< Haggai 2 >

1 Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù keje, ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai wí pé,
În luna a șaptea, în ziua a douăzeci și una a lunii, a venit cuvântul DOMNULUI prin profetul Hagai, spunând:
2 “Sọ fún Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn yòókù. Béèrè lọ́wọ́ wọn pé,
Vorbește acum lui Zorobabel, fiul lui Șealtiel, guvernator al lui Iuda, și lui Iosua, fiul lui Ioțadac, marele preot, și rămășiței poporului, spunând:
3 ‘Ta ni nínú yín tí ó kù tí ó sì ti rí ilé yìí ní ògo rẹ̀ àkọ́kọ́? Báwo ni ó ṣe ri sí yín nísinsin yìí? Ǹjẹ́ kò dàbí asán lójú yín?
Cine a mai rămas între voi dintre cei ce au văzut această casă în gloria ei dintâi? Și cum o vedeți acum? Nu este ea ca nimic în ochii voștri pe lângă aceea?
4 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, múra gírí, ìwọ Serubbabeli,’ ni Olúwa wí. ‘Múra gírí, ìwọ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà. Ẹ sì múra gírí gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ilẹ̀ náà,’ ni Olúwa wí, ‘kí ẹ sì ṣiṣẹ́. Nítorí èmi wà pẹ̀lú yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Totuși acum fii tare, Zorobabel, spune DOMNUL; și fii tare, Iosua, fiu al lui Ioțadac, marele preot; și fiți tari, voi, tot poporul țării, zice DOMNUL, și lucrați, pentru că eu sunt cu voi, spune DOMNUL oștirilor;
5 ‘Èyí ni ohun tí Èmi fi bá a yín dá májẹ̀mú nígbà tí ẹ jáde kúrò ní Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni Ẹ̀mí ì mi sì wà pẹ̀lú yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù.’
Conform cuvântului prin care am făcut legământ cu voi, când ați ieșit din Egipt, tot astfel duhul meu rămâne printre voi: nu vă temeți.
6 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Láìpẹ́ jọjọ, Èmi yóò mi àwọn ọrun àti ayé, Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
Fiindcă astfel spune DOMNUL oștirilor: Încă o dată, mai este puțin timp și voi clătina cerurile și pământul și marea și uscatul;
7 Èmi yóò mi gbogbo orílẹ̀-èdè, ìfẹ́ gbogbo orílẹ̀-èdè yóò fà sí tẹmpili yìí, Èmi yóò sì kún ilé yìí pẹ̀lú ògo,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Și voi clătina toate națiunile și dorința tuturor națiunilor va veni, și voi umple casa aceasta cu glorie, spune DOMNUL oștirilor.
8 ‘Tèmi ni fàdákà àti wúrà,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Argintul este al meu și aurul este al meu, spune DOMNUL oștirilor.
9 ‘Ògo ìkẹyìn ilé yìí yóò pọ̀ ju ti ìṣáájú lọ,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Àti ní ìhín yìí ni Èmi ó sì fi àlàáfíà fún ni,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
Gloria acestei case de pe urmă va fi mai mare decât cea dinainte, spune DOMNUL oștirilor; și în acest loc voi da pace, zice DOMNUL oștirilor.
10 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Hagai wá pé,
În ziua a douăzeci și patra a lunii a noua, în anul al doilea al lui Darius, a venit cuvântul DOMNULUI prin profetul Hagai, spunând:
11 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà ohun tí òfin wí pé:
Astfel zice DOMNUL oștirilor: Întreabă acum pe preoți, referitor [la] lege, spunând:
12 Bí ẹnìkan bá gbé ẹran mímọ́ ní ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, tí ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀ kan àkàrà tàbí ọbẹ̀, wáìnì, òróró tàbí oúnjẹ mìíràn, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ mímọ́ bí?’” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
Dacă cineva poartă carne sfântă în poala hainei lui și cu poala sa atinge pâine sau supă sau vin sau untdelemn sau orice hrană, va fi aceasta sfântă? Și preoții au răspuns și au zis: Nu.
13 Nígbà náà ni Hagai wí pé, “Bí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífi ara kan òkú bá fi ara kan ọ̀kan lára nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ aláìmọ́?” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, yóò jẹ́ aláìmọ́.”
