< Haggai 2 >

1 Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù keje, ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai wí pé,
W siódmym [miesiącu], dwudziestego pierwszego [dnia] tego miesiąca, słowo PANA doszło przez proroka Aggeusza mówiące:
2 “Sọ fún Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn yòókù. Béèrè lọ́wọ́ wọn pé,
Mów teraz do Zorobabela, syna Szealtiela, namiestnika Judy, i do Jozuego, syna Josadaka, najwyższego kapłana, oraz do reszty ludu:
3 ‘Ta ni nínú yín tí ó kù tí ó sì ti rí ilé yìí ní ògo rẹ̀ àkọ́kọ́? Báwo ni ó ṣe ri sí yín nísinsin yìí? Ǹjẹ́ kò dàbí asán lójú yín?
Któż pozostał pośród was, który widział ten dom w jego dawnej chwale? A jakim go teraz widzicie? Czy nie wydaje się wam, że jest niczym w porównaniu z tamtym?
4 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, múra gírí, ìwọ Serubbabeli,’ ni Olúwa wí. ‘Múra gírí, ìwọ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà. Ẹ sì múra gírí gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ilẹ̀ náà,’ ni Olúwa wí, ‘kí ẹ sì ṣiṣẹ́. Nítorí èmi wà pẹ̀lú yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Teraz jednak umocnij się, Zorobabelu, mówi PAN; umocnij się, Jozue, synu Josadaka, najwyższy kapłanie; umocnij się też, cały ludu tej ziemi, mówi PAN, i pracujcie. Ja bowiem jestem z wami, mówi PAN zastępów.
5 ‘Èyí ni ohun tí Èmi fi bá a yín dá májẹ̀mú nígbà tí ẹ jáde kúrò ní Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni Ẹ̀mí ì mi sì wà pẹ̀lú yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù.’
Zgodnie ze słowem, przez które zawarłem z wami przymierze, gdy wyszliście z Egiptu, mój Duch jest stale wśród was, nie bójcie się.
6 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Láìpẹ́ jọjọ, Èmi yóò mi àwọn ọrun àti ayé, Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
Tak bowiem mówi PAN zastępów: Jeszcze raz, [po] krótkim [czasie], wstrząsnę niebem i ziemią, morzem i lądem;
7 Èmi yóò mi gbogbo orílẹ̀-èdè, ìfẹ́ gbogbo orílẹ̀-èdè yóò fà sí tẹmpili yìí, Èmi yóò sì kún ilé yìí pẹ̀lú ògo,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Wstrząsnę wszystkimi narodami i przyjdzie Pożądany przez wszystkie narody. I napełnię ten dom chwałą, mówi PAN zastępów.
8 ‘Tèmi ni fàdákà àti wúrà,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Moje jest srebro i moje [jest] złoto, mówi PAN zastępów.
9 ‘Ògo ìkẹyìn ilé yìí yóò pọ̀ ju ti ìṣáájú lọ,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Àti ní ìhín yìí ni Èmi ó sì fi àlàáfíà fún ni,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
Chwała tego domu będzie większa od tej, jaką miał tamten dawny, mówi PAN zastępów; bo to miejsce obdarzę pokojem, mówi PAN.
10 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Hagai wá pé,
Dnia dwudziestego czwartego, dziewiątego [miesiąca], w drugim roku Dariusza, słowo PANA doszło przez proroka Aggeusza mówiące:
11 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà ohun tí òfin wí pé:
Tak mówi PAN zastępów: Zapytaj teraz kapłanów o prawo:
12 Bí ẹnìkan bá gbé ẹran mímọ́ ní ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, tí ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀ kan àkàrà tàbí ọbẹ̀, wáìnì, òróró tàbí oúnjẹ mìíràn, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ mímọ́ bí?’” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
Gdyby ktoś niósł poświęcone mięso [włożone] za połę swojej szaty, a połą dotknął chleba, potrawy, wina, oliwy lub jakiegokolwiek pokarmu, czy to stałoby się poświęcone? Odpowiedzieli kapłani: Nie.
13 Nígbà náà ni Hagai wí pé, “Bí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífi ara kan òkú bá fi ara kan ọ̀kan lára nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ aláìmọ́?” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, yóò jẹ́ aláìmọ́.”
Wtedy Aggeusz zapytał: Jeśli ktoś, będąc nieczysty od zwłok, dotknie którejś z tych rzeczy, czy staje się ona nieczysta? Odpowiedzieli kapłani: Stanie się nieczysta.
