ũrĩa ũthũkũmaga, aanyiita mũcaara wake awĩkagĩra mũhuko ũrĩ na marima.”
7 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga atĩrĩ, “Mwĩcũraniei wega ũrĩa mĩthiĩre yanyu ĩtariĩ.
8 Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà le è dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí.
Ambatai irĩma-inĩ mũgĩĩre mbaũ, mũũke mũnjakĩre nyũmba, nĩgeetha niĩ ndĩmĩkenagĩre na nduĩke wa gũtĩĩagwo,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
9 “Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsi i, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dahoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀.
Mwerĩgagĩrĩra uumithio mũingĩ, no rĩrĩ, mũkĩona o kĩndũ kĩnini. Kĩrĩa mwainũkirie, ngĩkĩũmbũra na mĩhũmũ yakwa. Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekũũria atĩrĩ, “Ndeekire ũguo nĩkĩ? Ndeekire ũguo nĩ ũndũ wa nyũmba yakwa, ĩrĩa ĩikarĩte ĩrĩ nyanangĩku, rĩrĩa o ũmwe wanyu arahangʼĩra maũndũ ma nyũmba yake mwene.
10 Nítorí yín ni àwọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde.
Nĩ ũndũ wanyu, igũrũ nĩrĩregete gũita ime, nayo thĩ ĩkarega na maciaro mayo.
11 Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí àwọn òkè ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”
Nĩndatũmire bũrũri wage mbura mĩgũnda-inĩ na irĩma-inĩ, o na ngĩũmia ngano, na ngĩniina ndibei ya mũhihano na maguta na kĩrĩa gĩothe thĩ ĩciaraga, na ngĩnyiihia andũ na mahiũ, na ngĩthũkia wĩra wa moko manyu.”
12 Nígbà náà ni Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hagai, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.
Ningĩ Zerubabeli mũrũ wa Shealitieli, na Joshua mũrũ wa Jehozadaki, mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene, na matigari mothe ma andũ, magĩathĩkĩra mũgambo wa Jehova Ngai wao, o na ndũmĩrĩri ya mũnabii Hagai, tondũ nĩ Jehova Ngai wao wamũtũmĩte. Nao andũ acio magĩĩtigĩra Jehova.
13 Nígbà náà ni Hagai ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí.
Ningĩ Hagai mũtũmwo wa Jehova akĩheana ndũmĩrĩri ĩno ya Jehova kũrĩ andũ, akĩmeera atĩrĩ: Jehova ekuuga atĩrĩ, “Niĩ ndĩ hamwe na inyuĩ.”
14 Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli sókè, baálẹ̀ Juda àti ẹ̀mí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn,
Nake Jehova akĩarahũra roho wa Zerubabeli mũrũ wa Shealitieli, mwathi wa Juda, na roho wa Joshua mũrũ wa Jehozadaki, mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene, o na roho wa andũ othe arĩa maatigarĩte, nao magĩũka, makĩambĩrĩria kũruta wĩra wa nyũmba ya Jehova Mwene-Hinya-Wothe, Ngai wao.
15 ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dariusi.
Kwarĩ mũthenya wa mĩrongo ĩĩrĩ na ĩna, mweri wa gatandatũ, mwaka-inĩ wa keerĩ wa gũthamaka kwa Dario.

< Haggai 1 >