Atunci Hagai a spus: Dacă [cineva] care este necurat printr-un trup mort atinge vreuna din acestea, va fi aceasta necurată? Și preoții au răspuns și au zis: Va fi necurată.
14 Nígbà náà ni Hagai dáhùn ó sì wí pé, “‘Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn wọ̀nyí rí, bẹ́ẹ̀ sì ni orílẹ̀-èdè yìí rí níwájú mi,’ ni Olúwa wí. ‘Bẹ́ẹ̀ sì ni olúkúlùkù iṣẹ́ ọwọ́ wọn; èyí tí wọ́n sì fi rú ẹbọ níbẹ̀ jẹ́ aláìmọ́.
Atunci Hagai a răspuns și a zis: Așa este acest popor și așa este această națiune înaintea mea, zice DOMNUL; și așa este fiecare lucrare a mâinilor lor; și ceea ce ei oferă acolo este necurat.
15 “‘Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ ro èyí dáradára láti òní yìí lọ, ẹ kíyèsi bí nǹkan ṣe rí tẹ́lẹ̀, a to òkúta kan lé orí èkejì ní tẹmpili Olúwa.
Și acum, vă rog, luați aminte din această zi și de acum încolo, înainte de a se pune piatră pe piatră în templul DOMNULUI;
16 Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi òkìtì òsùwọ̀n ogun, mẹ́wàá péré ni yóò ba níbẹ̀. Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi ìfúntí wáìnì láti wọn àádọ́ta ìwọ̀n, ogún péré ni yóò ba níbẹ̀.
De când au fost acele zile, când cineva venea la o grămadă de douăzeci de măsuri, erau doar zece; când cineva venea la teasc să scoată cincizeci de vase din teasc, erau doar douăzeci.
17 Mo fi ìrẹ̀dànù, ìmúwòdù àti yìnyín bá gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín jẹ; síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí ọ̀dọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
V-am lovit cu tăciune [în grâu] și cu mană și cu grindină în toate ostenelile mâinilor voastre; totuși nu v-ați întors la mine, spune DOMNUL.
18 ‘Láti òní lọ, láti ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán yìí kí ẹ kíyèsi, kí ẹ sì rò ó dáradára, ọjọ́ ti a fi ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa lélẹ̀, rò ó dáradára.
Luați aminte acum din această zi și de acum încolo, din a douăzeci și patra zi a lunii a noua, din ziua când a fost pusă temelia templului DOMNULUI, luați aminte.
19 Ǹjẹ́ èso ha wà nínú abà bí? Títí di àkókò yìí, àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ àti pomegiranate, àti igi olifi kò ì tí ì so èso kankan. “‘Láti òní lọ ni èmi yóò bùkún fún un yin.’”
Este încă sămânța în grânar? Da, și vița și smochinul și rodiul și măslinul, nu au rodit: din această zi vă voi binecuvânta.
20 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ Hagai wá nígbà kejì, ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù náà pé,
Și din nou cuvântul DOMNULUI a venit la Hagai, în a douăzeci și patra zi a lunii, spunând:
21 “Sọ fún Serubbabeli baálẹ̀ Juda pé èmi yóò mi àwọn ọ̀run àti ayé.
Vorbește lui Zorobabel, guvernatorul lui Iuda, zicând: Voi clătina cerurile și pământul;
22 Èmi yóò bi ìtẹ́ àwọn ìjọba ṣubú, Èmi yóò sì pa agbára àwọn aláìkọlà run, Èmi yóò sì dojú àwọn kẹ̀kẹ́ ogun dé, àti àwọn tí ń gùn wọ́n; ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin yóò ṣubú; olúkúlùkù nípa idà arákùnrin rẹ̀.”
Și voi dărâma tronul împărățiilor și voi distruge tăria împărățiilor păgânilor; și voi răsturna carele și pe cei ce merg cu ele; și caii și călăreții lor vor cădea, fiecare prin sabia fratelui său.
23 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní ọjọ́ náà, ìwọ ìránṣẹ́ mi Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Èmi yóò mú ọ, Èmi yóò sì sọ ọ di bí òrùka èdìdì mi, nítorí mo ti yan ọ, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
În acea zi, spune DOMNUL oștirilor, te voi lua, Zorobabel, servitorul meu, fiul lui Șealtiel, zice DOMNUL, și te voi face ca un sigiliu, pentru că eu te-am ales, spune DOMNUL oștirilor.

< Haggai 2 >