14 Nígbà náà ni Hagai dáhùn ó sì wí pé, “‘Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn wọ̀nyí rí, bẹ́ẹ̀ sì ni orílẹ̀-èdè yìí rí níwájú mi,’ ni Olúwa wí. ‘Bẹ́ẹ̀ sì ni olúkúlùkù iṣẹ́ ọwọ́ wọn; èyí tí wọ́n sì fi rú ẹbọ níbẹ̀ jẹ́ aláìmọ́.
Wtedy Aggeusz odezwał się i powiedział: Taki jest ten lud, taki jest ten naród przede mną, mówi PAN; takie jest każde dzieło ich rąk; i wszystko, co tam składają w ofierze, jest nieczyste.
15 “‘Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ ro èyí dáradára láti òní yìí lọ, ẹ kíyèsi bí nǹkan ṣe rí tẹ́lẹ̀, a to òkúta kan lé orí èkejì ní tẹmpili Olúwa.
Teraz więc, proszę, zastanówcie się, [jak się wam powodziło] od dzisiejszego dnia do minionych [dni], zanim ułożono kamień na kamieniu w świątyni PANA.
16 Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi òkìtì òsùwọ̀n ogun, mẹ́wàá péré ni yóò ba níbẹ̀. Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi ìfúntí wáìnì láti wọn àádọ́ta ìwọ̀n, ogún péré ni yóò ba níbẹ̀.
Dawniej, gdy ktoś przyszedł do stosu zboża z dwudziestu [miar], było [ich] tylko dziesięć; gdy przyszedł do prasy, aby naczerpać pięćdziesiąt wiader [wina], było [ich] tylko dwadzieścia.
17 Mo fi ìrẹ̀dànù, ìmúwòdù àti yìnyín bá gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín jẹ; síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí ọ̀dọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
Karałem was suszą, pleśnią i gradem we wszystkich dziełach waszych rąk; lecz żaden z was nie [wrócił] do mnie, mówi PAN.
18 ‘Láti òní lọ, láti ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán yìí kí ẹ kíyèsi, kí ẹ sì rò ó dáradára, ọjọ́ ti a fi ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa lélẹ̀, rò ó dáradára.
Zastanówcie się teraz [nad okresem] od dzisiejszego dnia po [dni] minione, od dnia dwudziestego czwartego, dziewiątego [miesiąca, to znaczy] od dnia, w którym położono [fundament] świątyni PANA; zastanówcie się.
19 Ǹjẹ́ èso ha wà nínú abà bí? Títí di àkókò yìí, àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ àti pomegiranate, àti igi olifi kò ì tí ì so èso kankan. “‘Láti òní lọ ni èmi yóò bùkún fún un yin.’”
Czy ziarno jeszcze [jest] w spichlerzu? I [owszem] ani winorośl, ani drzewo figowe, granatowe i oliwne nie wydały jeszcze owocu. Od tego dnia będę [wam] błogosławił.
20 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ Hagai wá nígbà kejì, ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù náà pé,
Potem słowo PANA doszło po raz drugi do Aggeusza dnia dwudziestego czwartego [tego] miesiąca mówiące:
21 “Sọ fún Serubbabeli baálẹ̀ Juda pé èmi yóò mi àwọn ọ̀run àti ayé.
Mów do Zorobabela, namiestnika Judy: Ja wstrząsnę niebiosami i ziemią;
22 Èmi yóò bi ìtẹ́ àwọn ìjọba ṣubú, Èmi yóò sì pa agbára àwọn aláìkọlà run, Èmi yóò sì dojú àwọn kẹ̀kẹ́ ogun dé, àti àwọn tí ń gùn wọ́n; ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin yóò ṣubú; olúkúlùkù nípa idà arákùnrin rẹ̀.”
I przewrócę tron królestw, i zniszczę moc królestw pogan; przewrócę także rydwany i tych, którzy na nich jeżdżą; i upadną konie i ich jeźdźcy, każdy od miecza swego brata.
23 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní ọjọ́ náà, ìwọ ìránṣẹ́ mi Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Èmi yóò mú ọ, Èmi yóò sì sọ ọ di bí òrùka èdìdì mi, nítorí mo ti yan ọ, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
W tym dniu, mówi PAN zastępów, wezmę cię, Zorobabelu, mój sługo, synu Szealtiela, mówi PAN, i uczynię cię niczym sygnet. Ja bowiem wybrałem ciebie, mówi PAN zastępów.

< Haggai 2 >